< Ezekiel 8 >

1 Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
I stało się roku szóstego, piątego dnia, szóstego miesiąca, gdym siedzał w domu swym, a starsi Judzcy siedzieli przedemną, tedy tam przypadła na mię ręka panującego Pana.
2 Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
I widzałem, a oto podobieństwo na wejrzeniu jako ogień; od biódr jego na dół jako ogień, a od biódr jego w górę na wejrzeniu jako blask, i niby prędka światłość.
3 Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
Tedy ściągnąwszy podobieństwo ręki, uchwycił mię za kędzierze głowy mojej, i podniósł mię duch między ziemią i między niebem, a przywiódł mię do Jeruzalemu w widzeniach Bożych, do wejścia bramy wewnętrznej, która patrzy ku północy, gdzie była stolica bałwana do gorliwości i zapalczywości pobudzająca.
4 Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
A oto tam była chwała Boga Izraelskiego na wejrzeniu jako ona, którąm widział na polu.
5 Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
I rzekł do mnie: Synu człowieczy! teraz podnieś oczy swe ku drodze na północy; a tak podniosłem oczy swe ku drodze na północy, a oto na północy był u bramy ołtarzowej on bałwan pobudzający do gorliwości w samem prawie wejściu.
6 Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
Wtem mi rzekł: Synu człowieczy! widziszże ty, co ci czynią, obrzydliwości wielkie, które tu czyni dom Izraelski? tak, że się oddalić muszę od świątnicy mojej; ale obróciwszy się ujrzysz obrzydliwości jeszcze większe.
7 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
I przywiódł mię do drzwi sieni, gdziem ujrzał, a oto dziura jedna była w ścianie.
8 Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
I rzekł do mnie: Synu człowieczy! przekop teraz tę ścianę: i przekopałem ścianę, a oto drzwi jedne.
9 Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
I rzekł do mnie: Wnijdź, a obacz te złe obrzydliwości, które tu oni czynią.
10 Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
Przetoż wszedłszy ujrzałem, a oto wszelakie podobieństwa płazu, i zwierząt obrzydłych, i wszelakich plugawych bałwanów domu Izraelskiego wyryte były na ścianie wszędy w około.
11 Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
A siedmdziesiąt mężów starszych z domu Izraelskiego, z Jazanijaszem, synem Safanowym, stojącym w pośród nich, stali przed nimi, mając każdy kadzielnicę swoję w ręcę swej, tak, że gęsty obłok kadzenia w górę wstępował.
12 Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
I rzekł do mnie: A widziałżeś, synu człowieczy! co starsi domu Izraelskiego w ciemności czynią, każdy w pokojach swoich malowanych? Bo mówią: Nie widzi nas Pan, opuścił Pan tę ziemię.
13 Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
Znowu rzekł do mnie: Jeszcze obróciwszy się ujrzysz obrzydliwości większe, które oni czynią.
14 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
I przywiódł mię do wrót bramy domu Pańskiego, która jest na półnpcy, a oto tam niewiasty siedziały, płacząc Tammusa;
15 Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
I rzekł mi: A widziałżeś, synu człowieczy? Ale obróciwszy się ujrzysz jeszcze większe obrzydliwości, niżeli te.
16 Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
Tedy mię wprowadził do wnętrznej sieni domu Pańskiego, a oto u drzwi kościoła Pańskiego między przysionkim i ołtarzem było dwadzieścia i pięć mężów, których tyły były obrócone ku kościołowi Pańskiemu, a twarze ich na wschód, którzy się kłaniali przeciwko wschodowi słońca.
17 Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
I rzekł mi: A widziałżeś, synu człowieczy? Izali to lekka rzecz jest domowi Judzkiemu, czynić takie obrzydliwości, jakie tu czynią? Bo napełniwszy ziemię nieprawością, obrócili się, aby mię draźnili, a oto przykładają latorośl winną do nosów swoich.
18 Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”
Przetoż i Ja postąpię z nimi wedłu zapalczywości; oko moje nie sfolguje ani się zmiłuję; i będą wołać do uszów moich głosem wielkim, a nie wysłucham ich.

< Ezekiel 8 >