< Ezra 2 >

1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Now these are the children of the province, that went up out of the captivity of those that had been carried away, whom Nebuchadnezzar the king of Babylon had carried away unto Babylon, and that returned unto Jerusalem and Judah, every one unto his city;
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
who came with Zerubbabel, Jeshua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordecai, Bilshan, Mispar, Bigvai, Rehum, Baanah. The number of the men of the people of Israel:
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
The children of Parosh, two thousand a hundred seventy and two.
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
The children of Shephatiah, three hundred seventy and two.
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
The children of Arah, seven hundred seventy and five.
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
The children of Pahath-moab, of the children of Jeshua and Joab, two thousand eight hundred and twelve.
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
The children of Elam, a thousand two hundred fifty and four.
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
The children of Zattu, nine hundred forty and five.
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
The children of Zaccai, seven hundred and threescore.
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
The children of Bani, six hundred forty and two.
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
The children of Bebai, six hundred twenty and three.
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
The children of Azgad, a thousand two hundred twenty and two.
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
The children of Adonikam, six hundred sixty and six.
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
The children of Bigvai, two thousand fifty and six.
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
The children of Adin, four hundred fifty and four.
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
The children of Ater, of Hezekiah, ninety and eight.
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
The children of Bezai, three hundred twenty and three.
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
The children of Jorah, a hundred and twelve.
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
The children of Hashum, two hundred twenty and three.
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
The children of Gibbar, ninety and five.
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
The children of Beth-lehem, a hundred twenty and three.
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
The men of Netophah, fifty and six.
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
The men of Anathoth, a hundred twenty and eight.
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
The children of Azmaveth, forty and two.
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
The children of Kiriath-arim, Chephirah, and Beeroth, seven hundred and forty and three.
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
The children of Ramah and Geba, six hundred twenty and one.
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
The men of Michmas, a hundred twenty and two.
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
The men of Beth-el and Ai, two hundred twenty and three.
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
The children of Nebo, fifty and two.
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
The children of Magbish, a hundred fifty and six.
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
The children of the other Elam, a thousand two hundred fifty and four.
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
The children of Harim, three hundred and twenty.
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
The children of Lod, Hadid, and Ono, seven hundred twenty and five.
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
The children of Jericho, three hundred forty and five.
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
The children of Senaah, three thousand and six hundred and thirty.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
The priests: the children of Jedaiah, of the house of Jeshua, nine hundred seventy and three.
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
The children of Immer, a thousand fifty and two.
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
The children of Pashhur, a thousand two hundred forty and seven.
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
The children of Harim, a thousand and seventeen.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
The Levites: the children of Jeshua and Kadmiel, of the children of Hodaviah, seventy and four.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
The singers: the children of Asaph, a hundred twenty and eight.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
The children of the porters: the children of Shallum, the children of Ater, the children of Talmon, the children of Akkub, the children of Hatita, the children of Shobai, in all a hundred thirty and nine.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
The Nethinim: the children of Ziha, the children of Hasupha, the children of Tabbaoth;
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
the children of Keros, the children of Siaha, the children of Padon;
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
the children of Lebanah, the children of Hagabah, the children of Akkub;
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
the children of Hagab, the children of Salmai, the children of Hanan;
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
the children of Giddel, the children of Gahar, the children of Reaiah;
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
the children of Rezin, the children of Nekoda, the children of Gazzam;
49 Ussa, Pasea, Besai,
the children of Uzza, the children of Paseah, the children of Besai;
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
the children of Asnah, the children of Meunim, the children of Nephusim;
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
the children of Bakbuk, the children of Hakupha, the children of Harhur;
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
the children of Bazluth, the children of Mehida, the children of Harsha;
53 Barkosi, Sisera, Tema,
the children of Barkos, the children of Sisera, the children of Temah;
54 Nesia àti Hatifa.
the children of Neziah, the children of Hatipha.
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
The children of Solomon's servants: the children of Sotai, the children of Hassophereth, the children of Peruda;
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
the children of Jaalah, the children of Darkon, the children of Giddel;
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
the children of Shephatiah, the children of Hattil, the children of Pochereth-hazzebaim, the children of Ami.
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
All the Nethinim, and the children of Solomon's servants, were three hundred ninety and two.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
And these were they that went up from Tel-melah, Tel-harsa, Cherub, Addan, and Immer; but they could not tell their fathers' houses, and their seed, whether they were of Israel:
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
the children of Delaiah, the children of Tobiah, the children of Nekoda, six hundred fifty and two.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
And of the children of the priests: the children of Habaiah, the children of Hakkoz, the children of Barzillai, who took a wife of the daughters of Barzillai the Gileadite, and was called after their name.
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
These sought their register, that is, the genealogy, but it was not found; therefore were they deemed polluted and put from the priesthood.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
And the Tirshatha said unto them, that they should not eat of the most holy things, till there stood up a priest with Urim and with Thummim.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
The whole congregation together was forty and two thousand three hundred and threescore,
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
beside their men-servants and their maid-servants, of whom there were seven thousand three hundred thirty and seven; and they had two hundred singing men and singing women.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Their horses were seven hundred thirty and six; their mules, two hundred forty and five;
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
their camels, four hundred thirty and five; their asses, six thousand seven hundred and twenty.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
And some of the heads of fathers' houses, when they came to the house of the LORD which is in Jerusalem, offered willingly for the house of God to set it up in its place;
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
they gave after their ability into the treasury of the work threescore and one thousand darics of gold, and five thousand pounds of silver, and one hundred priests' tunics.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
So the priests, and the Levites, and some of the people, and the singers, and the porters, and the Nethinim, dwelt in their cities, and all Israel in their cities.

< Ezra 2 >