< Ezekiel 5 >
1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
Te pedig, ember fia, végy magadnak éles kardot, borbélyok borotvájául vedd magadnak, vezesd végig fejeden és szakálladon, erre végy magadnak mérőserpenyőket és osszad föl:
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
egyharmadot tűzben égess el a város közepén, amint letelnek az ostrom napjai, és végy egyharmadot és vagdald szét a karddal körülötte, egy harmadot pedig szórj a szélnek – és kardot fogok kirántani utánuk.
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
És végy onnan egy keveset és kösd be ruhád szögleteibe,
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
és abból végy ismét és vesd a tűzbe és égesd el a tűzben; ebből tűz fog eredni Izrael egész házára
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
Így szól az Úr, az Örökkévaló: Ez a Jeruzsálem -nemzetek közibe helyeztem, körülötte pedig országok;
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
de engedetlenkedett rendeleteim iránt, hogy gonoszabb legyen a nemzeteknél, és törvényeim iránt jobban a körülötte levő országoknál; mert rendeleteimet megvetették és törvényeim szerint nem jártak.
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
Azért így szól az Úr, az Örökkévaló: Mivelhogy engedetlenkedtetek, jobban a körülöttetek levő nemzeteknél, törvényeim szerint nem jártatok és rendeleteimet véghez nem vittétek, és a körülöttetek levő nemzetek rendeletei szerint sem cselekedtetek:
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
azért így szól az Úr, az Örökkévaló: íme ellened fordulok én is és végzek közepetted ítéleteket a nemzetek szeme láttára;
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
és cselekszem rajtad olyat, amit nem cselekedtem és amihez hasonlót nem fogok többé cselekedni mind a te utálatosságaid miatt.
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
Azért atyák gyermekeket fognak enni közepetted és a gyermekek atyáikat eszik meg; és végzek rajtad büntetést és minden szélnek elszórom minden maradékodat.
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
Azért ahogy élek, úgymond az Úr, az Örökkévaló, bizony mivel a szentélyemet megtisztátalanítottad mind a te undokságaiddal és mind a te utálatosságaiddal, én is elvonom a szememet, hogy ne sajnáljon és én sem könyörülök.
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
Harmadrészed dögvészben hal meg és éhségben semmisül meg közepetted, egy harmadrész kard által esik el körülötted; harmadrészt pedig minden szélnek szórok el és kardot rántok ki utánuk.
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
Akkor fogytáig dúl haragom és lecsillapítom rajtuk hevemet és megnyugtatom magamat; és megtudják, hogy én az Örökkévaló beszéltem buzgalmamban, midőn rajtuk bevégeztem hevemet.
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
És teszlek rommá és gyalázattá a körülötted levő nemzetek között, minden arra járónak szeme láttára
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
És így lesz gyalázás és káromlás, okulás és eliszonyodás a körülötted levő nemzeteknél, midőn végzek rajtad büntetést haraggal és hévvel és a hévnek fenyítéseivel; én az Örökkévaló beszéltem;
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
amikor az éhségnek rossz nyilait ellenük kibocsátom, amelyek pusztításra lesznek, amelyeket kibocsátok pusztítástokra; és éhséget tovább is hozok rátok, és eltöröm nálatok a kenyér pálcáját.
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
Bocsátok rátok éhséget és gonosz vadat; hogy gyermekeidtől fosszanak meg téged és dögvész meg vér átvonul rajtad, és kardot hozok rád. Én az Örökkévaló beszéltem.