< Ezekiel 7 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
HIKI mai la hoi ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
2 “Ọmọ ènìyàn, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ilé Israẹli: “‘Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà!
O oe hoi, e ke heiki a ke kanaka, ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; He hopena o ka aina o ka Iseraela, ua hiki mai ka hopena maluna o na kihi eha o ka aina.
3 Òpin tí dé sí ọ báyìí, èmi yóò sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, èmi yóò dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, èmi yóò sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.
Ua hiki mai ka hopena maluna ou auo, a e hoouna au i ko'u huhu maluna ou, a e hoahewa au ia oe e like me kou hele ana, a e uku aku au ia oe no kou mau mea hoopailua a pau.
4 Ojú mi kò ní i dá ọ sì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú; ṣùgbọ́n èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrín rẹ. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Aole e aloha ko'u maka ia oe, aole au e ahonui ia oe; aka, e hooili au i ka uku no kou mau aoao maluna on, a mawaena aku no ou kou mau mea inaina; a e ike no oukou owau no Iehova.
5 “Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ibi! Ibi kan ṣoṣo. Kíyèsi, ó bọ̀ ní orí rẹ!
Ke i mai nei Iehova ka Haku penei, He poino, he poino wale no, eia hoi, ua hiki mai ia.
6 Òpin ti dé! Òpin ti dé! Ó ti dìde lòdì sí ọ. Kíyèsi, ó ti dé!
He hopena ua hiki mai, na hiki mai ka hopena; ke kiai nei no ia ia oe; eia hoi ua hiki mai ia.
7 Ìparun ti dé sórí rẹ, ìwọ tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àkókò náà dé! Ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé! Kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.
Ua hiki mai ke kakahiaka maluna ou, e ka mea e noho ana ma ka aina; ua hiki mai ka manawa, kokoke mai ka la e popilikia ai, aole ka hooho ana o na mauna.
8 Mo ṣetán láti tú ìbínú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gẹ́gẹ́ bí ìwà ìríra rẹ ni èmi yóò sì san án fún ọ.
Ano, e ninini koke aku au i ko'u ukiuki maluna ou, a e hooko i ko'u huhu maluna ou; a e hoopai au ia oe e like me kou mau aoao, a e uku aku au ia oe no kou mau mea inainaia a pau.
9 Ojú mi kò ní i dá ọ sí, Èmi kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti fún gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrín rẹ. “‘Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé Èmi Olúwa lo kọlù yín.
Aole e aloha ko'u maka, aole hoi au e ahonui; e uku au ia oe e like me kou mau aoao, a me kou mau mea inainaia iwaenakonu ou, a e ike no oukou, owau no Iehova ka mea i hahau.
10 “‘Ọjọ́ náà dé! Kíyèsi ó ti dé! Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tanná, ìgbéraga ti rúdí!
Aia hoi ka la, aia hoi ua hiki mai ia; ua puka ae ke kakahiaka, ua mohala ke kookoo-alii, ua opuu ae ka haaheo.
11 Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; ọ̀pá láti jẹ ẹni búburú ní ìyà. Kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kù, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí nínú ọrọ̀ wọn, kò sí ohun tí ó ní iye.
Ua ku mai iluna ka lalauwale i kookoo hewa; aole kauwahi o lakou, aole o ko lakou lehulehu, aole hoi o ka lakou waiwai, aole hoi he kanikau no lakou.
12 Àkókò náà dé! Ọjọ́ náà ti dé! Kí òǹrajà má ṣe yọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ki òǹtajà má ṣe ṣọ̀fọ̀; nítorí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.
Ua hiki mai ka manawa, ke kokoke mai nei ka la; mai hauoli ka mea kuai lilo mai, aole hoi e u ka mea kuai lilo aku, no ka mea, e kau ana ka inaina maluna o kona lehulehu a pau.
13 Nítorí pé òǹtajà kì yóò rí gbà padà dúkìá èyí tó tà níwọ̀n ìgbà ti àwọn méjèèjì bá wà láààyè. Nítorí ìran tó kan gbogbo ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.
No ka mea, aole e hoi aku ka mea kuai lilo aku, ina e ola ana lakou; no ka mea, o ka hihio, no kona lehulehu okoa no ia, aole e hoi mai; aole hoi e hooikaika kekahi ia ia iho ma ka hewa o kona ola ana.
14 “‘Wọ́n ti fọn ìpè ogun, tí wọ́n sì pèsè ohun gbogbo sílẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò lọ ojú ogun, nítorí ìbínú gbígbóná mi ti wà lórí gbogbo ènìyàn.
E pupuhi oukou i ka pu, e hoomakaukau ai i na mea a pau; aole nae he mea hele i ke kaua; no ka mea, maluna o kolaila lehulehu okoa kuu inaina.
15 Idà wà ní ìta, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn wà nílé, idà yóò pa ẹni tó bá wà ní orílẹ̀-èdè, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn yóò pa ẹni tó bá wà ní ìlú.
O ka pahikaua ka iwaho, a o ka mai ahulau a me ka wi ka iloko: o ka mea ma ke kula, e make no ia i ka pahikaua; a o ka mea maloko o ke kulanakauhale, e pau ia i ka aiia e ka wi a me ka mai ahulau.
16 Gbogbo àwọn tí ó bọ́ nínú wọn yóò sálà, wọn yóò sì wà lórí òkè. Bí i àdàbà inú àfonífojì, gbogbo wọn yóò máa ṣọ̀fọ̀, olúkúlùkù nítorí àìṣedéédéé rẹ̀.
A o ko lakou poe pakele, e pakele lakou, a maluna o na mauna no lakou, me he mau manu-ku la ma na awawa e u ana kela mea keia mea no kona hewa iho.
17 Gbogbo ọwọ́ yóò rọ, gbogbo orúnkún yóò di aláìlágbára bí omi.
E nawaliwali na lima a pau, a e palupalu na kuli a pau me he wai la.
18 Wọn yóò wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ̀rù yóò sì bò wọ́n mọ́lẹ̀, ìtìjú yóò mù wọn, wọn yóò sì fá irun wọn.
E kaei lakou i ke kapa ino, a e uhi mai ka makau ia lakou: a e kau ka hilahila maluna o na wahi maka a pau, a me ka ohule ma ko lakou mau poo a pau.
19 “‘Wọn yóò dà fàdákà wọn sí ojú pópó, wúrà wọn yóò sì dàbí èérí fàdákà àti wúrà wọn kò ní le gbà wọ́n ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná Olúwa. Wọn kò ní le jẹun tẹ́ ra wọn lọ́rùn tàbí kí wọn kún ikùn wọn pẹ̀lú oúnjẹ nítorí pé ó ti di ohun ìkọ̀sẹ̀ fún wọn.
E hoolei lakou i ka lakou kala i na alanui, a e laweia'e ka lakou gula; aole e hiki i ka lakou kala, a me ka lakou gula i ka hoopakele ia lakou i ka la o ka inaina o Iehova; aole e hooluolu i ko lakou mau uhane, aole hoi e hoopiha i ko lakou mau naau, no ka mea. o ka mea e hina ai ia e hewa ai lakou.
20 Wọ́n ń ṣe ìgbéraga pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ wọn tí ó lẹ́wà, wọn sì ti fi ṣe òrìṣà, wọn sì tún ya àwòrán ìríra wọn níbẹ̀. Nítorí náà, èmi yóò sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí di aláìmọ́ fún wọn.
A o ka nani o kona mea i nani ai, ua hoonoho oia ia i ka hanohano: aka, hana ae la lakou i na kii o ko lakou mau mea e inainaia, a me ko lakou mau mea e hoowahawahaia ilaila; nolaila, i hoonoho aku au ia mea i mamao aku o lakou.
21 Èmi yóò sì fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe ìjẹ fún àjèjì àti ìkógun fún àwọn ènìyàn búburú ayé, wọn yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́.
A e haawi aku au ia mea iloko o na lima o na malihini i waiwai pio, a i ka poe hewa o ka honua i waiwai kaili; a e hoohaumia lakou ia mea.
22 Èmi yóò gbójú mi kúrò lára wọn, àwọn ọlọ́ṣà yóò sì sọ ibi ìṣúra mi di aláìmọ́; àwọn ọlọ́ṣà yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sì bà á jẹ́.
A e haliu aku au i ko'u wahi maka mai o lakau aku, a e hoohaumia lakou i ko'u wahi nalo; no ka mea, e komo no na powa iloko ona, a e hoohaumia ia ia.
23 “‘Rọ ẹ̀wọ̀n irin! Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún ẹ̀ṣẹ̀ ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìlú náà sí kún fún ìwà ipá.
E hana i kaula hao; no ka mea, ua paapu ka aina i na hewa koko, a ua piha ke kulanakauhale i ka lalauwale.
24 Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè ti ó búburú jùlọ láti jogún ilé wọn. Èmi yóò sì fi òpin sí ìgbéraga àwọn alágbára, ibi mímọ́ wọn yóò sì di bíbàjẹ́.
Nolaila e lawe mai au i ka poe hewa nui o na lahuikanaka, a lilo ko lakou nei mau hale ia lakou la, a e hooki au i ka hanohano o ka poe ikaika, a e hoohaumiaia ko lakou mau wahi hoano.
25 Nígbà tí ìpayà bá dé, wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.
E hele mai ana ka luku ana; a e imi lakou i ka malu, aole ia.
26 Wàhálà lórí wàhálà yóò dé, ìdágìrì lórí ìdágìrì. Nígbà náà ni wọn yóò wá ìran lọ́dọ̀ wòlíì, ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ òfin yóò parun lọ́dọ̀ àlùfáà, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ràn yóò ṣègbé lọ́dọ̀ àwọn àgbàgbà.
E kau mai kekahi hewa maluna o kekahi hewa, a o kekahi lono maluna o kekahi lono; alaila e imi lakou i ka hihio o ke kaula, aka, e pau o ke kanawai mai ke kahuna aku, a me ka oleloao, mai na lunakahiko aku.
27 Ọba yóò ṣọ̀fọ̀, ọmọ-aládé yóò wà láìní ìrètí, ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yóò wárìrì. Èmi yóò ṣe é fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, èmi yóò ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìgbékalẹ̀ wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa.’”
E u no hoi ke alii, a e hoaahuia ke alii opiopio me ka neoneo ana, a e hoopilikiaia na lima o ko ka aina; a e hana aku au ia lakou mamuli o ko lakou mau aoao, a mamuli o ka lakou hana ana e hoopai aku ai au ia lakou; a e ike lakou owau no Iehova.

< Ezekiel 7 >