< Ezekiel 7 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Mai mult, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ilé Israẹli: “‘Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà!
De asemenea, tu fiu al omului, astfel spune Domnul DUMNEZEU către țara lui Israel: Un sfârșit, sfârșitul a venit peste cele patru colțuri ale țării.
3 Òpin tí dé sí ọ báyìí, èmi yóò sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, èmi yóò dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, èmi yóò sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.
Acum [a venit] sfârșitul asupra ta și eu voi trimite mânia mea asupra ta și conform căilor tale te voi judeca, și voi întoarce asupra ta toate urâciunile tale.
4 Ojú mi kò ní i dá ọ sì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú; ṣùgbọ́n èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrín rẹ. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Și ochiul meu nu te va cruța, nici nu va avea milă; ci voi întoarce căile tale asupra ta și urâciunile tale vor fi în mijlocul tău; și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
5 “Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ibi! Ibi kan ṣoṣo. Kíyèsi, ó bọ̀ ní orí rẹ!
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Un rău, un singur rău, iată, a venit.
6 Òpin ti dé! Òpin ti dé! Ó ti dìde lòdì sí ọ. Kíyèsi, ó ti dé!
Un sfârșit a venit, sfârșitul a venit; se trezește [împotriva] ta; iată, a venit.
7 Ìparun ti dé sórí rẹ, ìwọ tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àkókò náà dé! Ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé! Kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.
Dimineața a venit la tine, tu cel care locuiești în țară; a venit timpul, ziua tulburării [este] aproape și nu răsunetul munților.
8 Mo ṣetán láti tú ìbínú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gẹ́gẹ́ bí ìwà ìríra rẹ ni èmi yóò sì san án fún ọ.
Acum, îmi voi turna în curând furia mea asupra ta și voi împlini mânia mea asupra ta; și conform căilor tale te voi judeca și te voi răsplăti pentru toate urâciunile tale.
9 Ojú mi kò ní i dá ọ sí, Èmi kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti fún gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrín rẹ. “‘Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé Èmi Olúwa lo kọlù yín.
Și ochiul meu nu va cruța, nici nu voi avea milă; te voi răsplăti conform căilor tale și urâciunilor tale, care [sunt] în mijlocul tău; și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL care lovește.
10 “‘Ọjọ́ náà dé! Kíyèsi ó ti dé! Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tanná, ìgbéraga ti rúdí!
Iată, ziua, iată, a venit; dimineața a rodit, toiagul a înflorit, mândria a înmugurit.
11 Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; ọ̀pá láti jẹ ẹni búburú ní ìyà. Kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kù, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí nínú ọrọ̀ wọn, kò sí ohun tí ó ní iye.
Violența s-a ridicat într-un toiag al stricăciunii; nimeni dintre ei [nu va rămâne], nici din mulțimea lor, nici vreunul dintre ei; nici nu [va fi] bocire pentru ei.
12 Àkókò náà dé! Ọjọ́ náà ti dé! Kí òǹrajà má ṣe yọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ki òǹtajà má ṣe ṣọ̀fọ̀; nítorí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.
A venit timpul, ziua se apropie; să nu se bucure cumpărătorul și să nu jelească vânzătorul, căci furie [este] peste întreaga lor mulțime.
13 Nítorí pé òǹtajà kì yóò rí gbà padà dúkìá èyí tó tà níwọ̀n ìgbà ti àwọn méjèèjì bá wà láààyè. Nítorí ìran tó kan gbogbo ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.
Pentru că vânzătorul nu se va întoarce la ceea ce este vândut, chiar dacă ei ar fi încă în viață, pentru că viziunea se referă la întreaga lor mulțime, [care] nu se va întoarce; nici nu se va întări cineva în nelegiuirea vieții lui.
14 “‘Wọ́n ti fọn ìpè ogun, tí wọ́n sì pèsè ohun gbogbo sílẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò lọ ojú ogun, nítorí ìbínú gbígbóná mi ti wà lórí gbogbo ènìyàn.
Ei au sunat din trâmbiță ca să pregătească totul; dar nimeni nu merge la bătălie, pentru că furia mea [este] peste întreaga lor mulțime.
15 Idà wà ní ìta, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn wà nílé, idà yóò pa ẹni tó bá wà ní orílẹ̀-èdè, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn yóò pa ẹni tó bá wà ní ìlú.
Sabia [este] afară și ciuma și foametea înăuntru; cel din câmp va muri de sabie; și pe cel din cetate, foametea și ciuma îl vor mânca.
16 Gbogbo àwọn tí ó bọ́ nínú wọn yóò sálà, wọn yóò sì wà lórí òkè. Bí i àdàbà inú àfonífojì, gbogbo wọn yóò máa ṣọ̀fọ̀, olúkúlùkù nítorí àìṣedéédéé rẹ̀.
Dar cei dintre ei care scapă, vor scăpa și vor fi pe munți ca porumbeii văilor, jelind cu toții, fiecare pentru nelegiuirea lui.
17 Gbogbo ọwọ́ yóò rọ, gbogbo orúnkún yóò di aláìlágbára bí omi.
Toate mâinile vor fi slăbite și toți genunchii vor fi slabi [ca] apa.
18 Wọn yóò wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ̀rù yóò sì bò wọ́n mọ́lẹ̀, ìtìjú yóò mù wọn, wọn yóò sì fá irun wọn.
Ei [se] vor încinge de asemenea cu pânză de sac și groaza îi va acoperi; și rușine [va fi] pe toate fețele și chelie pe toate capetele lor.
19 “‘Wọn yóò dà fàdákà wọn sí ojú pópó, wúrà wọn yóò sì dàbí èérí fàdákà àti wúrà wọn kò ní le gbà wọ́n ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná Olúwa. Wọn kò ní le jẹun tẹ́ ra wọn lọ́rùn tàbí kí wọn kún ikùn wọn pẹ̀lú oúnjẹ nítorí pé ó ti di ohun ìkọ̀sẹ̀ fún wọn.
Vor arunca argintul lor pe străzi și aurul lor va fi îndepărtat; argintul lor și aurul lor nu vor fi în stare să îi scape în ziua furiei DOMNULUI; nu le vor sătura sufletele, nici nu le vor umple adâncurile, pentru că aceasta este piatra de poticnire a nelegiuirii lor.
20 Wọ́n ń ṣe ìgbéraga pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ wọn tí ó lẹ́wà, wọn sì ti fi ṣe òrìṣà, wọn sì tún ya àwòrán ìríra wọn níbẹ̀. Nítorí náà, èmi yóò sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí di aláìmọ́ fún wọn.
Cât despre frumusețea ornamentului său, el l-a pus în măreție; dar ei au făcut chipurile urâciunilor lor [și] lucrurile lor detestabile, în el; de aceea l-am pus eu departe de ei.
21 Èmi yóò sì fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe ìjẹ fún àjèjì àti ìkógun fún àwọn ènìyàn búburú ayé, wọn yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́.
Și îl voi da în mâinile străinilor ca pradă și stricaților pământului ca jefuire; și ei îl vor spurca.
22 Èmi yóò gbójú mi kúrò lára wọn, àwọn ọlọ́ṣà yóò sì sọ ibi ìṣúra mi di aláìmọ́; àwọn ọlọ́ṣà yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sì bà á jẹ́.
Îmi voi întoarce de asemenea fața de la ei și ei vor spurca [locul] meu tainic; fiindcă jefuitorii vor intra în el și îl vor spurca.
23 “‘Rọ ẹ̀wọ̀n irin! Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún ẹ̀ṣẹ̀ ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìlú náà sí kún fún ìwà ipá.
Fă un lanț, pentru că țara este plină de crime sângeroase și cetatea este plină de violență.
24 Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè ti ó búburú jùlọ láti jogún ilé wọn. Èmi yóò sì fi òpin sí ìgbéraga àwọn alágbára, ibi mímọ́ wọn yóò sì di bíbàjẹ́.
De aceea voi aduce pe cei mai răi dintre păgâni și ei vor stăpâni casele lor; voi face de asemenea să înceteze fastul celor puternici; și locurile lor sfinte vor fi spurcate.
25 Nígbà tí ìpayà bá dé, wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.
Nimicirea vine; iar ei vor căuta pace și nu [va fi].
26 Wàhálà lórí wàhálà yóò dé, ìdágìrì lórí ìdágìrì. Nígbà náà ni wọn yóò wá ìran lọ́dọ̀ wòlíì, ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ òfin yóò parun lọ́dọ̀ àlùfáà, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ràn yóò ṣègbé lọ́dọ̀ àwọn àgbàgbà.
Ticăloșie va veni peste ticăloșie și zvon va fi peste zvon; atunci vor cere ei o viziune a profetului; dar legea va pieri de la preot și sfatul de la cei bătrâni.
27 Ọba yóò ṣọ̀fọ̀, ọmọ-aládé yóò wà láìní ìrètí, ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yóò wárìrì. Èmi yóò ṣe é fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, èmi yóò ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìgbékalẹ̀ wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa.’”
Împăratul va jeli și prințul va fi îmbrăcat cu pustiire și mâinile poporului țării vor fi tulburate; le voi face după calea lor și conform cu meritele lor îi voi judeca; și ei vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.

< Ezekiel 7 >