< Ezekiel 8 >

1 Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
And it came to pass, in the sixth year in the sixth month, on the fifth of the month, I being seated in my house, and the elders of Judah being seated before me, then fell upon me there the hand of My Lord Yahweh.
2 Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
So I looked, and lo! a likeness as the appearance of a man, from the appearance of his loins and downward fire, and from his loins and upwards as an appearance of shining, as the look of amber,
3 Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
Then put he forth the similitude of a hand, and took me by the forelock of my head, —and the Spirit lifted me up between the earth and the heavens and brought me to Jerusalem in the visions of God into the opening of the inner gate that looketh toward the north, where was the seat of the Statue of Jealousy. that provoketh to jealousy;
4 Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
and lo! there, the glory of the God of Israel, like the appearance which I had seen in the valley.
5 Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
Then said he unto me, Son of man Lift up. I pray thee thine eyes, the way toward the north. So I lifted up mine eyes the way toward the north, and lo! on the north by the gate of the altar, this Statue of Jealousy, in the entrance.
6 Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
Then said he unto me, Son of man Canst thou see what they are doing, —the great abominations which the house of Israel are committing here, that I should go faraway from my sanctuary? Howbeit yet again, shalt thou see great abominations.
7 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
So he brought me into the opening of the court, —and I looked, and lo! a single hole in the wall.
8 Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
Then said he unto me Son of man Break I pray thee through the wall. So I broke through the wall, and lo! a single opening.
9 Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
Then said he unto me, — Go in, and see the wicked abominations. which they are committing here.
10 Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
So I went in. and looked, and lo! every similitude of creeping thing, and detestable beast, and all the manufactured gods of the house of Israel, - portrayed upon the wall round about on every side;
11 Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
and seventy men of the elders of the house of Israel with Jaazaniah son of Shaphan, who stood in their midst were standing before them, even every man with his censer in his hand, —and the fragrance of the cloud of incense ascending.
12 Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
Then said he unto me, Hast thou seen Son of man what the elders of the house of Israel, are doing in the dark, every man in his image-chambers? for they are saying— Yahweh doth not see us! Yahweh hath forsaken the land!
13 Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
Then said he unto me, — Yet again, shalt thou see great abominations, which they are committing.
14 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
So he brought me into the opening of the gate of the house of Yahweh, which was toward the north, —and Lo! there, women sitting, weeping for Tammuz.
15 Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
Then said he unto me Hast thou seen O son of man? Yet again, shalt thou see greater abominations than these.
16 Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
So he brought me into the inner court of the house of Yahweh, and lo! at the opening of the temple of Yahweh, between the porch and the altar, about twenty-five men, —their backs towards the temple of Yahweh and their faces eastward, and they were bowing down eastward unto the Sun.
17 Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
Then said he unto me Hast thou seen O son of man? Is it too small a thing for the house of Judah, to be committing the abominations which they have committed here, —that they have filled the land with violence and have again provoked me to anger and there they are! putting the branch to my nose.
18 Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”
Therefore even I, will act with indignation, Mine eye shall not shield. Neither will I pity, — Though they have cried in mine ears with a loud voice, yet will I not hear them.

< Ezekiel 8 >