< Ezra 10 >
1 Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
Kuin Esra näin rukoili ja tunnusti, itki ja makasi Jumalan huoneen edessä, kokoontui suuri joukko Israelista hänen tykönsä, miehistä, vaimoista ja lapsista, ja kansa itki sangen kovin.
2 Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
Ja Sekania Jehielin poika, Elamin lapsista, vastasi Esraa ja sanoi: me olemme rikkoneet Jumalaamme vastaan, että me olemme ottaneet muukalaiset vaimot maan kansoista; mutta vielä on toivo sen vuoksi Israelissa.
3 Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
Niin tehkäämme nyt liitto meidän Jumalamme kanssa ajaaksemme kaikki vaimot pois ja ne, jotka heistä syntyneet ovat, Herran neuvon jälkeen ja niiden, jotka pelkäävät meidän Jumalamme käskyä; ja tapahtukoon lain jälkeen.
4 Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
Niin nouse, sillä sinun se tulee, me olemme sinun kanssas; ole hyvässä turvassa ja tee niin.
5 Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
Silloin nousi Esra ja vannotti ylimmäiset papit ja Leviläiset, ja koko Israelin, tekemään tämän sanan jälkeen; ja he vannoivat.
6 Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
Ja Esra nousi Jumalan huoneen edestä ja meni Johananin Eliasibin pojan kammioon; ja kuin hän sinne tuli, ei hän syönyt leipää eikä juonut vettä; sillä hän murehti heidän rikostensa tähden, jotka olivat olleet vankeudessa.
7 Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
Ja he kuuluttivat Juudassa ja Jerusalemissa kaikille lapsille, jotka vankina olivat olleet, tulemaan kokoon Jerusalemiin.
8 Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
Ja joka ei kolmena päivänä tullut päämiesten ja vanhimpain neuvon jälkeen, niin kaikki hänen tavaransa piti kirottu oleman, ja hän itse piti eroitettaman niiden joukosta, jotka vankina olivat olleet.
9 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
Niin tulivat kaikki Juudan ja Benjaminin miehet Jerusalemiin kolmessa päivässä kokoon, se on, kahdentenakymmenentenä päivänä yhdeksännessä kuussa; ja kaikki kansa istui kadulla Herran huoneen edessä, ja värisivät siitä asiasta ja sateen tähden.
10 Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
Ja pappi Esra nousi ja sanoi heille: te olette rikkoneet, naidessanne muukalaisia vaimoja, ja lisänneet Israelin synnit.
11 Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
Niin tunnustakaat nyt se Herralle isäinne Jumalalle, ja tehkäät sitä, kuin hänelle kelpaa, ja eroittakaat teitänne maan kansoista ja muukalaisista vaimoista.
12 Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
Niin vastasi koko seurakunta ja sanoi korkialla äänellä: se pitää niin tapahtuman, kuin sinä meille olet sanonut.
13 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
Mutta kansaa on paljo, ja on sadeilma, ja ei voi ulkona seisoa, eikä tämä ole yhden eli kahden päivän työ; sillä meitä on paljo, jotka olemme siinä asiassa sangen suuresti syntiä tehneet.
14 Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
Anna meidän päämiestemme koko seurakunnassa toimittaa, että kaikki, jotka meidän kaupungeissamme ovat naineet muukalaisia vaimoja, tulevat tänne määrättynä päivänä, jokaisen kaupungin vanhimpain ja tuomarein kanssa, siihenasti kuin meidän Jumalamme viha kääntyy meistä tämän syyn tähden.
15 Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
Niin astuivat ainoastaan Jonatan Asahelin poika ja Jahasia Tikvan poika tähän toimitukseen; ja Metullam ja Sabtai, Leviläiset, auttivat heitä.
16 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
Ja vankeuden lapset tekivät niin; ja eroitettiin Esra pappi ja päämiehet heidän isäinsä sukukuntain seassa, ja kaikki, kuin nimitetyt ovat, ja he istuivat ensimäisenä päivänä kymmenennessä kuukaudessa tutkistelemaan sitä.
17 ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
Ja he toimittivat sen kaikkein miesten kanssa, joilla olivat muukalaiset vaimot, ensimäiseen päivään asti ensimäisessä kuussa.
18 Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
Ja pappein poikain seasta löydettiin, jotka olivat ottaneet muukalaisia vaimoja: Jesuan Jotsadakin pojan lasten seassa, ja hänen veljeinsä Maeseja, Elieser, Jarib ja Gedalia.
19 Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
Ja he antoivat kätensä, ajamaan vaimonsa ulos ja antamaan jäärän rikosuhriksensa rikoksensa edestä;
20 Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
Immerin lasten seassa: Hanani ja Sebadia;
21 Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
Harimin lasten seassa: Maeseja, Elia, Semaja, Jehiel ja Ussia;
22 Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
Pashurin lasten seassa: Eljoenai, Maaseja, Ismael, Netaneel, Josabad ja Eleasa;
23 Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
Leviläisistä: Josabad, Simei ja Kelaja, se on Kelita, Petakia, Juuda ja Elieser;
24 Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
Veisaajain seassa: Eljasib; ovenvartijain seassa: Sallum, Telem ja Uri.
25 Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
Israelista Paroksen lasten seassa: Ramia, Jesia, Malkia, Mejamin, Eleasar, Malkia ja Benaja;
26 Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
Elamin lasten seassa: Mattania, Sakaria, Jehiel, Abdi, Jeremot ja Elia;
27 Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
Sattun lasten seassa: Eljoenai, Eljasib, Mattania, Jeremot, Sabad ja Asisa;
28 Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
Bebain lasten seassa: Johanan, Hanania, Sebai ja Atlai;
29 Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
Banin lasten seassa: Mesullam, Malluk, Adaja, Jasub, Seal ja Jeramoth;
30 Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
Pahatmoabin lasten seassa: Adna ja Kelal, Benaja, Maeseja, Mattania, Betsaleel, Binnui ja Manasse;
31 Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
Harimin lasten seassa: Elieser, Jesia, Malkia, Semaja, Simeon,
32 Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
Benjamin, Malluk ja Semaria;
33 Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
Hasumin lasten seassa: Mattenai, Mattatta, Sabad, Eliphelet, Jeremai, Manasse ja Simei;
34 Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
Banin lasten seassa: Maadai, Amram, Uel,
35 Benaiah, Bediah, Keluhi
Benaja, Bedeja, Keluhi,
36 Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
Vania, Meremot, Eljasib
37 Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
Mattania, Mattenai, Jaasav,
38 Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
Bani, Binnui, Simei,
39 Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
Selemia, Natan, Adaja,
40 Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
Maknadbai, Sasai, Sarai,
41 Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
Asareel, Selemia, Semaria,
42 Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
Sallum, Amaria ja Joseph;
43 Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
Nebon lasten seassa: Jejel, Mattitia, Sabad, Sebina, Jaddai, Joel ja Benaja.
44 Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.
Nämät kaikki olivat ottaneet muukalaisia vaimoja, ja olivat monikahdat niistä vaimoista, joiden kanssa he olivat siittäneet lapsia.