< Ezekiel 7 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
La parole de Yahvé me fut adressée, en ces termes:
2 “Ọmọ ènìyàn, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ilé Israẹli: “‘Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà!
« Toi, fils d'homme, le Seigneur Yahvé dit au pays d'Israël: C'est fini! La fin est arrivée aux quatre coins du pays.
3 Òpin tí dé sí ọ báyìí, èmi yóò sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, èmi yóò dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, èmi yóò sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.
Maintenant la fin est sur toi, et j'enverrai ma colère sur toi, et je te jugerai selon tes voies. Je ferai retomber sur vous toutes vos abominations.
4 Ojú mi kò ní i dá ọ sì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú; ṣùgbọ́n èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrín rẹ. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Mon œil ne vous épargnera pas, et je n'aurai pas de pitié; mais je ferai venir sur vous vos voies, et vos abominations seront au milieu de vous. Alors vous saurez que je suis Yahvé ».
5 “Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ibi! Ibi kan ṣoṣo. Kíyèsi, ó bọ̀ ní orí rẹ!
« Le Seigneur Yahvé dit: « Un désastre! Un désastre unique! Voici qu'il arrive.
6 Òpin ti dé! Òpin ti dé! Ó ti dìde lòdì sí ọ. Kíyèsi, ó ti dé!
La fin est venue. La fin est venue! Elle se réveille contre toi. Voici, elle arrive.
7 Ìparun ti dé sórí rẹ, ìwọ tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àkókò náà dé! Ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé! Kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.
Ta fin est arrivée, habitant du pays! L'heure est venue! Le jour est proche, jour de tumulte, et non de cris de joie, sur les montagnes.
8 Mo ṣetán láti tú ìbínú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gẹ́gẹ́ bí ìwà ìríra rẹ ni èmi yóò sì san án fún ọ.
Maintenant, je vais bientôt répandre sur toi ma fureur, accomplir ma colère contre toi, et te juger selon tes voies. Je ferai retomber sur toi toutes tes abominations.
9 Ojú mi kò ní i dá ọ sí, Èmi kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti fún gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrín rẹ. “‘Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé Èmi Olúwa lo kọlù yín.
Mon œil n'épargnera pas, et je n'aurai pas de pitié. Je vous punirai selon vos voies. Vos abominations seront au milieu de vous. Alors vous saurez que c'est moi, Yahvé, qui frappe.
10 “‘Ọjọ́ náà dé! Kíyèsi ó ti dé! Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tanná, ìgbéraga ti rúdí!
"'Voici le jour! Voici qu'il arrive! Ta malédiction est sortie. La verge a fleuri. L'orgueil a bourgeonné.
11 Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; ọ̀pá láti jẹ ẹni búburú ní ìyà. Kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kù, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí nínú ọrọ̀ wọn, kò sí ohun tí ó ní iye.
La violence s'est élevée en un bâton de méchanceté. Il ne restera rien d'eux, ni de leur multitude, ni de leurs richesses. Il n'y aura rien de précieux parmi eux.
12 Àkókò náà dé! Ọjọ́ náà ti dé! Kí òǹrajà má ṣe yọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ki òǹtajà má ṣe ṣọ̀fọ̀; nítorí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.
Le temps est venu! Le jour approche. Que l'acheteur ne se réjouisse pas, et que le vendeur ne se lamente pas, car la colère est sur toute sa multitude.
13 Nítorí pé òǹtajà kì yóò rí gbà padà dúkìá èyí tó tà níwọ̀n ìgbà ti àwọn méjèèjì bá wà láààyè. Nítorí ìran tó kan gbogbo ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.
Car le vendeur ne reviendra pas à ce qui est vendu, bien qu'ils soient encore en vie; car la vision concerne toute sa multitude. Nul ne reviendra. Nul ne se fortifiera dans l'iniquité de sa vie.
14 “‘Wọ́n ti fọn ìpè ogun, tí wọ́n sì pèsè ohun gbogbo sílẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò lọ ojú ogun, nítorí ìbínú gbígbóná mi ti wà lórí gbogbo ènìyàn.
Ils ont sonné de la trompette et se sont préparés; mais personne ne va au combat, car ma colère s'abat sur toute sa multitude.
15 Idà wà ní ìta, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn wà nílé, idà yóò pa ẹni tó bá wà ní orílẹ̀-èdè, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn yóò pa ẹni tó bá wà ní ìlú.
"'L'épée est au dehors, la peste et la famine au dedans. Celui qui est dans les champs mourra par l'épée. Celui qui est dans la ville sera dévoré par la famine et la peste.
16 Gbogbo àwọn tí ó bọ́ nínú wọn yóò sálà, wọn yóò sì wà lórí òkè. Bí i àdàbà inú àfonífojì, gbogbo wọn yóò máa ṣọ̀fọ̀, olúkúlùkù nítorí àìṣedéédéé rẹ̀.
Mais ceux qui échapperont, ils s'échapperont et seront sur les montagnes comme les colombes des vallées, tous gémissant, chacun dans son iniquité.
17 Gbogbo ọwọ́ yóò rọ, gbogbo orúnkún yóò di aláìlágbára bí omi.
Toutes les mains seront affaiblies, et tous les genoux seront faibles comme de l'eau.
18 Wọn yóò wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ̀rù yóò sì bò wọ́n mọ́lẹ̀, ìtìjú yóò mù wọn, wọn yóò sì fá irun wọn.
Ils se revêtiront de sacs, et l'horreur les couvrira. La honte sera sur tous les visages, et la calvitie sur toutes leurs têtes.
19 “‘Wọn yóò dà fàdákà wọn sí ojú pópó, wúrà wọn yóò sì dàbí èérí fàdákà àti wúrà wọn kò ní le gbà wọ́n ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná Olúwa. Wọn kò ní le jẹun tẹ́ ra wọn lọ́rùn tàbí kí wọn kún ikùn wọn pẹ̀lú oúnjẹ nítorí pé ó ti di ohun ìkọ̀sẹ̀ fún wọn.
Ils jetteront leur argent dans les rues, et leur or sera comme une chose impure. Leur argent et leur or ne pourront les délivrer au jour de la colère de Yahvé. Ils ne rassasieront pas leurs âmes et ne rempliront pas leurs ventres, car ils ont été la pierre d'achoppement de leur iniquité.
20 Wọ́n ń ṣe ìgbéraga pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ wọn tí ó lẹ́wà, wọn sì ti fi ṣe òrìṣà, wọn sì tún ya àwòrán ìríra wọn níbẹ̀. Nítorí náà, èmi yóò sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí di aláìmọ́ fún wọn.
Quant à la beauté de sa parure, il l'a placée dans la majesté; mais eux, ils y ont placé les images de leurs abominations et de leurs choses détestables. C'est pourquoi je l'ai rendu pour eux comme une chose impure.
21 Èmi yóò sì fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe ìjẹ fún àjèjì àti ìkógun fún àwọn ènìyàn búburú ayé, wọn yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́.
Je la livrerai aux mains des étrangers comme butin, et aux méchants de la terre comme pillage, et ils la profaneront.
22 Èmi yóò gbójú mi kúrò lára wọn, àwọn ọlọ́ṣà yóò sì sọ ibi ìṣúra mi di aláìmọ́; àwọn ọlọ́ṣà yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sì bà á jẹ́.
Je détournerai aussi ma face d'eux, et ils profaneront mon lieu secret. Des voleurs y entreront, et le profaneront.
23 “‘Rọ ẹ̀wọ̀n irin! Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún ẹ̀ṣẹ̀ ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìlú náà sí kún fún ìwà ipá.
"'Faites des chaînes, car le pays est plein de crimes sanglants, et la ville est pleine de violence.
24 Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè ti ó búburú jùlọ láti jogún ilé wọn. Èmi yóò sì fi òpin sí ìgbéraga àwọn alágbára, ibi mímọ́ wọn yóò sì di bíbàjẹ́.
C'est pourquoi je ferai venir les pires des nations, et elles posséderont leurs maisons. Je ferai aussi cesser l'orgueil des puissants. Leurs lieux saints seront profanés.
25 Nígbà tí ìpayà bá dé, wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.
La destruction arrive! Ils chercheront la paix, et il n'y en aura pas.
26 Wàhálà lórí wàhálà yóò dé, ìdágìrì lórí ìdágìrì. Nígbà náà ni wọn yóò wá ìran lọ́dọ̀ wòlíì, ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ òfin yóò parun lọ́dọ̀ àlùfáà, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ràn yóò ṣègbé lọ́dọ̀ àwọn àgbàgbà.
La calamité succédera à la calamité, et la rumeur à la rumeur. Ils chercheront la vision du prophète; mais la loi disparaîtra du sacrificateur, et le conseil des anciens.
27 Ọba yóò ṣọ̀fọ̀, ọmọ-aládé yóò wà láìní ìrètí, ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yóò wárìrì. Èmi yóò ṣe é fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, èmi yóò ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìgbékalẹ̀ wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa.’”
Le roi sera dans le deuil, et le prince sera revêtu de désolation. Les mains des habitants du pays seront troublées. Je les traiterai selon leur voie, et je les jugerai selon leurs propres jugements. Alors ils sauront que je suis Yahvé.'"

< Ezekiel 7 >