< Ezra 1 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi, ọba Persia, kí a lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí Jeremiah sọ ṣẹ, Olúwa ru ọkàn Kirusi ọba Persia sókè láti ṣe ìkéde jákèjádò gbogbo agbègbè ìjọba rẹ̀, kí ó sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ pé,
Agora, no primeiro ano de Ciro, rei da Pérsia, que a palavra de Javé pela boca de Jeremias poderia ser cumprida, Javé despertou o espírito de Ciro, rei da Pérsia, para que ele fizesse uma proclamação por todo o seu reino, e a colocasse também por escrito, dizendo,
2 “Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia wí pé: “‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mi ní gbogbo ìjọba ayé. Ó sì ti yàn mí láti kọ́ tẹmpili Olúwa fún un ní Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda.
“Ciro, rei da Pérsia, diz: 'Javé, o Deus do céu, me deu todos os reinos da terra; e ordenou-me que lhe construísse uma casa em Jerusalém, que está em Judá.
3 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín—kí Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda, láti kọ́ tẹmpili Olúwa Ọlọ́run Israẹli, Ọlọ́run tí ó wà ní Jerusalẹmu.
Quem quer que esteja entre vós de todo seu povo, que seu Deus esteja com ele, e o deixe subir a Jerusalém, que está em Judá, e construir a casa de Javé, o Deus de Israel (ele é Deus), que está em Jerusalém.
4 Kí àwọn ènìyàn ní ibikíbi tí ẹni náà bá ń gbé kí ó fi fàdákà àti wúrà pẹ̀lú ohun tí ó dára àti ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú ọrẹ àtinúwá ràn án lọ́wọ́ fún tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu.’”
Quem ficar, em qualquer lugar onde ele viva, que os homens de seu lugar o ajudem com prata, com ouro, com bens e com animais, além da oferta gratuita pela casa de Deus que está em Jerusalém'”.
5 Nígbà náà àwọn olórí ìdílé Juda àti Benjamini àti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi—olúkúlùkù ẹni tí Ọlọ́run ti fọwọ́ tọ́ ọkàn rẹ̀—múra láti gòkè lọ láti kọ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu.
Então os chefes de família dos pais de Judá e Benjamim, os sacerdotes e os levitas, todos cujo espírito Deus tinha agitado para subir, levantaram-se para construir a casa de Iavé, que está em Jerusalém.
6 Gbogbo àwọn aládùúgbò wọn ràn wọ́n lọ́wọ́ pẹ̀lú ohun èlò ti fàdákà àti wúrà, pẹ̀lú onírúurú ohun ìní àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn iyebíye, ní àfikún si gbogbo àwọn ọrẹ àtinúwá.
Todos aqueles que estavam ao seu redor fortaleceram suas mãos com vasos de prata, com ouro, com mercadorias, com animais e com coisas preciosas, além de tudo o que foi oferecido de bom grado.
7 Ní àfikún, ọba Kirusi mú àwọn ohun èlò tí ó jẹ́ ti ilé Olúwa jáde wá, tí Nebukadnessari ti kó lọ láti Jerusalẹmu tí ó sì ti kó sí ilé òrìṣà rẹ̀.
Também o rei Ciro trouxe os vasos da casa de Iavé, que Nabucodonosor tinha trazido de Jerusalém, e tinha colocado na casa de seus deuses;
8 Kirusi ọba Persia pàṣẹ fún Mitredati olùṣọ́ ilé ìṣúra láti kó wọn jáde, ó sì kà wọ́n fún Ṣeṣbassari ìjòyè Juda.
até mesmo aqueles, Ciro, rei da Pérsia, trazidos pela mão de Mitredath, o tesoureiro, e os contou para Sesbazar, o príncipe de Judá.
9 Èyí ni iye wọn. Ọgbọ̀n àwo wúrà 30 Ẹgbẹ̀rún àwo fàdákà 1,000 Àwo ìrúbọ fàdákà mọ́kàndínlọ́gbọ̀n 29
Este é o número deles: trinta bandejas de ouro, mil bandejas de prata, vinte e nove facas,
10 Ọgbọ̀n àdému wúrà 30 Irinwó ó lé mẹ́wàá oríṣìí àdému fàdákà mìíràn 410 Ẹgbẹ̀rún kan àwọn ohun èlò mìíràn 1,000
trinta taças de ouro, quatrocentos e dez taças de prata de um segundo tipo, e mil outros recipientes.
11 Gbogbo ohun èlò wúrà àti ti fàdákà ní àpapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ó lé irinwó. Ṣeṣbassari kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí wá pẹ̀lú àwọn ìgbèkùn tí ó gòkè wá láti Babeli sí Jerusalẹmu.
Todos os vasos de ouro e de prata eram cinco mil e quatrocentos. Sheshbazzar trouxe todos eles quando os cativos foram trazidos da Babilônia para Jerusalém.

< Ezra 1 >