< Ezekiel 9 >

1 Mo gbọ́ ti ó kígbe ní ohùn rara pé, “Mú àwọn olùṣọ́ ìlú súnmọ́ itòsí, kí olúkúlùkù wọn mú ohun ìjà olóró lọ́wọ́.”
Un Viņš sauca priekš manām ausīm ar stipru balsi un sacīja: lai nāk tuvu tie pilsētas piemeklētāji, un ikviens ar saviem kaujamiem ieročiem rokā.
2 Lójú ẹsẹ̀ ni ọkùnrin mẹ́fà jáde láti ẹnu-ọ̀nà òkè tó kọjú sí ìhà àríwá, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà olóró lọ́wọ́ wọn. Ọkùnrin kan tó wọ aṣọ funfun gbòò wa láàrín wọn, pẹ̀lú ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Gbogbo wọn sì dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ idẹ.
Un redzi, seši vīri nāca no augšvārtu ceļa, kas pret ziemeli, ikviens savu kaujamo ieroci rokā. Bet viens vīrs bija viņu vidū, audeklī ģērbies, un rakstāmās lietas pie gurniem. Un tie nāca iekšā un nostājās vara altārim sānis.
3 Ògo Ọlọ́run Israẹli sì gòkè kúrò lórí kérúbù, níbi tó wà tẹ́lẹ̀ lọ sí ibi ìloro tẹmpili. Nígbà náà ni Olúwa pe ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun náà tí ó sì ní ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
Un Israēla Dieva godība aizcēlās no tā ķeruba, virs kā tā bija, pie nama sliekšņa, un sauca tam vīram, kas ģērbies audeklī, kam tās rakstāmās lietas bija pie gurniem.
4 Ó sì sọ fún un pé, “La àárín ìlú Jerusalẹmu já, kí ìwọ sì fi àmì síwájú orí gbogbo àwọn tó ń kẹ́dùn, tó sì ń sọkún nítorí ohun ìríra tí wọn ń ṣe láàrín rẹ̀.”
Un Tas Kungs uz viņu sacīja: ej pa pilsētu cauri, pa Jeruzālemi cauri, un apzīmē ar zīmi pie pierēm tos ļaudis, kas nopūšas un vaid par visām šīm negantībām, kas viņu starpā top darītas.
5 Bí mo ṣe ń fetí sí èyí, O tún sọ fún àwọn yòókù pé, “Tẹ̀lé ọkùnrin náà lọ sí àárín ìlú láti pa láì dá sí àti láì ṣàánú rárá.
Bet uz tiem citiem Viņš sacīja priekš manām ausīm: ejat pa pilsētu viņam pakaļ un kaujiet jūsu acs lai nežēlo, un nesaudzējiet.
6 Ẹ pa arúgbó àti ọ̀dọ́mọkùnrin, ẹ pa ọlọ́mọge, obìnrin àti ọmọ kéékèèké, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan àwọn tó ní àmì. Ẹ bẹ̀rẹ̀ láti ibi mímọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà tó wà níwájú tẹmpili.
Nokaujiet sirmgalvjus, jaunekļus un jaunietes un bērnus un sievas, kamēr jūs tos izdeldējat. Bet neaizskariet nevienu no tiem, pie kā tā zīme ir. Un iesāciet no manas svētās vietas. Un tie iesāka pie tiem vecajiem, kas tā nama priekšā bija.
7 Nígbà náà lo sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ tẹmpili náà di àìmọ́, kí òkú sì kún àgbàlá náà. Ẹ lọ!” Wọ́n jáde síta, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa ènìyàn láàrín ìlú.
Un Viņš uz tiem sacīja: sagāniet to namu un piepildiet tos pagalmus ar nokautiem; izejiet! Un tie izgāja un sita to pilsētu.
8 Èmi nìkan ló ṣẹ́kù nígbà tí wọ́n lọ pa àwọn ènìyàn, mo dójú mi bolẹ̀, mo kígbe pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli nípa dída ìbínú gbígbóná rẹ sórí Jerusalẹmu?”
Un notikās, kad tie tos sita un es atliku, tad es kritu uz savu vaigu un brēcu un sacīju: ak Kungs, Dievs! Vai Tu visus atlikušos iekš Israēla gribi izdeldēt, izgāzdams Savu bardzību pār Jeruzālemi?
9 Ó dá mi lóhùn pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli àti Juda pọ gidigidi; ilé wọn kún fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àti àìṣòótọ́. Wọ́n ní, ‘Olúwa tí kọ ilẹ̀ náà sílẹ̀; Olúwa kò sì rí wa.’
Tad Viņš uz mani sacīja: Israēla un Jūda nama noziegums ir ļoti varen liels, un zeme ir ar asinīm piepildīta, un pilsēta ir netaisnības pilna; jo tie saka: Tas Kungs zemi atstājis, un Tas Kungs neredz.
10 Nítorí náà, èmi kò ní wò wọ́n pẹ̀lú àánú, èmi kò sì ní dá wọn sí, ṣùgbọ́n Èmi yóò dá ohun tí wọ́n ti ṣe padà sórí wọn.”
Tad ir Mana acs nežēlos, un Es nesaudzēšu, Es metīšu viņu grēkus uz viņu galvu.
11 Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, tí ó ní ìwo tàdáwà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ròyìn pé, “Mo ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti pàṣẹ fún mi.”
Un redzi, tas vīrs, kas ģērbies audeklī, kam tās rakstāmās lietas bija pie gurniem, atnesa vēsti atpakaļ un sacīja: es esmu darījis, kā Tu man pavēlējis.

< Ezekiel 9 >