< Ezekiel 6 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
K meni je prišla Gospodova beseda, rekoč:
2 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
»Človeški sin, naravnaj svoj obraz proti Izraelovim goram in prerokuj zoper njih
3 wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
in reci: ›Ve Izraelove gore, poslušajte besedo Gospoda Boga: ›Tako govori Gospod Bog goram in hribom, rekam in dolinam: ›Glejte jaz, celó jaz, bom nad vas privedel meč in uničil bom vaše visoke kraje.
4 Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
Vaši oltarji bodo zapuščeni in vaši kipi bodo razbiti, in jaz bom vrgel dol vaše umorjene ljudi pred vaše malike.
5 Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
Mrtva trupla Izraelovih otrok bom položil pred njihove malike in vaše kosti bom raztrosil okoli vaših oltarjev.
6 Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
V vseh vaših bivališčih bodo mesta opustošena in visoki kraji bodo zapuščeni, da bodo vaši oltarji lahko opustošeni in zapuščeni in bodo vaši maliki lahko razbiti in prenehali [obstajati] in bodo vaše podobe lahko posekane in bodo vaša dela lahko odpravljena.
7 Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Umorjeni bodo padli v vaši sredi in spoznali boste, da jaz sem Gospod.
8 “‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
Vendar bom pustil ostanek, da boste lahko imeli nekatere, ki bodo pobegnili meču med narodi, ko boste razkropljeni po deželah.
9 Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
Tisti izmed vas, ki pobegnejo, se me bodo spomnili med narodi, kamor bodo odvedeni ujetniki, kajti zlomljen sem z njihovim vlačugarskim srcem, ki je odšlo od mene in z njihovimi očmi, ki se gredo vlačugat za njihovimi maliki in gnusili se bodo samim sebi zaradi zla, ki so ga zagrešili pri vseh svojih ogabnostih.
10 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
In spoznali bodo, da jaz sem Gospod in da nisem zaman rekel, da jim bom storil to zlo.‹«
11 “‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
Tako govori Gospod Bog: »Udari s svojo roko in zatopotaj s svojim stopalom ob tla ter reci: ›Ojoj za vse zle ogabnosti Izraelove hiše! Kajti padli bodo pod mečem, od lakote in kužne bolezni.
12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
Kdor je daleč, bo umrl od kužne bolezni, in kdor je blizu, bo padel pod mečem, in kdor preostaja in je oblegan, bo umrl od lakote. Tako bom nad njimi dovršil svojo razjarjenost.
13 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
Potem boste vedeli, da jaz sem Gospod, ko bodo njihovi pobiti ljudje [ležali] med njihovimi maliki, naokoli njihovih oltarjev, na vsakem visokem hribu, po vseh vrhovih gora in pod vsakim zelenim drevesom in pod vsakim debelim hrastom, [na] kraju, kjer so vsem svojim malikom darovali prijetno dišavo.
14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Tako bom svojo roko iztegnil nadnje in njihovo deželo naredil zapuščeno, da, bolj zapuščeno kakor divjino proti Dibli, v vseh njihovih prebivališčih, in spoznali bodo, da jaz sem Gospod.‹«

< Ezekiel 6 >