< Ezra 2 >
1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Et voici les fils de la terre promise qui partirent de la captivité et du lieu d'exil où les avait transportés Nabuchodonosor, roi de Babylone, pour retourner à Jérusalem et en Juda, chacun en sa ville.
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
Ceux qui partirent avec Zorobabel furent: Josué, Néhémias, Saraïas, Réhétias, Mardochée, Balasan, Masphar, Bachué, Rehum, Baana. Voici le dénombrement du peuple d'Israël
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Fils de Pharès: deux mille cent soixante-douze.
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Fils de Saphatia: trois cent soixante-douze.
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
Fils d'Arès: sept cent soixante-quinze.
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
Fils de Phaath -Moab, issus des fils de Josué et de Joab: deux mille huit cent douze.
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Fils d'Elam: mille deux cent cinquante-quatre.
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
Fils de Zatthua: neuf cent quarante-cinq.
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Fils de Zacchu: sept cent soixante.
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
Fils de Banui: six cent quarante-deux.
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
Fils de Balai: six cent vingt-trois.
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
Fils d'Asgad: mille deux cent vingt-deux.
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
Fils d'Adonicam: six cent soixante-six.
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Fils de Bagué: deux mille cinquante-six.
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
Fils d'Addin: quatre cent cinquante-quatre.
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
Fils d'Ater, issu d'Ezéchias: neuf cent huit.
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
Fils de Bassu: trois cent vingt-trois.
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Fils de Jora: cent douze.
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Fils d'Asum: deux cent vingt-trois.
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Fils de Gaber: quatre-vingt-quinze.
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Fils de Bethléem: cent vingt-trois.
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Fils de Netopha: cinquante-six.
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Fils d'Anathoth: cent vingt-huit.
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Fils d'Asmoth: quarante-trois.
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Fils de Cariathiarim, Haphira et Beroth: sept cent quarante-trois.
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
Fils de Rhama et de Gabaa: six cent vingt et un.
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Hommes de Machmas: cent vingt-deux.
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Hommes de Béthel et d'Aia: quatre cent vingt-trois.
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Fils de Nabu: cinquante-deux.
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
Fils de Magebis: cent cinquante-six.
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Fils d'Elamar: douze cent cinquante-quatre.
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
Fils d'Elam: trois cent vingt.
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Fils de Lodadi et d'Ono, sept cent vingt-cinq.
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
Fils de Jéricho: trois cent quarante-cinq.
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
Fils de Senaa: trois mille six cent trente.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Prêtres, fils de Jedua, de la maison de Josué: neuf cent soixante-treize.
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Fils d'Emmer: mille cinquante-deux.
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Fils de Phassur: douze cent quarante-sept.
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Fils d'Erem: mille sept.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Lévites, fils de Josué et de Cadmiel, des fils d'Oduia: soixante-quatorze.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
Chantres, fils d'Asaph: cent vingt-huit.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
Fils des portiers: fils de Sellom, fils d'Atér, fils de Telmon, fils d'Acub, fils d'Alita, fils de Sobaï: en tout, cent trente-neuf.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
Les Nathinéens: fils de Suthia, fils d'Asupha, fils de Tabaoth
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
Fils de Cades, fils de Siaa, fils de Phadon,
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
Fils de Laban, fils d'Agaba, fils d'Acub,
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
Fils d'Agab, fils de Selam, fils d'Anan,
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
Fils de Geddel, fils de Gaar, fils de Rhaïa,
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
Fils de Rason, fils de Necoda, fils de Gazena,
Fils d'Azo, fils de Phasé, fils de Basi,
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
Fils d'Asena, fils de Mounim, fils de Nephusim,
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
Fils de Bacbuc, fils d'Acupha, fils d'Azur,
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
Fils de Basaloth, fils de Maüda, fils d'Arsa,
53 Barkosi, Sisera, Tema,
Fils de Barcos, fils de Sisara, fils de Théma,
Fils de Nasthié, fils d'Atupha,
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
Fils de serviteurs de Salomon, fils de Sotaï, fils de Sephèra, fils de Phadura,
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Fils de Jeligla, fils de Darcon, fils de Gedel,
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
Fils de Saphatia, fils d'Atil, fils de Phacherath, fils d'Aseboïm, fils d'Emeï;
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Total des Nathinéens et des fils d'Abdeselma: trois cent quatre vingt- douze.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Et voici tous ceux qui partirent de Thelmelech: Thelaresa, Cherub, Hédan, Emmer; et ils n'étaient point capables de déclarer leurs familles paternelles ni leur race; car ils étaient nés hors d'Israël.
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Fils de Daldia, fils de Rua, fils de Tobias, fils de Necoda: six cent cinquante-deux.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
Et parmi les fils des prêtres, les fils de Labia, les fils d'Accus, les fils de Berzellaï, qui épousa l'une des filles de Berzellaï le Galaadite, et qui prit son nom;
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
Ceux-là cherchèrent leur généalogie, mais ils ne la trouvèrent pas, et ils furent rejetés du sacerdoce.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
Et l'athersastha leur dit de ne point manger des choses les plus saintes jusqu'à ce qu'un prêtre fût suscité, portant lumières et perfections.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
Or, toute l'Église réunie montait à environ quarante-deux mille trois cent soixante âmes.
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
Sans compter leurs serviteurs et leurs servantes au nombre de sept mille trois cent trente-sept, parmi lesquels il y avait deux cents chantres et chanteuses.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Ils avaient sept mille trente-six chevaux, deux cent quarante-cinq mulets,
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Quatre cent trente-cinq chameaux, six mille sept cent vingt ânes.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
Et quelques-uns des chefs de famille, lorsqu'ils entrèrent dans le temple du Seigneur à Jérusalem, offrirent volontairement de le relever au lieu qui était préparé,
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
Autant que le comportaient leurs richesses; ils donnèrent donc, au trésor des travaux, soixante et un mille mines d'or pur, cinq mille mines d'argent, et cent costumes sacerdotaux.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
Et les prêtres, et les lévites, et ceux du peuple, et les chantres, et les portiers, et les Nathinéens, et tout Israël, s'établirent dans leurs villes.