< Ezra 2 >
1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Now these are the children of the province, that went out of the captivity, which Nabuchodonosor king of Babylon had carried away to Babylon, and who returned to Jerusalem and Juda, every man to his city.
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
Who came with Zorobabel, Josue, Nehemia, Saraia, Rahelaia, Mardochai, Belsan, Mesphar, Beguai, Rehum, Baana. The number of the men of the people of Israel:
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
The children of Pharos two thousand one hundred seventy-two.
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
The children of Sephatia, three hundred seventy-two.
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
The children of Area, seven hundred seventy-five.
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
The children of Phahath Moab, of the children of Josue: Joab, two thousand eight hundred twelve.
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
The children of Elam, a thousand two hundred fifty-four.
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
The children of Zethua, nine hundred forty-five.
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
The children of Zachai, seven hundred sixty.
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
The children of Bani, six hundred forty-two.
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
The children of Bebai, six hundred twenty-three.
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
The children of Azgad, a thousand two hundred twenty-two.
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
The children of Adonicam, six hundred sixty-six.
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
The children of Beguai, two thousand fifty-six.
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
The children of Adin, four hundred fifty-four.
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
The children of Ather, who were of Ezechias, ninety-eight.
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
The children of Besai, three hundred and twenty-three.
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
The children of Jora, a hundred and twelve.
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
The children of Hasum, two hundred twenty-three.
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
The children of Gebbar, ninety-five.
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
The children of Bethlehem, a hundred twenty-three.
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
The men of Netupha, fifty-six.
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
The men of Anathoth, a hundred twenty-eight.
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
The children of Azmaveth, forty-two.
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
The children of Cariathiarim, Cephira, and Beroth, seven hundred forty-three.
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
The children of Rama and Gabaa, six hundred twenty-one.
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
The men of Machmas, a hundred twenty-two.
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
The men of Bethel and Hai, two hundred twenty-three.
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
The children of Nebo, fifty-two.
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
The children of Megbis, a hundred fifty-six.
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
The children of the other Elam, a thousand two hundred fifty-four.
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
The children of Harim, three hundred and twenty.
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
The children of Lod, Hadid and One, seven hundred twenty-five.
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
The children of Jericho, three hundred forty-five.
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
The children of Senaa, three thousand six hundred thirty.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
The priests: the children of Jadaia of the house of Josue, nine hundred seventy-three.
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
The children of Emmer, a thousand fifty-two.
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
The children of Pheshur, a thousand two hundred forty-seven.
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
The children of Harim, a thousand and seventeen.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
The Levites: the children of Josue and of Cedmihel, the children of Odovia, seventy-four.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
The singing men: the children of Asaph, a hundred twenty-eight.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
The children of the porters: the children of Sellum, the children of Ater, the children of Telmon, the children of Accub, the children of Hatita, the children of Sobai: in all a hundred thirty-nine.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
The Nathinites: the children of Siha, the children of Hasupha, the children of Tabbaoth,
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
The children of Ceros, the children of Sia, the children of Phadon,
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
The children of Lebana, the children of Hegaba, the children of Accub,
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
The children of Hagab, the children of Semlai, the children of Hanan,
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
The children of Gaddel, the children of Gaher, the children of Raaia,
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
The children of Basin, the children of Necoda, the children of Gazam,
The children of Asa, the children of Phasea, the children of Besee,
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
The children of Asena, the children of Munim, the children of Nephusim,
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
The children of Bacbuc, the children of Hacupha, the children of Harhur,
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
The children of Besluth, the children of Mahida, the children of Harsa,
53 Barkosi, Sisera, Tema,
The children of Bercos, the children of Sisara, the children of Thema,
The children of Nasia, the children of Hatipha,
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
The children of the servants of Solomon, the children of Sotai, the children of Sopheret, the children of Pharuda,
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
The children of Jala, the children of Dercon, the children of Geddel,
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
The children of Saphatia, the children of Hatil, the children of Phochereth, which were of Asebaim, the children of Ami,
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
All the Nathinites, and the children of the servants of Solomon, three hundred ninety-two.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
And these are they that came up from Thelmela, Thelharsa, Cherub, and Adon, and Emer. And they could not shew the house of their fathers and their seed, whether they were of Israel.
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
The children of Dalaia, the children of Tobia, the children of Necoda, six hundred fifty-two.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
And of the children of the priests: the children of Hobia, the children of Accos, the children of Berzellai, who took a wife of the daughters of Berzellai, the Galaadite, and was called by their name:
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
These sought the writing of their genealogy, and found it not, and they were cast out of the priesthood.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
And Athersatha said to them, that they should not eat of the holy of holies, till there arose a priest learned and perfect.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
All the multitudes as one man, were forty-two thousand three hundred and sixty:
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
Besides their menservants, and womenservants, of whom there were seven thousand three hundred and thirty-seven: and among them singing men, and singing women two hundred.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Their horses seven hundred thirty-six, their mules two hundred forty-five,
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Their camels four hundred thirty-five, their asses six thousand seven hundred and twenty.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
And some of the chief of the fathers, when they came to the temple of the Lord, which is in Jerusalem, offered freely to the house of the Lord to build it in its place.
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
According to their ability, they gave towards the expenses of the work, sixty-one thousand solids of gold, five thousand pounds of silver, and a hundred garments for the priests.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
So the priests and the Levites, and some of the people, and the singing men, and the porters, and the Nathinites dwelt in their cities, and all Israel in their cities.