< Ezekiel 5 >

1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
А ти, сину лю́дський, візьми собі го́строго меча, як бритву стрижіїв; візьми його собі, і проведи ним по голові своїй та по бороді своїй. І візьми собі вагові́ ша́льки, і поділи те воло́сся.
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
Третину спали в огні посеред міста, коли ви́повняться дні обло́ги; і візьми другу третину, і посічи мечем навко́ло нього, а третину розпороши́ на вітер, і Я ви́тягну меча за ними.
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
І візьми звідти мале число воло́сся, і зав'яжи його в своїх по́лах.
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
І візьми із нього ще, і кинь його до сере́дини огню, і спали його в огні, — з нього вийде огонь на ввесь Ізраїлів дім“.
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
Так говорить Господь Бог: „Цей Єрусалим — Я поставив його в сере́дині народів, а довкі́лля його — країни.
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
Та він став проти постанов Моїх більше від пога́нів, а проти устав Моїх — більше від тих країн, що навколо нього, бо права́ Мої вони відкинули, а устави Мої — не ходили вони ними.
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
Тому́ так говорить Господь Бог: За те, що ви ворохо́билися більше від тих поган, що навколо вас, й уставами Моїми не ходили, і постанов Моїх не вико́нували, а робили за постановами тих поган, що навколо вас,
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
тому́ так говорить Господь Бог: Ось Я проти тебе, Сам Я, і зроблю́ серед тебе суди́ перед очи́ма тих поган!
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
І зроблю́ на тобі те, чого Я не робив, і нічого подібного вже не зроблю́, за гидо́ти твої.
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
Тому́ серед тебе батьки будуть їсти синів, а сини будуть їсти батьків своїх, і виконаю над тобою при́суди, і розпоро́шу ввесь останок твій на всі вітри́!
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
Тому, як живий Я, говорить Господь Бог, — за те, що ти занечи́стив святиню Мою всіма́ гидо́тами своїми та всіма́ обри́дженнями своїми, то теж Я відкину тебе, й око Моє не матиме милосердя, і Сам Я не змилосе́рджуся!
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
Третина твоя помре від морови́ці й загине від голоду серед тебе, а третина попа́дає від меча в твоїх околицях, а третину розпоро́шу на всі вітри́, і витягну за ними меча!
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
І докі́нчиться гнів Мій, і Я заспоко́ю Свою лють проти них, і задовольню́ся. І пізнають вони, що Я, Господь, говорив у горли́вості Своїй, коли докона́ю Свою лютість на них!
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
І зроблю́ тебе руїною та га́ньбою серед людів, що навколо тебе, перед очи́ма кожного, хто буде прохо́дити.
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
I стане ш га́ньбою та посміхо́виськом, осторогою та остовпі́нням для народів, що навколо тебе, коли буду виконувати на тобі при́суди гнівом та люттю, та лютими карта́ннями. Я, Господь, оце говорив!
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
Коли Я пошлю́ на них злі стрі́ли голоду, що будуть нищівни́ми, що пошлю́ їх понищити вас та примно́жу голод на вас, то Я злама́ю вам підпо́ру хліба, —
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
і пошлю на вас голод та злу звірину́, і позбавлю тебе дітей, і морови́ця та кров пере́йде серед тебе, і спрова́джу на тебе меча. Я, Господь, оце говорив!“

< Ezekiel 5 >