< Ezekiel 5 >

1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
بگیر و آن را مثل استره حجام به جهت خود بکار برده، آن را بر سر و ریش خود بگذران وترازویی گرفته، مویها را تقسیم کن.۱
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
و چون روزهای محاصره را به اتمام رسانیده باشی، یک ثلث را در میان شهر به آتش بسوزان و یک ثلث راگرفته، اطراف آن را با تیغ بزن و ثلث دیگر را به بادها بپاش و من در عقب آنها شمشیری خواهم فرستاد.۲
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
و اندکی از آن را گرفته، آنها را در دامن خود ببند.۳
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
و باز قدری از آنها را بگیر و آنها را درمیان آتش انداخته، آنها را به آتش بسوزان وآتشی برای تمام خاندان اسرائیل از آن بیرون خواهد آمد.»۴
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
خداوند یهوه چنین می‌گوید: «من این اورشلیم را در میان امت‌ها قرار دادم و کشورها رابهر طرف آن.۵
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
و او از احکام من بدتر از امت‌ها واز فرایض من بدتر از کشورهایی که گرداگرد اومی باشد، عصیان ورزیده است زیرا که اهل او احکام مرا ترک کرده، به فرایض من سلوک ننموده‌اند.»۶
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
بنابراین خداوند یهوه چنین می‌گوید: «چونکه شما زیاده از امت هایی که گرداگرد شما می‌باشند غوغا نمودید و به فرایض من سلوک نکرده، احکام مرا بعمل نیاوردید، بلکه موافق احکام امت هایی که گرداگرد شما می‌باشندنیز عمل ننمودید،۷
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
لهذا خداوند یهوه چنین می‌گوید: من اینک من به ضد تو هستم و در میان تو به نظر امت‌ها داوریها خواهم نمود.۸
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
و با تو به‌سبب جمیع رجاساتت کارها خواهم کرد که قبل از این نکرده باشم و مثل آنها هم دیگر نخواهم کرد.۹
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
بنابراین پدران در میان تو پسران راخواهند خورد و پسران پدران خویش را خواهندخورد و بر تو داوریها نموده، تمامی بقیت تو رابسوی هر باد پراکنده خواهم ساخت.»۱۰
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
لهذاخداوند یهوه می‌گوید: «به حیات خودم قسم چونکه تو مقدس مرا بتمامی رجاسات و جمیع مکروهات خویش نجس ساختی، من نیز البته تورا منقطع خواهم ساخت و چشم من شفقت نخواهد نمود و من نیز رحمت نخواهم فرمود.۱۱
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
یک ثلث تو در میانت از وبا خواهند مرد و ازگرسنگی تلف خواهند شد. و یک ثلث به اطرافت به شمشیر خواهند افتاد و ثلث دیگر را بسوی هرباد پراکنده ساخته، شمشیر را در عقب ایشان خواهم فرستاد.۱۲
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
پس چون غضب من به اتمام رسیده باشد و حدت خشم خویش را بر ایشان ریخته باشم، آنگاه پشیمان خواهم شد. و چون حدت خشم خویش را بر ایشان به اتمام رسانده باشم، آنگاه خواهند دانست که من یهوه این را درغیرت خویش گفته‌ام.۱۳
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
و تو را در در نظر همه رهگذریان در میان امت هایی که به اطراف تومی باشند، به خرابی و رسوایی تسلیم خواهم نمود.۱۴
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
و چون بر تو به خشم و غضب وسرزنشهای سخت داوری کرده باشم، آنگاه این موجد عار و مذمت و عبرت و دهشت برای امت هایی که به اطراف تو می‌باشند خواهد بود. من که یهوه هستم این را گفتم.۱۵
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
و چون تیرهای بد قحطی را که برای هلاکت می‌باشد و من آنها رابه جهت خرابی شما می‌فرستم در میان شماانداخته باشم، آنگاه قحط را بر شما سخت‌ترخواهم گردانید و عصای نان شما را خواهم شکست.۱۶
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
و قحط و حیوانات درنده در میان توخواهم فرستاد تا تو را بی‌اولاد گردانند و وبا وخون از میان تو عبور خواهد کرد و شمشیری برتو وارد خواهم آورد. من که یهوه هستم این راگفتم.»۱۷

< Ezekiel 5 >