< Ezra 10 >

1 Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
Torej ko je Ezra molil in ko je priznaval, jokal in se metal dol pred Božjo hišo, se je tam k njemu iz Izraela zbrala zelo velika skupnost mož, žena in otrok, kajti ljudstvo je zelo hudo jokalo.
2 Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
Jehiélov sin Šehanjája, eden izmed Elámovih sinov, je odgovoril in Ezru rekel: »Pregrešili smo se zoper svojega Boga in si jemali tuje žene izmed ljudstva dežele, vendar je sedaj v Izraelu upanje glede te stvari.
3 Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
Sedaj torej sklenimo zavezo s svojim Bogom, da odslovimo vse žene in tiste, ki so se rodili od njih, glede na nasvet mojega gospoda in tistih, ki trepetajo ob zapovedi našega Boga. In to naj bo storjeno glede na postavo.
4 Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
Vstani, kajti ta zadeva pripada tebi. Tudi mi bomo s teboj. Bodi odločnega poguma in to naredi.«
5 Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
Potem je Ezra vstal in pripravil vodilne duhovnike, Lévijevce in ves Izrael, da prisežejo, da bodo storili glede na to besedo. In so prisegli.
6 Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
Potem je Ezra vstal izpred Božje hiše in odšel v sobo Eljašíbovega sina Johanána. Ko je prišel tja, ni jedel kruha niti pil vode, kajti žaloval je zaradi prestopka tistih, ki so bili odvedeni proč.
7 Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
Naredili so razglas po vsej Judeji in Jeruzalemu, vsem otrokom iz ujetništva, da naj se skupaj zberejo v Jeruzalemu.
8 Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
In da kdorkoli ne bo hotel priti v treh dneh, glede na nasvet princev in starešin, bo vse njegovo imetje zaseženo in on sam oddvojen od skupnosti tistih, ki so bili odvedeni proč.
9 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
Potem so se v treh dneh vsi možje iz Juda in Benjamina zbrali skupaj v Jeruzalemu. To je bil deveti mesec, na dvanajsti dan meseca, in vse ljudstvo je sedelo na ulici Božje hiše in trepetalo zaradi te zadeve in zaradi velikega dežja.
10 Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
Duhovnik Ezra je vstal in jim rekel: »Pregrešili ste se in si vzeli tuje ženske, da povečate Izraelov prekršek.
11 Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
Zdaj torej naredite priznanje Gospodu, Bogu svojih očetov in storite njegovo voljo in se ločite od ljudstva dežele in od tujih žena.«
12 Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
Potem je vsa skupnost odgovorila in z močnim glasom rekla: »Kakor si rekel, tako moramo storiti.«
13 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
Toda ljudstva je mnogo in to je čas obilnega dežja in mi nismo zmožni stati zunaj niti to ni delo enega dne ali dveh, kajti mnogo nas je, ki smo se pregrešili v tej stvari.
14 Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
Naj sedaj naši voditelji vse skupnosti vstanejo in naj vsi, ki so si v naših mestih vzeli tuje žene, pridejo ob določenih časih in z njimi starešine iz vsakega mesta in njihovi sodniki, dokler kruti bes našega Boga zaradi te zadeve ne bo odvrnjen od nas.
15 Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
Samo Asaélov sin Jonatan in Tikvájev sin Jahzejá sta bila zaposlena okoli te zadeve. Mešulám in Lévijevec Šabetáj pa sta jima pomagala.
16 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
Otroci ujetništva so storili tako. Duhovnik Ezra z nekaterimi vodilnimi očeti, po hiši njihovih očetov in vsi izmed njih po njihovih imenih, so se oddvojili in se usedli na prvi dan desetega meseca, da preiščejo zadevo.
17 ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
In z vsemi možmi, ki so si vzeli tuje žene, so zaključili do prvega dne prvega meseca.
18 Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
Med sinovi duhovnikov so bili najdeni, da so si vzeli tuje žene, namreč od Ješúvovih sinov Jocadákov sin in njegovi bratje Maasejá, Eliézer, Jaríb in Gedaljá.
19 Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
Dali so svoje roke, da bodo odslovili svoje žene in ker so bili krivi, so darovali ovna od tropa za svoj prekršek.
20 Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
Izmed Imêrjevih sinov Hananí in Zebadjá.
21 Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
Izmed Harímovih sinov Maasejá, Elija, Šemajá, Jehiél in Uzíjah.
22 Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
Izmed Pašhúrjevih sinov Eljoenáj, Maasejá, Jišmaél, Netanél, Jozabád in Elasá.
23 Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
Tudi izmed Lévijevcev: Jozabád, Šimí, Kelajá (isti je Kelitá), Petahjá, Juda in Eliézer.
24 Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
Tudi izmed pevcev Eljašíb in izmed vratarjev Šalúm, Telem in Urí.
25 Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
Poleg tega od Izraela izmed Paróševih sinov Ramjá, Malkijá, Mijamín, Eleazar, Malkijá in Benajá.
26 Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
Izmed Elámovih sinov Matanjá, Zeharjá, Jehiél, Abdí, Jeremót in Elijá.
27 Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
Izmed Zatújevih sinov Eljoenáj, Eljašíb, Matanjá, Jeremót, Zabád in Azizá.
28 Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
Tudi izmed Bebájevih sinov Johanán, Hananjá, Zabáj in Atláj.
29 Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
Izmed Baníjevih sinov Mešulám, Malúh, Adajá, Jašúb, Šeál in Ramót.
30 Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
Izmed Pahat Moábovih sinov Adná, Kelál, Benajá, Maasejá, Matanjá, Becalél, Binúj in Manáse.
31 Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
In izmed Harímovih sinov Eliézer, Jišijá, Malkijá, Šemajá, Šimón,
32 Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
Benjamin, Malúh in Šemarjá.
33 Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
Izmed Hašúmovih sinov Matenáj, Matatá, Zabád, Elifélet, Jeremáj, Manáse in Šimí.
34 Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
Izmed Baníjevih sinov Maadáj, Amrám, Uél,
35 Benaiah, Bediah, Keluhi
Benajá, Bedjá, Keluhí,
36 Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
Vanjá, Meremót, Eljašíb,
37 Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
Matanjá, Matenáj, Jaasáj,
38 Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
Baní, Binúj, Šimí,
39 Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
Šelemjá, Natána, Adajá,
40 Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
Mahnadbáj, Šašáj, Šaráj,
41 Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
Azarél, Šelemjá, Šemarjá,
42 Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
Šalúm, Amarjá in Jožef.
43 Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
Izmed Nebójevih sinov Jeiél, Matitjá, Zabád, Zebiná, Jadáj, Joél in Benajá.
44 Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.
Vsi ti so si vzeli tuje žene in nekateri izmed njih so imeli žene, s katerimi so imeli otroke.

< Ezra 10 >