< Ezra 1 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi, ọba Persia, kí a lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí Jeremiah sọ ṣẹ, Olúwa ru ọkàn Kirusi ọba Persia sókè láti ṣe ìkéde jákèjádò gbogbo agbègbè ìjọba rẹ̀, kí ó sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ pé,
Kwathi ngomnyaka wokuqala kaKoresi inkosi yePerisiya, ekugcwalisekeni kwelizwi leNkosi ngomlomo kaJeremiya, iNkosi yavusa umoya kaKoresi inkosi yePerisiya ukuthi edlulise isimemezelo embusweni wakhe wonke, njalo langombhalo, esithi:
2 “Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia wí pé: “‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mi ní gbogbo ìjọba ayé. Ó sì ti yàn mí láti kọ́ tẹmpili Olúwa fún un ní Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda.
Utsho njalo uKoresi inkosi yePerisiya: INkosi, uNkulunkulu wamazulu, inginikile yonke imibuso yomhlaba; layo ingilayile ukuyakhela indlu eJerusalema ekoJuda.
3 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín—kí Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda, láti kọ́ tẹmpili Olúwa Ọlọ́run Israẹli, Ọlọ́run tí ó wà ní Jerusalẹmu.
Ngubani ophakathi kwenu kubo bonke abantu bayo? UNkulunkulu wakhe kabe laye, enyukele eJerusalema ekoJuda, akhe indlu yeNkosi, uNkulunkulu kaIsrayeli (unguNkulunkulu) oseJerusalema.
4 Kí àwọn ènìyàn ní ibikíbi tí ẹni náà bá ń gbé kí ó fi fàdákà àti wúrà pẹ̀lú ohun tí ó dára àti ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú ọrẹ àtinúwá ràn án lọ́wọ́ fún tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu.’”
Laloba ngubani oseleyo lakuyiphi yezindawo lapho ahlala njengowezizwe khona, kakuthi abantu bendawo yakibo bamsekele ngesiliva, langegolide, langempahla, langezifuyo, kanye lomnikelo wesihle wendlu kaNkulunkulu eseJerusalema.
5 Nígbà náà àwọn olórí ìdílé Juda àti Benjamini àti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi—olúkúlùkù ẹni tí Ọlọ́run ti fọwọ́ tọ́ ọkàn rẹ̀—múra láti gòkè lọ láti kọ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu.
Kwasekusukuma inhloko zaboyise bakoJuda loBhenjamini, labapristi lamaLevi, laye wonke uNkulunkulu ayevuse umoya wakhe, ukuthi benyukele ukwakha indlu yeNkosi eseJerusalema.
6 Gbogbo àwọn aládùúgbò wọn ràn wọ́n lọ́wọ́ pẹ̀lú ohun èlò ti fàdákà àti wúrà, pẹ̀lú onírúurú ohun ìní àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn iyebíye, ní àfikún si gbogbo àwọn ọrẹ àtinúwá.
Labo bonke ababebaphahlile baqinisa izandla zabo ngezitsha zesiliva, ngegolide, ngempahla, langezifuyo, langezinto eziligugu, ngaphandle kwakho konke okwakunikelwe ngesihle.
7 Ní àfikún, ọba Kirusi mú àwọn ohun èlò tí ó jẹ́ ti ilé Olúwa jáde wá, tí Nebukadnessari ti kó lọ láti Jerusalẹmu tí ó sì ti kó sí ilé òrìṣà rẹ̀.
UKoresi inkosi laye wakhupha izitsha zendlu yeNkosi, uNebhukadinezari ayezikhuphe eJerusalema wazifaka endlini yabonkulunkulu bakhe.
8 Kirusi ọba Persia pàṣẹ fún Mitredati olùṣọ́ ilé ìṣúra láti kó wọn jáde, ó sì kà wọ́n fún Ṣeṣbassari ìjòyè Juda.
UKoresi inkosi yePerisiya wasezikhupha ngesandla sikaMithiredathi umphathisikhwama owazibalela uSheshibazari isiphathamandla sakoJuda.
9 Èyí ni iye wọn. Ọgbọ̀n àwo wúrà 30 Ẹgbẹ̀rún àwo fàdákà 1,000 Àwo ìrúbọ fàdákà mọ́kàndínlọ́gbọ̀n 29
Leli-ke linani lazo: Imiganu yegolide engamatshumi amathathu, imiganu yesiliva eyinkulungwane, izingqamu ezingamatshumi amabili lesificamunwemunye,
10 Ọgbọ̀n àdému wúrà 30 Irinwó ó lé mẹ́wàá oríṣìí àdému fàdákà mìíràn 410 Ẹgbẹ̀rún kan àwọn ohun èlò mìíràn 1,000
inkezo zegolide ezingamatshumi amathathu, ezinye inkezo zesiliva ezingamakhulu amane letshumi, ezinye izitsha eziyinkulungwane.
11 Gbogbo ohun èlò wúrà àti ti fàdákà ní àpapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ó lé irinwó. Ṣeṣbassari kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí wá pẹ̀lú àwọn ìgbèkùn tí ó gòkè wá láti Babeli sí Jerusalẹmu.
Zonke izitsha zegolide lezesiliva zazizinkulungwane ezinhlanu lamakhulu amane. Zonke lezi uSheshibazari wazenyusa lalabo ababenyuswe ekuthunjweni bevela eBhabhiloni besiya eJerusalema.

< Ezra 1 >