< Ezekiel 6 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
És lőn az Úrnak szava én hozzám, mondván:
2 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
Embernek fia, vesd tekintetedet Izráel hegyeire, és prófétálj ellenök:
3 wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
És mondjad: Izráel hegyei, halljátok meg az Úr Isten beszédét! Ezt mondja az Úr Isten a hegyeknek és a halmoknak, a mélységeknek és a völgyeknek: Ímé én fegyvert hozok reátok, és elvesztem a ti magaslataitokat.
4 Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
És elpusztulnak oltáraitok, és összetörnek naposzlopaitok, és elhullatom sebesültjeiteket bálványaitok előtt.
5 Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
És vetem az Izráel fiainak holttesteit bálványaik elé, és szétszórom csontjaitokat oltáraitok körül.
6 Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
Minden lakóhelyeteken a városok elpusztuljanak, és a magaslatok elveszszenek, hogy elpusztuljanak és rommá legyenek oltáraitok, és törjenek össze és legyenek semmivé bálványaitok, és kivágattassanak naposzlopaitok, és eltöröltessenek csinálmányaitok.
7 Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
És elhulljon a sebesült közöttetek, hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Úr.
8 “‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
De maradékot hagyok, hogy legyenek közületek, a kik megmenekedtek a fegyvertől a pogányok közt, mikor szétszórattok a tartományokban.
9 Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
Akkor megemlékeznek én rólam menekültjeitek a pogányok közt, kik közé fogságba vitetének, mert megtörtem parázna szívöket, mely tőlem elszakadt, és bálványaikkal paráználkodó szemeiket, és megundorodnak önmagok előtt a gonoszságokért, melyeket cselekedtek minden útálatosságuk szerint;
10 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
És megismerik, hogy én vagyok az Úr: nem hiába mondottam, hogy megcselekszem velök e gonoszt.
11 “‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
Így szólt az Úr Isten: Csapj tenyeredbe, toppants lábaddal és mondd: Jaj az Izráel háza minden gonosz útálatosságáért, mert fegyver, éhség és döghalál miatt hullanak el;
12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
A ki messze van, döghalál miatt hal meg, a ki közel van, fegyver miatt esik el, és a ki megmaradt biztonságban, éhség miatt hal meg; és teljessé teszem búsulásomat rajtok.
13 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
És megtudjátok, hogy én vagyok az Úr, mikor sebesültjeik ott lesznek bálványaik között az ő oltáraik körül, minden magas halmon, minden hegyeknek tetein, minden zöld fa alatt és minden lombos terpentinfa alatt, a hol csak kedves illatot adának minden bálványaiknak.
14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Kinyújtom azért kezemet reájok, és teszem a földet kietlen pusztasággá, a pusztától fogva Dibláig minden lakóhelyökön, hadd tudják meg, hogy én vagyok az Úr!

< Ezekiel 6 >