< Ezekiel 5 >

1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
Ty zaś, synu człowieczy, weź sobie ostry nóż, weź sobie brzytwę fryzjerską i ogól nią sobie głowę oraz brodę. Potem weź sobie wagę i rozdziel [włosy].
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
[Jedną] trzecią spal w ogniu w środku miasta, gdy wypełnią się dni oblężenia. Potem weź trzecią część i posiekaj mieczem dokoła, a trzecią część rozrzuć na wiatr, bo ja dobędę miecz na nich.
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
Ale weź z nich małą ilość i zawiń w poły swojej [szaty].
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
Z tych weź jeszcze [trochę], wrzuć je w środek ognia i spal je w ogniu; stamtąd wyjdzie ogień na cały dom Izraela.
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
Tak mówi Pan BÓG: To [jest] Jerozolima, którą umieściłem pośród pogan, otoczona zewsząd krajami.
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
Ale zamieniła moje sądy w niegodziwość, bardziej niż poganie, a moje ustawy – bardziej niż kraje, które ją otaczają. Wzgardzili bowiem moimi sądami i nie postępowali według moich ustaw.
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Ponieważ przewyższyliście swoimi [grzechami] pogan, którzy was otaczają, a nie postępowaliście według moich ustaw i nie przestrzegaliście moich sądów, nawet nie czyniliście według sądów pogan, którzy są dokoła was;
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Oto [występuję] przeciwko tobie i wykonam sądy pośrodku ciebie, na oczach pogan.
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
I z powodu wszystkich twoich obrzydliwości uczynię ci to, czego [wcześniej] nie uczyniłem, i czego już więcej nie uczynię.
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
Dlatego ojcowie będą jeść synów pośród ciebie, a synowie będą jeść swoich ojców. Wykonam sądy nad tobą i rozproszę całą twoją resztkę na wszystkie wiatry.
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
Dlatego jak żyję, mówi Pan BÓG: Ponieważ zbezcześciłeś moją świątynię wszelkimi twymi nieczystościami i wszelkimi twymi obrzydliwościami, ja także poniżę ciebie, moje oko nie oszczędzi [cię] i nie zlituję się [nad tobą].
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
Trzecia część twoich [ludzi] umrze od zarazy i wyginie z głodu pośród ciebie, trzecia część padnie od miecza wokół ciebie, a trzecią część rozproszę na wszystkie wiatry i miecz na nich dobędę.
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
Tak dopełni się mój gniew i natrę na nich swoją zapalczywością, i ucieszę się. I poznają, że ja, PAN, powiedziałem to w swojej zapalczywości, gdy wykonam na nich swój gniew.
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
I zamienię cię w spustoszenie i w hańbę narodów, które są wokoło ciebie, na oczach każdego przechodnia.
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
A tak staniesz się hańbą, pośmiewiskiem, przykładem i przerażeniem dla narodów, które cię otaczają, gdy wykonam na tobie sądy w zapalczywości i gniewie, i w srogich upomnieniach. Ja, PAN, [to] powiedziałem.
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
Gdy wypuszczę przeciw wam srogie strzały głodu, które będą [leciały] ku zniszczeniu, a które wypuszczę, aby was wyniszczyć, wzmogę głód przeciwko wam i zniszczę wasz zapas chleba.
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
Ześlę więc na was głód i okrutne zwierzęta, które cię osierocą. Przejdą przez ciebie zaraza i krew i sprowadzę na ciebie miecz. Ja, PAN, [to] powiedziałem.

< Ezekiel 5 >