< Ezekiel 6 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
Pǝrwǝrdigarning sɵzi manga kelip mundaⱪ deyildi: —
2 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
I insan oƣli, Israilning taƣliriƣa yüzüngni ⱪaritip ularni ǝyiblǝp mundaⱪ dǝp bexarǝt bǝrgin: —
3 wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
«Israilning taƣliri, Rǝb Pǝrwǝrdigarning sɵzini anglap ⱪoyunglar: Rǝb Pǝrwǝrdigar taƣlar wǝ egizliklǝrgǝ, wadilar wǝ jilƣilarƣa mundaⱪ dǝydu: — Mana, Mǝn üstünglarƣa bir ⱪiliqni qüxürüp, «yuⱪiri jay»liringlarni wǝyran ⱪilimǝn.
4 Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
Xuning bilǝn silǝrning ⱪurbangaⱨliringlar wǝyranǝ bolidu, «kün tüwrük»liringlar buzulidu; silǝrdin ɵltürülgǝnlǝrni butliringlarning aldiƣa taxlaymǝn.
5 Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
Israillardin bolƣan ɵlüklǝrni ɵz butliri aldiƣa yatⱪuzimǝn; ⱪurbangaⱨliringlar ǝtrapiƣa ustihanlirini qeqiwetimǝn.
6 Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
Silǝr turƣan barliⱪ jaylarda xǝⱨǝrlǝr yǝr bilǝn yǝksan ⱪilinidu, «yuⱪiri jaylar» wǝyranǝ bolidu; xuning bilǝn ⱪurbangaⱨliringlar ⱨalak bolidu, butliringlar qeⱪilip yoⱪilidu, «kün tüwrük»liringlar kesilip ƣulitilidu, wǝ ⱨǝmmǝ yasiƣininglar yoⱪ ⱪiliwetilidu;
7 Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Wǝ ɵltürülgǝnlǝr aranglarda yiⱪilixi bilǝn, silǝr Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni tonup yetisilǝr.
8 “‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
Biraⱪ Mǝn silǝrdin bir ⱪaldini ⱪaldurimǝn; qünki yat mǝmlikǝtlǝrgǝ tarⱪitiwetilgininglarda, silǝrdin ǝllǝr arisida ⱪiliqtin ⱪutulup ⱪalƣanlar bolidu.
9 Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
Wǝ silǝrdin [ⱪiliqtin] ⱪutulup ⱪalƣanlar sürgün ⱪilinƣan mǝmlikǝtlǝrdǝ Mǝndin yanƣan wapasiz ⱪǝlbliri wǝ butliriƣa paⱨixiwazlardǝk ⱨǝwǝs ⱪilƣan kɵzliri bilǝn baƣrimni parǝ-parǝ ⱪilƣanliⱪini esigǝ kǝltüridu; xuning bilǝn ular ⱪilƣan rǝzillikliri ⱨǝm yirginqlik ⱪilmixliri tüpǝylidin ɵz-ɵzliridin nǝprǝtlinidu.
10 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
Wǝ ular Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni tonup yetidu; Mǝn muxu külpǝtni silǝrning bexinglarƣa qüxürimǝn degǝnlikim bikardin-bikar ǝmǝs».
11 “‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — «Aliⱪiningni-aliⱪiningƣa urup, putung bilǝn yǝrni tǝpkin: «Israil jǝmǝtining barliⱪ ⱪǝbiⱨ, yirginqlik ⱪilmixliri üqün way! Qünki ular ⱪiliq, aqarqiliⱪ wǝ waba kesili bilǝn yiⱪilidu» — degin!
12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
Yiraⱪta turƣan wabadin ɵlidu; yeⱪinda turƣan ⱪiliq bilǝn yiⱪilidu; ⱨǝm tirik ⱪalƣan, yǝni muⱨasirigǝ qüxkǝn kixi aqarqiliⱪtin ɵlidu; xuning bilǝn mening ularƣa bolƣan ⱪǝⱨrimni qüxürüp piƣandin qiⱪimǝn.
13 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
Əmdi ulardin ɵltürülgǝnlǝr ɵz butliri arisida, ularning ⱪurbangaⱨliri ǝtrapida, ɵz butliriƣa huxbuy yaⱪⱪan ⱨǝr bir egiz dɵng üstidǝ, taƣ qoⱪⱪilirida, barliⱪ yexil dǝrǝh wǝ baraⱪsan dub astida yatⱪan qaƣda, ular Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni tonup yetidu.
14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Wǝ Mǝn Ɵz ⱪolumni ularning üstigǝ sozimǝn, ular ⱨǝr turƣan jaylirida zeminni Diblattiki qɵl-bayawandin bǝttǝr wǝyran ⱪiliwetimǝn. Andin ular Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni tonup yetidu».

< Ezekiel 6 >