< Ezra 10 >
1 Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
And just as was praying Ezra and just as was confessing he weeping and prostrating himself before [the] house of God they gathered to him from Israel a company great very men and women and children for they wept the people great weeping.
2 Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
And he answered Shecaniah [the] son of Jehiel one of [the] descendants of (Elam *Q(K)*) and he said to Ezra we we have acted unfaithfully against God our and we have married women foreign from [the] peoples of the land and now there [is] hope for Israel on this.
3 Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
And therefore let us make a covenant to God our to send out all wives and those born from them by [the] counsel of [the] Lord and the [people] trembling at [the] commandment of God our and according to the law let it be done.
4 Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
Arise for [is] on you the matter and we [will be] with you be strong and act.
5 Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
And he arose Ezra and he made to swear an oath [the] leaders of the priests the Levites and all Israel to do according to the manner this and they swore [the] oath.
6 Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
And he arose Ezra from to before [the] house of God and he went into [the] room of Jehohanan [the] son of Eliashib and he went there food not he ate and water not he drank for [he was] mourning on [the] unfaithfulness of the exile[s].
7 Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
And they caused to pass a proclamation in Judah and Jerusalem to all [the] children of the exile to assemble Jerusalem.
8 Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
And every [one] who not he will come to [the] three the days according to [the] counsel of the leaders and the elders it will be forfeited all property his and he he will be separated from [the] assembly of the exile[s].
9 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
And they assembled all [the] people of Judah and Benjamin - Jerusalem to [the] three the days it [was the] month ninth on [day] twenty in the month and they sat all the people in [the] open place of [the] house of God trembling on the matter and from the rains.
10 Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
And he arose Ezra the priest and he said to them you you have acted unfaithfully and you have married women foreign to add to [the] guilt of Israel.
11 Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
And therefore give praise to Yahweh [the] God of ancestors your and do will his and separate yourselves from [the] peoples of the land and from the women foreign.
12 Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
And they answered all the assembly and they said a voice great so (according to word your *Q(K)*) on us to do.
13 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
But the people [is] numerous and the time [is] rains and there not [is] ability to stand on the outside and the business not [belongs] to a day one and not to two for we have increased to transgress in the matter this.
14 Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
Let them stand please leaders our for all the assembly and every [one] - who [is] in cities our who he has married women foreign let him come to times appointed and with them [the] elders of a city and a city and judges its until turn back [the] burning of [the] anger of God our from us until to the matter this.
15 Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
Only Jonathan [the] son of Asahel and Jahzeiah [the] son of Tikvah they stood on this and Meshullam and Shabbethai the Levite[s] they supported them.
16 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
And they did thus [the] children of the exile and they separated themselves Ezra the priest men [the] leaders of the fathers for [the] house of ancestors their and all of them by names and they sat down on day one of the month tenth to investigate the matter.
17 ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
And they finished with everything [the] men who they had married women foreign until day one of the month first.
18 Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
And it was found some of [the] sons of the priests who they had married women foreign some of [the] sons of Jeshua [the] son of Jozadak and brothers his Maaseiah and Eliezer and Jarib and Gedaliah.
19 Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
And they gave hand their to send out wives their and [being] guilty a ram of [the] flock on guilt their.
20 Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
And of [the] sons of Immer Hanani and Zebadiah.
21 Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
And of [the] sons of Harim Maaseiah and Elijah and Shemaiah and Jehiel and Uzziah.
22 Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
And of [the] sons of Pashhur Elioenai Maaseiah Ishmael Nethanel Jozabad and Eleasah.
23 Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
And of the Levites Jozabad and Shimei and Kelaiah that [is] Kelita Pethahiah Judah and Eliezer.
24 Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
And of the singers Eliashib and of the gatekeepers Shallum and Telem and Uri.
25 Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
And of Israel of [the] sons of Parosh Ramiah and Izziah and Malkijah and Mijamin and Eleazar and Malkijah and Benaiah.
26 Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
And of [the] sons of Elam Mattaniah Zechariah and Jehiel and Abdi and Jeremoth and Elijah.
27 Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
And of [the] sons of Zattu Elioenai Eliashib Mattaniah and Jeremoth and Zabad and Aziza.
28 Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
And of [the] sons of Bebai Jehohanan Hananiah Zabbai Athlai.
29 Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
And of [the] sons of Bani Meshullam Malluch and Adaiah Jashub and Sheal (and Ramoth. *Q(K)*)
30 Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
And of [the] sons of Pahath-Moab Adna and Kelal Benaiah Maaseiah Mattaniah Bezalel and Binnui and Manasseh.
31 Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
And [the] sons of Harim Eliezer Isshiah Malkijah Shemaiah Simeon.
32 Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
Benjamin Malluch Shemariah.
33 Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
Of [the] sons of Hashum Mattenai Mattattah Zabad Eliphelet Jeremai Manasseh Shimei.
34 Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
Of [the] sons of Bani Maadai Amram and Uel.
35 Benaiah, Bediah, Keluhi
Benaiah Bedeiah (Keluhi. *Q(K)*)
36 Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
Vaniah Meremoth Eliashib.
37 Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
Mattaniah Mattenai (and Jaasai. *Q(K)*)
38 Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
And Bani and Binnui Shimei.
39 Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
And Shelemiah and Nathan and Adaiah.
40 Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
Machnadebai Shashai Sharai.
41 Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
Azarel and Shelemiah Shemariah.
42 Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
Shallum Amariah Joseph.
43 Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
Of [the] sons of Nebo Jeiel Mattithiah Zabad Zebina (Jaddai *Q(K)*) and Joel Benaiah.
44 Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.
All these (they had taken *Q(K)*) women foreign and there [were] some of them wives and they [masc] had made children.