< Ezekiel 6 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
2 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
Synu człowieczy! obróć twarz twoję ku górom Izraelskim, a prorokuj przeciwko nim,
3 wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
I rzecz: Góry Izraelskie! słuchajcie słowa panującego Pana. Tak mówi panujący Pan górom i pagórkom, strumieniom i dolinom: Oto Ja, Ja przywiodę na was miecz, i pokażę wyżyny wasze.
4 Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
A tak spustoszone będą ołtarze wasze, i zdruzgotane będą słoneczne obrazy wasze, a porozrzucam pobitych waszych przed plugawemi bałwanami waszemi.
5 Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
Położę też trupy synów Izraelskich przed plugawemi bałwanami ich, a rozrzucę kości wasze około ołtarzów waszych.
6 Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
Po wszystkich mieszkaniach waszych miasta spustoszone będą, i wyżyny spustoszeją, tak, iż będą skażone i rozwalone ołtarze wasze, zdruzgotane będą, i ustaną plugawe bałwany wasze, a będą podrąbione słoneczne obrazy wasze, a tak wygładzone będą dzieła wasze.
7 Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
I padnie zraniony w pośrodku was, a poznacie, żem Ja Pan.
8 “‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
Wszakże z was niektórych pozostawię, którzyby uszli miecza między poganami, gdy rozproszeni będziecie po ziemiach.
9 Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
I wspomną na mię, którzy z was zachowani będą między narodami, u krórych będą w pojmaniu, żem ubolewał nad sercem ich wszetecznem, które odstąpiło odemnie, i nad oczyma ich, które nierząd płodziły, chodząc za plugawemi bałwanami swojemi: i omierzną sami sobie dla złości, które czynili we wszystkich obrzydliwościach swoich.
10 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
I poznają, żem Ja Pan, a iżem nie darmo mówił, że na nich to złe przywiodę.
11 “‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
Tak mówi panujący Pan: Klaśnij ręką twoją, a tąpnij nogą twoją, i mów: Niestetyż na wszystkie złe obrzydliwości domu Izraelskiego; bo od miecza, od głodu, od morowego powietrza polegną.
12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
Ten, co będzie daleko, morem umrze, a ten, co blisko, od miecza polegnie, a ten, co zostanie, i oblężony, od głodu umrze; a tak wykonam popędliwość moję nad nimi.
13 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
Tedy poznacie, żem Ja Pan, gdy będą pobici ich leżeli w pośrodku plugawych bałwanów ich, i około ołtarzów ich, na każdym pagórku wysokim, po wszystkich wierzchach gór, i pod każdem drzewem zielonem, i pod każdym dębem krzewistym, na któremkolwiek miejscu sprawowali wonność wdzięczną wszystkim plugawym bałwanom swoim.
14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Bo rękę swoję wyciągnę przeciwko nim, i uczynię tę ziemię spustoszoną i bardziej spustoszoną niż pustynię Dyblat, we wszystkich mieszkaniach ich. A tak poznają, żem Ja Pan.

< Ezekiel 6 >