< Ezekiel 5 >

1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
Și tu, fiu al omului, ia-ți un cuțit ascuțit, ia-ți un brici de bărbier și fă-[l] să treacă pe capul tău și pe barba ta; apoi ia-ți balanțe de cântărit și împarte [părul.]
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
Să arzi cu foc a treia parte în mijlocul cetății, când zilele asediului se vor împlini; și să iei a treia parte [și] să o lovești împrejur cu un cuțit; și a treia parte să o împrăștii în vânt; și eu voi scoate o sabie după ei.
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
Tu de asemenea să iei de acolo puțini la număr și să îi legi în poalele [hainei] tale.
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
Apoi să iei din nou dintre ei și să îi arunci în mijlocul focului și să îi arzi în foc; [fiindcă] din el un foc va ieși la toată casa lui Israel.
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Acesta [este] Ierusalimul; eu l-am pus în mijlocul națiunilor și al țărilor [care sunt] în jurul lui.
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
Și [Ierusalimul] a schimbat judecățile mele în stricăciune mai mult decât națiunile și statutele mele mai mult decât țările care [sunt] în jurul lui, pentru că ei au refuzat judecățile mele [și] nu au umblat în statutele mele.
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pentru că ați făcut mai mult decât națiunile care [sunt] de jur împrejurul vostru [și] nu ați umblat în statutele mele, nici nu ați ținut judecățile mele, nici nu ați făcut conform cu judecățile națiunilor care [sunt] de jur împrejurul vostru;
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, eu, chiar eu, [sunt] împotriva ta și voi face judecăți în mijlocul tău, înaintea vederii națiunilor.
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
Și voi face în tine ceea ce nu am [mai] făcut și ce nu voi mai face la fel, din cauza tuturor urâciunilor tale.
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
De aceea părinții vor mânca pe fii în mijlocul tău și fiii vor mânca pe părinții lor; și eu voi face judecăți în tine și toată rămășița ta o voi împrăștia în toate vânturile.
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
Pentru aceea, [precum] eu trăiesc, spune Domnul DUMNEZEU: Într-adevăr, pentru că ai spurcat sanctuarul meu cu toate lucrurile tale detestabile și cu toate urâciunile tale, de aceea [te] voi micșora și eu; ochiul meu nu va cruța, nici nu voi avea vreo milă.
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
A treia parte din tine va muri de ciumă și cu foamete vor fi mistuiți în mijlocul tău; și a treia parte va cădea prin sabie de jur împrejurul tău; și voi împrăștia a treia parte în toate vânturile și voi scoate o sabie după ei.
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
Astfel mânia mea va fi împlinită și furia mea se va odihni asupra lor iar eu voi fi mângâiat; și ei vor cunoaște că eu, DOMNUL, am vorbit [aceasta] în zelul meu, când îmi voi fi împlinit furia în ei.
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
Mai mult, te voi face risipire și ocară printre națiunile care [sunt] de jur împrejurul tău, înaintea ochilor tuturor care trec pe lângă [tine].
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
Astfel, aceasta va fi o ocară și o batjocură, o instruire și o înmărmurire pentru națiunile care [sunt] de jur împrejurul tău, când voi face judecăți în tine în mânie și în furie și în mustrări furioase. Eu, DOMNUL, am vorbit [aceasta].
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
Când voi trimite asupra lor săgețile rele ale foametei, care vor fi pentru nimicirea [lor și] pe care le voi trimite pentru a vă nimici; și voi mări foametea asupra voastră și vă voi zdrobi toiagul pâinii;
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
Astfel voi trimite asupra voastră foamete și fiare rele și ele te vor văduvi; și ciuma și sângele vor trece prin tine; și voi aduce sabia asupra ta. Eu, DOMNUL, am vorbit [aceasta].

< Ezekiel 5 >