< Ezekiel 8 >

1 Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
La sixième année, au sixième mois, le cinquième jour du mois, comme j'étais assis dans ma maison, et que les anciens de Juda étaient assis devant moi, la main du Seigneur Yahweh tomba sur moi.
2 Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
Et je vis; et voici une figure qui avait l'aspect du feu; depuis ce qui paraissait ses reins jusqu'en bas, c'était du feu; et depuis ses reins jusqu'en haut, c'était comme l'aspect d'une clarté, comme l'aspect d'un métal.
3 Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
Et il étendit une forme de main, et il me saisit par les boucles de mes cheveux, et l'Esprit m'enleva entre la terre et le ciel; et il m'amena à Jérusalem, en des visions divines, à l'entrée de la porte intérieure qui regarde au septentrion, où était placée l'idole de jalousie qui provoque la jalousie.
4 Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Et voici que là était la gloire du Dieu d'Israël selon l'aspect que j'avais vu dans la plaine.
5 Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
Il me dit: " Fils de l'homme, lève donc tes yeux dans la direction du septentrion. " Et je levai mes yeux dans la direction du septentrion, et voici qu'au nord de la porte de l'autel, il y avait cette idole de jalousie, à l'entrée.
6 Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
Et il me dit: " Fils de l'homme, vois-tu ce qu'ils font, les grandes abominations que la maison d'Israël commet ici, afin que je m'éloigne de mon sanctuaire. Et tu verras encore d'autres grandes abominations. "
7 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
Et il me conduisit à l'entrée du parvis, et je vis: et voici qu'il y avait un trou dans le mur!
8 Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
et il me dit: " Fils de l'homme, perce donc la muraille. " Et je perçai la muraille, et voici qu'il y avait une porte.
9 Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
Et il me dit: " Viens et vois les horribles abominations qu'ils commettent ici. "
10 Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
Et je vins et je vis: et voici qu'il y avait toutes sortes de figures de reptiles et d'animaux immondes, et toutes les horreurs de la maison d'Israël dessinées sur la muraille tout autour.
11 Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
Et soixante-dix hommes d'entre les anciens de la maison d'Israël, parmi lesquels était Jézonias, fils de Saphan, se tenaient debout devant elles, et chacun avait à la main son encensoir, d'où s'élevait le parfum d'un nuage d'encens.
12 Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
Et il me dit: " As-tu vu, fils de l'homme, ce que les anciens de la maison d'Israël font dans les ténèbres, chacun dans ses appartements couverts de figures, car ils disent: Yahweh ne nous voit pas; Yahweh a abandonné le pays! "
13 Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
Et il me dit: " Tu verras encore d'autres grandes abominations qu'ils commettent. "
14 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
Et il me conduisit à l'entrée de la porte de la maison de Yahweh qui regarde le septentrion; et voici que les femmes y étaient assises, pleurant le dieu Thammuz.
15 Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
Et il me dit: " As-tu vu, fils de l'homme? Tu verras encore d'autres abominations plus grandes que celles-là. "
16 Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
Et il me conduisit alors dans le parvis intérieur de la maison de Yahweh; et voici qu'à l'entrée de la maison de Yahweh, entre le portique et l'autel, il y avait environ vingt-cinq hommes, le dos tourné au temple de Yahweh, et le visage vers l'orient; et ils se prosternaient à l'orient devant le soleil.
17 Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
Et il me dit: " As-tu vu, fils de l'homme? Est-ce trop peu pour la maison de Juda de commettre les abominations qu'ils commettent ici? Faut-il qu'ils remplissent encore le pays de violence, et qu'ils recommencent toujours à m'irriter? Voici qu'ils portent le rameau à leur nez.
18 Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”
Et moi aussi, j'agirai avec colère; mon œil n'épargnera point, et je serai sans pitié; ils crieront à haute voix à mes oreilles, et je ne les entendrai point. "

< Ezekiel 8 >