< Ezekiel 6 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
2 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
Synu człowieczy, zwróć swoją twarz ku górom Izraela i prorokuj przeciwko nim;
3 wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
I mów: Góry Izraela, słuchajcie słowa Pana BOGA. Tak mówi Pan BÓG do gór i pagórków, do strumieni i dolin: Oto ja, właśnie ja sprowadzę na was miecz i zniszczę wasze wyżyny.
4 Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
Wasze ołtarze będą spustoszone i wasze posągi będą połamane, a porozrzucam waszych pobitych przed waszymi bożkami.
5 Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
Trupy synów Izraela położę przed ich bożkami i rozrzucę wasze kości wokół waszych ołtarzy.
6 Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
Wszędzie, gdzie mieszkacie, miasta zostaną spustoszone i wyżyny spustoszeją, tak że wasze ołtarze będą zburzone i zniszczone, wasze bożki będą rozbite i przestaną istnieć, wasze posągi będą wycięte, a wasze dzieła wyniszczone.
7 Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
I pobici padną pośród was, a poznacie, że ja jestem PANEM.
8 “‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
Lecz pozostawię niektórych spośród was, którzy ujdą spod miecza pogan, gdy będziecie rozproszeni po krajach.
9 Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
Ci z was, którzy ocaleją, będą o mnie pamiętać pośród narodów, do których zostaną uprowadzeni, bo ubolewam nad ich cudzołożnym sercem, które odstąpiło ode mnie, i nad ich oczami, które uprawiały nierząd, idąc za swymi bożkami. I poczują wstręt do samych siebie z powodu zła, które popełnili we wszystkich swoich obrzydliwościach.
10 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
I poznają, że ja [jestem] PANEM i że nie na próżno mówiłem, że sprowadzę na nich to nieszczęście.
11 “‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
Tak mówi Pan BÓG: Klaśnij swą dłonią, tupnij swą nogą i mów: Biada z powodu wszystkich złych obrzydliwości domu Izraela! Padną bowiem od miecza, od głodu i od zarazy.
12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
Ten, co będzie daleko, umrze od zarazy, ten, co blisko, polegnie od miecza, a ten, co pozostanie i będzie oblężony, umrze od głodu. Tak dopełnię na nich swej zapalczywości.
13 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
Wtedy poznacie, że ja jestem PANEM, gdy ich pobici będą leżeli wśród ich bożków i dokoła ich ołtarzy, na każdym wysokim pagórku, po wszystkich szczytach górskich, pod każdym drzewem zielonym i pod każdym rozłożystym dębem, gdzie składali miłą woń wszystkim swoim bożkom.
14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Wyciągnę swoją rękę przeciwko nim i uczynię tę ziemię spustoszoną, bardziej spustoszoną od pustyni Diblat, wszędzie, gdzie mieszkają. I tak poznają, że ja jestem PANEM.

< Ezekiel 6 >