< Ezra 10 >

1 Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
A gdy Ezdrasz modlił się i wyznawał [grzechy] z płaczem, klęcząc przed domem Bożym, zebrał się wokół niego bardzo wielki tłum mężczyzn, kobiet i dzieci z Izraela, a lud bardzo gorzko płakał.
2 Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
Wtedy Szekaniasz, syn Jechiela z synów Elama, powiedział do Ezdrasza: My zgrzeszyliśmy przeciwko naszemu Bogu, bo pojęliśmy obce żony z ludu tej ziemi. Ale jest jeszcze nadzieja dla Izraela w tej sprawie.
3 Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
Teraz więc zawrzyjmy przymierze z naszym Bogiem – odprawmy wszystkie żony i [dzieci] z nich urodzone, według rady PANA i tych, którzy drżą przed przykazaniem naszego Boga. Niech to się stanie według prawa.
4 Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
Wstań, bo do ciebie należy ta sprawa, a my [będziemy] z tobą. Wzmocnij się i działaj.
5 Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
Wtedy Ezdrasz wstał i zaprzysiągł przedniejszych kapłanów, Lewitów i całego Izraela, by postąpili według tego słowa. I przysięgli.
6 Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
Potem Ezdrasz opuścił dom Boży i udał się do komnaty Jochanana, syna Eliasziba. Kiedy tam wszedł, nie jadł chleba ani nie pił wody, gdyż smucił się z powodu przestępstwa tych, którzy powrócili z niewoli.
7 Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
Następnie ogłoszono w Judzie i Jerozolimie wszystkim, którzy powrócili z niewoli, że mają zgromadzić się w Jerozolimie.
8 Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
A ktokolwiek nie przyjdzie w ciągu trzech dni, według postanowienia naczelników i starszych, ten zostanie pozbawiony całego mienia, a sam będzie wykluczony ze zgromadzenia tych, którzy powrócili z niewoli.
9 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
Zgromadzili się więc wszyscy mężczyźni z Judy i Beniamina w Jerozolimie w ciągu trzech dni. Było to w dwudziestym [dniu] dziewiątego miesiąca. A cały lud siedział na placu przed domem Bożym, drżąc z powodu tej sprawy i z powodu deszczu.
10 Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
Wtedy Ezdrasz powstał i powiedział do nich: Wy zgrzeszyliście, bo pojęliście obce żony, a przez to pomnożyliście grzech Izraela.
11 Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
Teraz więc wyznajcie [grzech] PANU, Bogu waszych ojców, i spełnijcie jego wolę. Odłączcie się od ludu tej ziemi i od obcych żon.
12 Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
A całe zgromadzenie odpowiedziało donośnym głosem: Jak nam powiedziałeś, tak uczynimy.
13 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
Ale lud jest liczny i pora deszczowa i nie możemy stać na dworze. Ponadto ta sprawa nie jest na jeden dzień ani dwa, gdyż jest nas wielu, którzy dopuściliśmy się tego przestępstwa.
14 Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
Prosimy więc, niech nasi przywódcy będą postawieni przed całym zgromadzeniem i wszyscy, którzy w naszych miastach pojęli obce żony, niech przyjdą o wyznaczonej porze – z nimi starsi z każdego miasta oraz ich sędziowie, abyśmy w ten sposób odwrócili od nas zapalczywość gniewu naszego Boga z powodu tej sprawy.
15 Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
Tylko Jonatan, syn Asahela, i Jachzejasz, syn Tikwy, zajmowali się tym. I Meszullam i Szabbetaj, Lewici, pomagali im.
16 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
Tak więc postąpili ci, którzy powrócili z niewoli. I kapłan Ezdrasz wraz z naczelnikami poszczególnych rodów, wszyscy zostali [odłączeni] imiennie. I zasiedli w pierwszym dniu dziesiątego miesiąca, aby zbadać tę sprawę.
17 ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
I do pierwszego dnia pierwszego miesiąca zakończyli sprawę ze wszystkimi mężczyznami, którzy pojęli obce żony.
18 Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
Wśród synów kapłanów znaleźli się tacy, którzy pojęli obce żony: spośród synów Jeszuy, syna Jocadaka i jego braci: Maasejasz, Eliezer, Jarib i Gedaliasz.
19 Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
Ci zaręczyli, że odprawią swoje żony, a jako że byli winni – [każdy złoży] barana ze stada za swój występek.
20 Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
A z synów Immera: Chanani i Zebadiasz;
21 Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
A z synów Charima: Maasejasz, Eliasz, Szemajasz, Jechiel i Uzjasz;
22 Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
A z synów Paszchura: Elioenaj, Maasejasz, Izmael, Netaneel, Jozabad i Elasa;
23 Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
A z Lewitów: Jozabad, Szimei, Kelajasz, to jest Kelita, Petachiasz, Juda i Eliezer;
24 Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
A ze śpiewaków: Eliaszib; a z odźwiernych: Szallum, Telem i Uri;
25 Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
A z Izraela, z synów Parosza: Ramiasz, Jezjasz, Malkiasz, Miamin, Eelazar, Malkijasz i Benajasz;
26 Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
A z synów Elama: Mattaniasz, Zachariasz, Jechiel, Abdi, Jeremot i Eliasz;
27 Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
A z synów Zattua: Elioenaj, Eliaszib, Mattaniasz, Jeremot, Zabad i Aziza;
28 Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
A z synów Bebaja: Jehochanan, Chananiasz, Zabbaj i Atlaj;
29 Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
A z synów Baniego: Meszullam, Malluk, Adajasz, Jaszub, Szeal i Jeremot;
30 Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
A z synów Pachat-Moaba: Adna, Kelal, Benajasz, Maasejasz, Mattaniasz, Besaleel, Binnuj i Manasses;
31 Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
A z synów Charima: Eliezer, Jeszsziasz, Malkiasz, Szemajasz, Szymon;
32 Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
Beniamin, Maluk i Szemariasz;
33 Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
Z synów Chaszuma: Mattenaj, Mattatta, Zabad, Elifelet, Jeremaj, Manasses i Szimei;
34 Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
Z synów Baniego: Maadaj, Amram, Uel;
35 Benaiah, Bediah, Keluhi
Benajasz, Bedejasz, Cheluhu;
36 Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
Waniasz, Meremot, Eliaszib;
37 Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
Mattaniasz, Mattenaj, Jaasaj;
38 Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
I Bani, Binnuj, Szimei;
39 Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
I Szelemiasz, Natan, Adajasz;
40 Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
Machnadbaj, Szaszaj, Szaraj;
41 Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
Asarel, Szelemiasz, Szemariasz;
42 Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
Szallum, Amariasz i Józef;
43 Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
Z synów Nebo: Jejel, Mattitiasz, Zabad, Zebina, Jaddaj, Joel i Benajasz.
44 Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.
Ci wszyscy pojęli obce żony. A były wśród nich żony, które urodziły [im] dzieci.

< Ezra 10 >