< Ezekiel 6 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
La parole du Seigneur me fut adressée en ces termes:
2 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
"Fils de l’homme, tourne ta face vers les montagnes d’Israël et prophétise sur elles.
3 wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
Tu diras: Montagnes d’Israël, écoutez la parole du Seigneur Dieu! Ainsi parle le Seigneur Dieu aux montagnes et aux collines, aux torrents et aux vallées: Voici, je vais amener sur vous le glaive et je ruinerai vos hauts-lieux.
4 Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
Vos autels seront dévastés, vos statues solaires seront brisées, et je ferai tomber vos morts devant vos idoles.
5 Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
Et je mettrai les cadavres des enfants d’Israël devant leurs idoles et je disperserai vos ossements autour de vos autels.
6 Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
Dans tous vos établissements, les villes seront dévastées, et les hauts-lieux désolés, afin que soient ruinés et désolés vos autels, que soient brisées et anéanties vos idoles, que soient rasées vos statues solaires, et que soient effacées vos oeuvres.
7 Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Des morts tomberont au milieu de vous, et vous saurez que je suis le Seigneur.
8 “‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
Et si j’en épargne parmi vous qui échapperont au glaive parmi les nations, quand vous serez dispersés dans les pays,
9 Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
ces survivants parmi vous se souviendront de moi chez les nations où ils seront captifs, de moi qui aurai brisé leur coeur infidèle, qui s’est détourné de moi, et leurs yeux qui s’égaraient vers leurs idoles; et ils éprouveront le dégoût d’eux-mêmes à cause des méfaits qu’ils ont commis, par toutes leurs abominations.
10 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
Ils sauront que je suis le Seigneur, que je n’ai pas parlé en vain en les menaçant de ce malheur."
11 “‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
Ainsi a dit le Seigneur Dieu: "Frappe de la main et tape du pied et dis: "Hélas!" Au sujet de toutes les horreurs impies des gens de la maison d’Israël, qui tomberont par le glaive, par la famine et par la peste.
12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
Celui qui est loin mourra par la peste, celui qui est proche tombera sous le glaive, survivants et assiégés périront par la famine, et j’épuiserai ma fureur sur eux.
13 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
Et vous saurez que je suis le Seigneur, quand leurs cadavres seront couchés au milieu de leurs idoles, autour de leurs autels, sur chaque haute colline, sur toutes les cimes des montagnes, sous chaque arbre verdoyant et sous chaque chêne touffu, en tout endroit où ils offraient une odeur agréable à toutes leurs idoles.
14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
J’Étendrai ma main sur eux et je ferai du pays une solitude et une ruine pire que le désert de Diblat, partout où ils seront établis, et ils sauront que je suis l’Eternel."

< Ezekiel 6 >