< Ezekiel 8 >

1 Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
And it was doon in the sixte yeer, in the sixte monethe, in the fyuethe dai of the monethe, Y sat in myn hous, and the elde men of Juda saten bifore me; and the hond of the Lord God felle there on me.
2 Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
And Y siy, and lo! a licnesse as the biholdyng of fier; fro the biholding of hise leendis and bynethe was fier, and fro hise leendis and aboue was as the biholdyng of schynyng, as the siyt of electre.
3 Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
And the licnesse of an hond was sent out, and took me bi the heer of myn heed; and the spirit reiside me bitwixe heuene and erthe, and brouyte me in to Jerusalem, in the siyt of God, bisidis the ynnere dore that bihelde to the north, where the idol of enuye was set, to stire indignacioun.
4 Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
And lo! the glorie of God of Israel was there, bi siyt which Y siy in the feeld.
5 Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
And he seide to me, Thou, sone of man, reise thin iyen to the weie of the north; and Y reiside myn iyen to the weie of the north, and lo! fro the north of the yate of the auter the idol of enuye was in that entryng.
6 Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
And he seide to me, Sone of man, gessist thou whether thou seest what thing these men doon, the grete abhomynaciouns whiche the hous of Israel doith here, that Y go fer awei fro my seyntuarie? and yit thou schalt turne, and schalt se grettere abhomynaciouns.
7 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
And he ledde me with ynne to the dore of the halle; and Y siy, and lo! oon hoole in the wal.
8 Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
And he seide to me, Sone of man, digge thou the wal; and whanne Y hadde diggid the wal, o dore apperide.
9 Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
And he seide to me, Entre thou, and se the worste abhomynaciouns, whiche these men doon here.
10 Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
And Y entride, and siy; and lo! ech licnesse of `crepynge beestis, and abhomynacioun of beestis, and alle idols of the hous of Israel, weren peyntid in the wal al aboute in cumpas.
11 Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
And seuenti men of the eldere of the hous of Israel stoden; and Jeconye, the sone of Saphan, stood in the myddis of hem, stondynge bifore the peyntyngis; and ech man hadde a censere in his hond, and the smoke of a cloude of encense stiede.
12 Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
And he seide to me, Certis, sone of man, thou seest what thingis the eldere men of the hous of Israel doen in derknessis, ech man in the hid place of his bed; for thei seiyn, The Lord seeth not vs, the Lord hath forsake the lond.
13 Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
And the Lord seide to me, Yit thou schalt turne, and schalt se gretter abhomynaciouns, whiche these men doon.
14 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
And he ledde me with ynne, bi the dore of the yate of the hous of the Lord, which dore bihelde to the north; and lo! wymmen saten there, biweilynge Adonydes.
15 Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
And the Lord seide to me, Certis, sone of man, thou hast seyn; yit thou schalt turne, and schalt se gretere abhomynaciouns than these.
16 Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
And he ledde me with ynne, in to the ynnere halle of the hous of the Lord; and lo! in the dore of the temple of the Lord, bitwixe the porche and the auter, weren as fyue and twenti men hauynge the backis ayens the temple of the Lord, and her faces to the eest; and thei worschipiden at the risyng of the sunne.
17 Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
And the Lord seide to me, Certis, sone of man, thou hast seyn; whether this is a liyt thing to the hous of Juda, that thei schulden do these abhomynaciouns, whiche thei diden here? For thei filliden the lond with wickidnesse, and turneden to terre me to wraththe; and lo! thei applien a braunche to her nose thirlis.
18 Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”
Therfor and Y schal do in strong veniaunce; myn iye schal not spare, nether Y schal do merci; and whanne thei schulen crie to myn eris with greet vois, Y schal not here hem.

< Ezekiel 8 >