< Ezra 10 >

1 Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
Pendant qu'Esdras priait et se confessait, pleurant et se prosternant devant la maison de Dieu, une très grande assemblée d'hommes, de femmes et d'enfants s'assembla auprès de lui de la part d'Israël, car le peuple pleurait très amèrement.
2 Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
Shecania, fils de Jehiel, l'un des fils d'Élam, répondit à Esdras: « Nous avons péché contre notre Dieu et nous avons épousé des femmes étrangères parmi les peuples du pays. Mais maintenant, il y a de l'espoir pour Israël à ce sujet.
3 Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
Maintenant, faisons donc alliance avec notre Dieu pour répudier toutes les femmes et celles qui sont nées d'elles, selon le conseil de mon seigneur et de ceux qui tremblent devant l'ordre de notre Dieu. Qu'il en soit fait selon la loi.
4 Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
Lève-toi, car l'affaire est entre tes mains et nous sommes avec toi. Prends courage, et fais-le. »
5 Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
Alors Esdras se leva et fit jurer aux chefs des prêtres, aux lévites et à tout Israël qu'ils feraient selon cette parole. Et ils jurèrent.
6 Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
Esdras se leva de devant la maison de Dieu et entra dans la chambre de Jehohanan, fils d'Eliashib. Quand il y arriva, il ne mangea pas de pain et ne but pas d'eau, car il était en deuil à cause de la faute des exilés.
7 Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
On publia dans tout Juda et Jérusalem une annonce à tous les enfants de la captivité, pour qu'ils se rassemblent à Jérusalem,
8 Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
et que quiconque ne viendrait pas dans les trois jours, selon le conseil des princes et des anciens, perdrait tous ses biens, et serait lui-même séparé de l'assemblée des captifs.
9 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
Et tous les hommes de Juda et de Benjamin se rassemblèrent à Jérusalem dans les trois jours. C'était le neuvième mois, le vingtième jour du mois; et tout le peuple était assis sur la place large, devant la maison de Dieu, tremblant à cause de cette affaire et à cause de la grande pluie.
10 Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
Le prêtre Esdras se leva et leur dit: « Vous avez commis une faute, vous avez épousé des femmes étrangères, et vous avez aggravé la culpabilité d'Israël.
11 Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
Maintenant, confessez-vous à Yahvé, le Dieu de vos pères, et faites sa volonté. Séparez-vous des peuples du pays et des femmes étrangères. »
12 Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
Alors toute l'assemblée répondit d'une voix forte: « Nous devons faire ce que tu as dit à notre sujet.
13 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
Mais le peuple est nombreux, et c'est un temps de grande pluie, et nous ne pouvons pas rester dehors. Ce n'est pas l'œuvre d'un jour ou deux, car nous avons beaucoup transgressé dans cette affaire.
14 Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
Maintenant, que nos chefs soient désignés pour toute l'assemblée, et que tous ceux qui sont dans nos villes et qui ont épousé des femmes étrangères viennent à des heures fixes, et avec eux les anciens de chaque ville et ses juges, jusqu'à ce que l'ardente colère de notre Dieu se détourne de nous, jusqu'à ce que cette affaire soit résolue. »
15 Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
Seuls Jonathan, fils d'Asahel, et Jahzeia, fils de Tikva, s'y opposèrent; Meshullam et Shabbethai, le Lévite, les aidèrent.
16 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
Les enfants de la captivité firent ainsi. Le prêtre Esdras, avec certains chefs de famille, selon les maisons de leurs pères, et tous selon leurs noms, furent mis à part; ils s'assirent le premier jour du dixième mois pour examiner la question.
17 ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
Ils en finirent avec tous les hommes qui avaient épousé des femmes étrangères, le premier jour du premier mois.
18 Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
Parmi les fils des prêtres, il s'en trouvait qui avaient épousé des femmes étrangères: des fils de Jeshua, fils de Jozadak, et de ses frères: Maaséja, Éliézer, Jarib et Guedalia.
19 Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
Ils donnèrent leur main pour répudier leurs femmes; et, étant coupables, ils offrirent un bélier du troupeau pour leur faute.
20 Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
Des fils d'Immer: Hanani et Zebadiah.
21 Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
Des fils de Harim: Maaséja, Élie, Shemahia, Jehiel et Ozias.
22 Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
Des fils de Pashhur: Elioénaï, Maaséja, Ismaël, Nethanel, Jozabad et Elasah.
23 Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
Parmi les Lévites: Jozabad, Shimei, Kelaiah (appelé aussi Kelita), Pethahiah, Juda et Eliezer.
24 Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
Des chanteurs: Eliashib. Des gardiens: Shallum, Telem, et Uri.
25 Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
D'Israël: Des fils de Parosh: Ramia, Izzia, Malkija, Mijamin, Eléazar, Malkija et Benaja.
26 Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
Des fils d'Elam: Mattania, Zacharie, Jehiel, Abdi, Jeremoth et Élie.
27 Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
Des fils de Zattu: Eliœnai, Eliashib, Mattaniah, Jeremoth, Zabad et Aziza.
28 Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
Des fils de Bébaï: Jehohanan, Hanania, Zabbai et Athlaï.
29 Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
Des fils de Bani: Meshullam, Malluch, Adaiah, Jashub, Sheal et Jeremoth.
30 Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
Des fils de Pahathmoab: Adna, Chelal, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Bezalel, Binnui et Manassé.
31 Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
Des fils de Harim: Éliézer, Ischija, Malkija, Schemaeja, Shimeon,
32 Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
Benjamin, Malluch et Shemaria.
33 Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
Des fils de Hashum: Mattenai, Mattattah, Zabad, Eliphelet, Jeremai, Manasseh et Shimei.
34 Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
Des fils de Bani: Maadaï, Amram, Uel,
35 Benaiah, Bediah, Keluhi
Benaja, Bedeja, Cheluhi,
36 Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
Vania, Meremoth, Eliashib,
37 Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
Mattania, Mattenai, Jaasu,
38 Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
Bani, Binnui, Shimei,
39 Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
Shelemiah, Nathan, Adaiah,
40 Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
Machnadebai, Shashai, Sharai,
41 Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
Azarel, Shelemiah, Shemariah,
42 Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
Shallum, Amaria, et Joseph.
43 Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
Des fils de Nebo: Jeiel, Mattithiah, Zabad, Zebina, Iddo, Joël et Benaja.
44 Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.
Tous ceux-là avaient pris des femmes étrangères. Certains d'entre eux avaient des femmes dont ils avaient des enfants.

< Ezra 10 >