< Ezekiel 8 >
1 Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
I det sjette Aar paa den femte Dag i den sjette Maaned da jeg sad i mit Hus og Judas Ældste sad hos mig, faldt den Herre HERRENS Haand paa mig.
2 Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
Og jeg skuede, og se, der var noget ligesom en Mand; fra hans Hofter og nedefter var der Ild, og fra Hofterne og opefter saa det ud som straalende Lys, som funklende Malm.
3 Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
Han rakte noget som en Haand ud og greb mig ved en Lok af mit Hovedhaar, og Aanden løftede mig op mellem Himmel og Jord og førte mig i Guds Syner til Jerusalem, til Indgangen til den indre Forgaards Nordport, hvor Nidkærhedsbilledet, som vakte Nidkærhed, stod.
4 Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Og se, der var Israels Guds Herlighed; at se til var den, som jeg saa den i Dalen.
5 Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
Og han sagde til mig: »Menneskesøn, løft dit Blik mod Nord!« Jeg løftede mit Blik mod Nord, og se, norden for Alterporten stod Nidkærhedsbilledet, ved Indgangen.
6 Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
Og han sagde til mig: »Menneskesøn, ser du, hvad de gør? Store er de Vederstyggeligheder, Israels Hus øver her, saa jeg maa vige langt bort fra min Helligdom. Men du skal faa endnu større Vederstyggeligheder at se!«
7 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
Saa førte han mig hen til Indgangen til Forgaarden.
8 Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
Og han sagde til mig: »Menneskesøn, bryd igennem Væggen!« Og da jeg brød igennem Væggen, saa jeg en Indgang.
9 Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
Og han sagde til mig: »Gaa ind og se, hvilke grimme Vederstyggeligheder de øver der!«
10 Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
Og da jeg kom derind og skuede, se, da var alskens væmmelige Billeder af Kryb og Kvæg og alle Israels Hus's Afgudsbilleder indridset rundt om paa Væggen.
11 Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
Og halvfjerdsindstyve af Israels Hus's Ældste med Ja'azanja, Sjafans Søn, i deres Midte stod foran dem, hver med sit Røgelsekar i Haanden, medens Røgelseskyens Duft steg op.
12 Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
Da sagde han til mig: »Ser du, Menneskesøn, hvad Israels Hus's Ældste øver i Mørke hver i sine Billedkamre? Thi de siger: HERREN ser intet, HERREN har forladt Landet!«
13 Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
Og han sagde til mig: »Du skal faa endnu større Vederstyggeligheder at se, som de øver!«
14 Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
Saa førte han mig hen til Indgangen til HERRENS Hus's Nordport, og se, der sad Kvinder og græd over Tammuz.
15 Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
Og han sagde til mig: »Ser du det, Menneskesøn? Men du skal faa endnu større Vederstyggeligheder at se!«
16 Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
Saa førte han mig hen til HERRENS Hus's indre Forgaard, og se, ved Indgangen til HERRENS Helligdom mellem Forhallen og Alteret var der omtrent fem og tyve Mænd; med Ryggen mod HERRENS Helligdom og Ansigtet mod Øst tilbad de Solen.
17 Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
Og han sagde til mig: »Ser du det, Menneskesøn? Har Judas Hus ikke nok i at øve de Vederstyggeligheder her, siden de fylder Landet med Vold og krænker mig endnu mere? Se, hvor de sender Stank op i Næsen paa mig!
18 Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”
Men derfor vil ogsaa jeg handle med dem i Vrede; jeg viser dem ingen Medynk eller Skaansel, og selv om de højlydt raaber mig ind i Øret, vil jeg ikke høre dem.«