< Ezekiel 9 >

1 Mo gbọ́ ti ó kígbe ní ohùn rara pé, “Mú àwọn olùṣọ́ ìlú súnmọ́ itòsí, kí olúkúlùkù wọn mú ohun ìjà olóró lọ́wọ́.”
És kiáltá füleimbe nagy felszóval, mondván: Hozzátok el a városra a meglátogatásokat, kinek-kinek a kezében legyen vesztő eszköze.
2 Lójú ẹsẹ̀ ni ọkùnrin mẹ́fà jáde láti ẹnu-ọ̀nà òkè tó kọjú sí ìhà àríwá, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà olóró lọ́wọ́ wọn. Ọkùnrin kan tó wọ aṣọ funfun gbòò wa láàrín wọn, pẹ̀lú ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Gbogbo wọn sì dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ idẹ.
És ímé hat férfi jő vala a felső kapu útjáról, a mely északra néz vala, mindeniknek kezében zúzó eszköze, egy férfi pedig köztük gyolcsba vala öltözve, és íróeszköz vala derekán. És bemenének és állának az érczoltár mellé.
3 Ògo Ọlọ́run Israẹli sì gòkè kúrò lórí kérúbù, níbi tó wà tẹ́lẹ̀ lọ sí ibi ìloro tẹmpili. Nígbà náà ni Olúwa pe ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun náà tí ó sì ní ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
És Izráel Istenének dicsősége elvonula a Kérubról, a mely fölött vala, a ház küszöbéhez, és kiálta a gyolcsba öltözött férfiúnak, a kinek derekán íróeszköz vala.
4 Ó sì sọ fún un pé, “La àárín ìlú Jerusalẹmu já, kí ìwọ sì fi àmì síwájú orí gbogbo àwọn tó ń kẹ́dùn, tó sì ń sọkún nítorí ohun ìríra tí wọn ń ṣe láàrín rẹ̀.”
És monda az Úr néki: Menj át a város közepén, Jeruzsálem közepén, és jegyezz egy jegyet a férfiak homlokára, a kik sóhajtanak és nyögnek mindazokért az útálatosságokért, a melyeket cselekedtek annak közepében.
5 Bí mo ṣe ń fetí sí èyí, O tún sọ fún àwọn yòókù pé, “Tẹ̀lé ọkùnrin náà lọ sí àárín ìlú láti pa láì dá sí àti láì ṣàánú rárá.
És amazoknak mondá az én hallásomra: Menjetek át a városon ő utána, és vágjátok; ne kedvezzen a ti szemetek, és ne szánakozzatok:
6 Ẹ pa arúgbó àti ọ̀dọ́mọkùnrin, ẹ pa ọlọ́mọge, obìnrin àti ọmọ kéékèèké, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan àwọn tó ní àmì. Ẹ bẹ̀rẹ̀ láti ibi mímọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà tó wà níwájú tẹmpili.
Vénet, ifjat, szűzet, gyermeket és asszonyokat öljetek meg mind egy lábig, de azokhoz a férfiakhoz, a kiken a jegy van, ne közelítsetek, és az én templomomon kezdjétek el. Elkezdék azért a vén férfiakon, a kik a ház előtt valának.
7 Nígbà náà lo sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ tẹmpili náà di àìmọ́, kí òkú sì kún àgbàlá náà. Ẹ lọ!” Wọ́n jáde síta, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa ènìyàn láàrín ìlú.
És mondá nékik: Fertőztessétek meg a házat, és töltsétek meg a pitvarokat megölettekkel. Menjetek ki. És kimenének és öldöklének a városban.
8 Èmi nìkan ló ṣẹ́kù nígbà tí wọ́n lọ pa àwọn ènìyàn, mo dójú mi bolẹ̀, mo kígbe pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli nípa dída ìbínú gbígbóná rẹ sórí Jerusalẹmu?”
És lőn, hogy levágák őket, és én megmaradtam és esém az én orczámra és kiálték és mondék: Ah, ah, Uram Isten, avagy ki akarod-é írtani Izráel egész maradékát, mikor kiöntöd búsulásodat Jeruzsálemre?
9 Ó dá mi lóhùn pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli àti Juda pọ gidigidi; ilé wọn kún fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àti àìṣòótọ́. Wọ́n ní, ‘Olúwa tí kọ ilẹ̀ náà sílẹ̀; Olúwa kò sì rí wa.’
És mondá nékem: Izráel és Júda házának vétke felette nagy, mivelhogy tele a föld vérontással, és a város tele van igazságtalansággal, mert azt mondották: Elhagyta az Úr ezt a földet, és az Úr nem lát.
10 Nítorí náà, èmi kò ní wò wọ́n pẹ̀lú àánú, èmi kò sì ní dá wọn sí, ṣùgbọ́n Èmi yóò dá ohun tí wọ́n ti ṣe padà sórí wọn.”
Azért én is (nem kedvez szemem, sem meg nem szánom őket) útjokat fejökhöz verem!
11 Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, tí ó ní ìwo tàdáwà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ròyìn pé, “Mo ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti pàṣẹ fún mi.”
És ímé a gyolcsba öltözött férfi, kinek íróeszköz vala derekán, választ hozott, mondván: Úgy cselekedtem, a mint parancsolád.

< Ezekiel 9 >