< Ezra 2 >

1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
And these [are] sons of the province who are going up—of the captives of the expulsion that Nebuchadnezzar king of Babylon removed to Babylon, and they return to Jerusalem and Judah, each to his city—
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
who have come in with Zerubbabel, Jeshua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordecai, Bilshan, Mispar, Bigvai, Rehum, Baanah. The number of the men of the people of Israel:
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
sons of Parosh, two thousand one hundred seventy-two;
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
sons of Shephatiah, three hundred seventy-two;
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
sons of Arah, seven hundred seventy-five;
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
sons of Pahath-Moab, of the sons of Jeshua [and] Joab, two thousand eight hundred and twelve;
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
sons of Elam, one thousand two hundred fifty-four;
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
sons of Zattu, nine hundred and forty-five;
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
sons of Zaccai, seven hundred and sixty;
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
sons of Bani, six hundred forty-two;
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
sons of Bebai, six hundred twenty-three;
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
sons of Azgad, one thousand two hundred twenty-two;
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
sons of Adonikam, six hundred sixty-six;
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
sons of Bigvai, two thousand fifty-six;
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
sons of Adin, four hundred fifty-four;
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
sons of Ater of Hezekiah, ninety-eight;
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
sons of Bezai, three hundred twenty-three;
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
sons of Jorah, one hundred and twelve;
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
sons of Hashum, two hundred twenty-three;
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
sons of Gibbar, ninety-five;
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
sons of Beth-Lehem, one hundred twenty-three;
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
men of Netophah, fifty-six;
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
men of Anathoth, one hundred twenty-eight;
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
sons of Azmaveth, forty-two;
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
sons of Kirjath-Arim, Chephirah, and Beeroth, seven hundred and forty-three;
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
sons of Ramah and Gaba, six hundred twenty-one;
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
men of Michmas, one hundred twenty-two;
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
men of Beth-El and Ai, two hundred twenty-three;
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
sons of Nebo, fifty-two;
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
sons of Magbish, one hundred fifty-six;
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
sons of another Elam, one thousand two hundred fifty-four;
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
sons of Harim, three hundred and twenty;
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
sons of Lod, Hadid, and Ono, seven hundred twenty-five;
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
sons of Jericho, three hundred forty-five;
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
sons of Senaah, three thousand and six hundred and thirty.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
The priests: sons of Jedaiah, of the house of Jeshua, nine hundred seventy-three;
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
sons of Immer, one thousand fifty-two;
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
sons of Pashhur, one thousand two hundred forty-seven;
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
sons of Harim, one thousand and seventeen.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
The Levites: sons of Jeshua and Kadmiel, of the sons of Hodaviah, seventy-four.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
The singers: sons of Asaph, one hundred twenty-eight.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
Sons of the gatekeepers: sons of Shallum, sons of Ater, sons of Talmon, sons of Akkub, sons of Hatita, sons of Shobai, the whole [are] one hundred thirty-nine.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
The Nethinim: sons of Ziha, sons of Hasupha, sons of Tabbaoth,
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
sons of Keros, sons of Siaha, sons of Padon,
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
sons of Lebanah, sons of Hagabah, sons of Akkub,
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
sons of Hagab, sons of Shalmai, sons of Hanan,
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
sons of Giddel, sons of Gahar, sons of Reaiah,
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
sons of Rezin, sons of Nekoda, sons of Gazzam,
49 Ussa, Pasea, Besai,
sons of Uzza, sons of Paseah, sons of Besai,
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
sons of Asnah, sons of Mehunim, sons of Nephusim,
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
sons of Bakbuk, sons of Hakupha, sons of Harhur,
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
sons of Bazluth, sons of Mehida, sons of Harsha,
53 Barkosi, Sisera, Tema,
sons of Barkos, sons of Sisera, sons of Thamah,
54 Nesia àti Hatifa.
sons of Neziah, sons of Hatipha.
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
Sons of the servants of Solomon: sons of Sotai, sons of Sophereth, sons of Peruda,
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
sons of Jaalah, sons of Darkon, sons of Giddel,
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
sons of Shephatiah, sons of Hattil, sons of Pochereth of Zebaim, sons of Ami.
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
All the Nethinim, and the sons of the servants of Solomon [are] three hundred ninety-two.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
And these [are] those going up from Tel-Melah, Tel-Harsa, Cherub, Addan, Immer, and they have not been able to declare the house of their fathers, and their seed, whether they [are] of Israel:
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
sons of Delaiah, sons of Tobiah, sons of Nekoda, six hundred fifty-two.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
And of the sons of the priests: sons of Habaiah, sons of Koz, sons of Barzillai (who took a wife from the daughters of Barzillai the Gileadite, and is called by their name);
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
these have sought their register among those reckoning themselves by genealogy, and they have not been found, and they are redeemed from the priesthood,
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
and the Tirshatha says to them that they do not eat of the most holy things until the standing up of a priest with [the] Lights and with [the] Perfections.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
All the assembly together [is] forty-two thousand three hundred sixty,
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
apart from their servants and their handmaids; these [are] seven thousand three hundred thirty-seven: and of them [are] two hundred male and female singers.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Their horses [are] seven hundred thirty-six, their mules, two hundred forty-five,
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
their camels, four hundred thirty-five, donkeys, six thousand seven hundred and twenty.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
And some of the heads of the fathers in their coming to the house of YHWH that [is] in Jerusalem, have offered willingly for the house of God, to establish it on its base;
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
according to their power they have given to the treasure of the work; of gold, sixty-one thousand drams, and of silver, five thousand pounds, and of priests’ coats, one hundred.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
And the priests dwell, and the Levites, and of the people, and the singers, and the gatekeepers, and the Nethinim, in their cities; even all Israel in their cities.

< Ezra 2 >