< Ezekiel 6 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
I stalo se ke mně slovo Hospodinovo, řkoucí:
2 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
Synu člověčí, obrať tvář svou proti horám Izraelským, a prorokuj proti nim,
3 wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
A rci: Hory Izraelské, slyšte slovo Panovníka Hospodina: Takto praví Panovník Hospodin horám a pahrbkům, prudkým potokům a údolím: Aj, já, já uvedu na vás meč, a zkazím výsosti vaše.
4 Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
A tak zpustnou oltářové vaši, a ztroskotáni budou sluneční obrazové vaši, a rozmeci zbité vaše před ukydanými bohy vašimi.
5 Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
Povrhu také mrtvá těla synů Izraelských před ukydanými bohy jejich, a rozptýlím kosti vaše okolo oltářů vašich.
6 Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
Kdekoli bydliti budete, města zpuštěna budou, a výsosti zpustnou. Pročež popléněni budou a zpustnou i oltářové vaši, potroskotáni budou a přestanou ukydaní bohové vaši, a sluneční obrazové vaši zpodtínáni, a tak vyhlazena budou díla vaše.
7 Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
I padnou zbití u prostřed vás, a zvíte, že já jsem Hospodin.
8 “‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
A pozůstavím některé z vás, kteříž by ušli meče, mezi pohany, když rozptýleni budete do zemí.
9 Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
I budou se rozpomínati na mne, kteříž z vás zachováni budou mezi národy, mezi něž budou zajati, že jsem kormoucen byl srdcem jejich smilným, kteréž odstoupilo ode mne, a očima jejich, kteréž smilníce, chodily za ukydanými bohy svými, a tak sami se býti hodné ošklivosti seznají pro nešlechetnosti, kteréž páchali ve všech ohavnostech svých.
10 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
A zvědí, že já jsem Hospodin, a že jsem ne nadarmo mluvil, že na ně uvedu zlé toto.
11 “‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
Takto praví Panovník Hospodin: Tleskni rukou svou, a dupni nohou svou, a rci: Nastojte na dům Izraelský, že pro všecky ohavnosti nejhorší mečem, hladem a morem padnouti mají.
12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
Ten, kdož daleko bude, morem umře, a kdo blízko, mečem padne, ostatní pak a obležený hladem umře, a tak docela vyleji prchlivost svou na ně.
13 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
A zvíte, že já jsem Hospodin, když budou zbití jejich u prostřed ukydaných bohů jejich vůkol oltářů jejich, na všelikém pahrbku vysokém, na všech vrších hor, a pod všelikým dřevem zeleným, i pod všelikým dubem hustým, na kterémkoli místě obětovávali vůni libou všelikým ukydaným bohům svým.
14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Nebo vztáhnu ruku svou na ně, a učiním zemi tuto zpustlou, zpustlejší než poušť Diblat, po všech obydlích jejich. I zvědí, že já jsem Hospodin.

< Ezekiel 6 >