< Ezekiel 5 >

1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
Potem ty, synu człowieczy! weźmij sobie nóż ostry, to jest brzytwę barwierską, weźmij ją sobie, a ogól nią głowę swoję i brodę swoję; potem weźmij sobie wagę, i rozdziel je.
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
Jednę trzecią część ogniem spal w pośród miasta, gdy się wypełnią dni oblężenia; potem wziąwszy drugą trzecią część, posiekaj mieczem około niego, a ostatnią trzecią część roztrząśnij na wiatr; bo miecza dobędę za nimi.
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
A wszakże weźmij z nich jaką trochę, i zawiąż w kraje szaty twojej.
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
A i z tych jeszcze wziąwszy wrzuć je w pośród ognia, i spal je w ogniu, skąd wynijdzie ogień na wszystek dom Izraelski.
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
Tak mówi panujący Pan: Toć jest Jeruzalem, którem postawił w pośród pogan, a zewsząd otoczył krainami;
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
Ale odmieniło sądy moje w niezbożność, bardziej niż poganie, a ustawy moje bardziej niż inne krainy, które są około niego; bo sądami mojemi pogardzili, i w ustawach moich nie chodzili.
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
Przetoż tak mówi panujący Pan: Dlatego, żeście pogaństwo grzechami przewyższyli, które jest około was, a w ustawach moich nie chodziliście, i sądów moich nie zachowaliście, nawet ani tak jako poganie, którzy są około was, sąduście nie czynili;
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
Przetoż tak mówi panujący Pan: Otom Ja przeciwko tobie, otom Ja, i wykonam w pośrodku ciebie sądy przed oczyma pogan;
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
Bo uczynię przy tobie to, czegom pierwej nie uczynił, i czego napotem nie uczynię dla wszystkich obrzydliwości twoich,
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
Tak, że ojcowie jeść będą synów w pośrodku ciebie, a synowie jeść będą ojców swoich; i wykonam sądy przeciwko tobie, a rozproszę wszystkie ostatki twoje na wszystkie strony.
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
Przetoż jako żyję Ja, mówi panujący Pan: Ponieważeś ty świątnicę moję splugawiło wszelakiemi nieczystościami twojemi, i wszelakiemi obrzydliwościami twemi, i Ja cię też podam w lekkość, a nie sfolgujeć oko moje, ani się zlituję.
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
Trzecia część z ciebie morem pomrze i głodem wyginie w pośrodku ciebie, a druga trzecia część od miecza padnie około ciebie, a trzecią ostatnią część na wszystkie strony rozproszę, i miecza dobędę za nimi.
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
A tak się do końca wyleje zapalczywość moja, i natrę popędliwością swoją na nich, i ucieszę się, i doznają, żem Ja Pan, którym to wyrzekł w zapalczywości mojej, gdy wypełnię gniew swój nad nimi.
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
A podam cię w spustoszenie i w pohańbienie narodom, które są około ciebie, przed oczyma każdego mijającego.
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
A tak będziesz na hańbę, na pośmiech, na srogi przykład i na zdumienie narodom, które są około ciebie, gdy wykonam przeciwko tobie sądy w popędliwości i w gniewie i w srogiem zagniewaniu. Ja Pan mówiłem.
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
Gdy wypuszczę srogie strzały głodu na zgubę waszę, które wypuszczę, abym was wygubił, a głód zgromadzę przeciwko wam, i złamię wam laskę chleba.
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
Poślę zaiste na was głód, i zwierzęta okrutne, które cię osierocą; i mór i krew przyjdzie na cię, gdy na cię miecz przywiodę. Ja Pan mówiłem.

< Ezekiel 5 >