< Ezekiel 9 >

1 Mo gbọ́ ti ó kígbe ní ohùn rara pé, “Mú àwọn olùṣọ́ ìlú súnmọ́ itòsí, kí olúkúlùkù wọn mú ohun ìjà olóró lọ́wọ́.”
El a strigat de asemenea în urechile mele cu voce tare, spunând: Fă pe cei care au sarcina asupra cetății să se apropie, fiecare bărbat [cu] arma lui de nimicire în mâna lui.
2 Lójú ẹsẹ̀ ni ọkùnrin mẹ́fà jáde láti ẹnu-ọ̀nà òkè tó kọjú sí ìhà àríwá, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà olóró lọ́wọ́ wọn. Ọkùnrin kan tó wọ aṣọ funfun gbòò wa láàrín wọn, pẹ̀lú ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Gbogbo wọn sì dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ idẹ.
Și, iată, șase bărbați veneau de pe calea porții de sus, care se află spre nord și fiecare bărbat [cu] arma lui de măcel în mână; și un bărbat printre ei [era] îmbrăcat în in, cu un corn cu cerneală la șoldul lui; și ei au intrat și au stat în picioare lângă altarul de aramă.
3 Ògo Ọlọ́run Israẹli sì gòkè kúrò lórí kérúbù, níbi tó wà tẹ́lẹ̀ lọ sí ibi ìloro tẹmpili. Nígbà náà ni Olúwa pe ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun náà tí ó sì ní ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
Și gloria Dumnezeului lui Israel se ridicase de la heruvimul, deasupra căruia era, la pragul casei. Și el a strigat la bărbatul îmbrăcat în in, care [avea] cornul cu cerneală la șold;
4 Ó sì sọ fún un pé, “La àárín ìlú Jerusalẹmu já, kí ìwọ sì fi àmì síwájú orí gbogbo àwọn tó ń kẹ́dùn, tó sì ń sọkún nítorí ohun ìríra tí wọn ń ṣe láàrín rẹ̀.”
Și DOMNUL i-a spus: Du-te prin mijlocul cetății, prin mijlocul Ierusalimului și pune un semn pe frunțile oamenilor care suspină și care strigă din cauza tuturor urâciunilor care sunt făcute în mijlocul lui.
5 Bí mo ṣe ń fetí sí èyí, O tún sọ fún àwọn yòókù pé, “Tẹ̀lé ọkùnrin náà lọ sí àárín ìlú láti pa láì dá sí àti láì ṣàánú rárá.
Și celorlalți le-a spus în auzul meu: Duceți-vă după el prin cetate și loviți, ochiul vostru să nu cruțe, nici să nu aveți milă;
6 Ẹ pa arúgbó àti ọ̀dọ́mọkùnrin, ẹ pa ọlọ́mọge, obìnrin àti ọmọ kéékèèké, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan àwọn tó ní àmì. Ẹ bẹ̀rẹ̀ láti ibi mímọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà tó wà níwájú tẹmpili.
Ucideți fără cruțare pe bătrân [și] pe tânăr, deopotrivă pe fecioare și pe copilași și pe femei; dar nu vă apropiați de vreun om asupra căruia [este] semnul; și începeți la sanctuarul meu. Atunci ei au început de la bătrânii care [erau] înaintea casei.
7 Nígbà náà lo sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ tẹmpili náà di àìmọ́, kí òkú sì kún àgbàlá náà. Ẹ lọ!” Wọ́n jáde síta, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa ènìyàn láàrín ìlú.
Și le-a spus: Spurcați casa și umpleți curțile cu cei uciși; ieșiți. Și au ieșit și au ucis în cetate.
8 Èmi nìkan ló ṣẹ́kù nígbà tí wọ́n lọ pa àwọn ènìyàn, mo dójú mi bolẹ̀, mo kígbe pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli nípa dída ìbínú gbígbóná rẹ sórí Jerusalẹmu?”
Și s-a întâmplat, în timp ce ei îi ucideau iar eu rămăsesem, că am căzut cu fața la pământ și am strigat și am spus: Ah, Doamne DUMNEZEULE! Vei nimici tu toată rămășița lui Israel în turnarea furiei tale asupra Ierusalimului?
9 Ó dá mi lóhùn pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli àti Juda pọ gidigidi; ilé wọn kún fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àti àìṣòótọ́. Wọ́n ní, ‘Olúwa tí kọ ilẹ̀ náà sílẹ̀; Olúwa kò sì rí wa.’
Atunci mi-a spus el: Nelegiuirea casei lui Israel și a lui Iuda [este] peste măsură de mare și țara este plină de sânge și cetatea plină de perversiune, pentru că ei spun: DOMNUL a părăsit pământul și DOMNUL nu vede.
10 Nítorí náà, èmi kò ní wò wọ́n pẹ̀lú àánú, èmi kò sì ní dá wọn sí, ṣùgbọ́n Èmi yóò dá ohun tí wọ́n ti ṣe padà sórí wọn.”
Și cât despre mine de asemenea, ochiul meu nu va cruța, nici nu voi avea milă, [ci] voi întoarce calea lor asupra capului lor.
11 Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, tí ó ní ìwo tàdáwà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ròyìn pé, “Mo ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti pàṣẹ fún mi.”
Și, iată, bărbatul îmbrăcat în in, care [avea] cornul cu cerneală la șold, a vestit despre ce s-a făcut, spunând: Am făcut precum mi-ai poruncit.

< Ezekiel 9 >