< Ezekiel 5 >

1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
And thou, sone of man, take to thee a scharp swerd, schauynge heeris; and thou schalt take it, and schalt leede it bi thin heed, and bi thi berd. And thou schalt take to thee a balaunce of weiyte, and thou schalt departe tho.
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
Thou schalt brenne the thridde part with fier in the myddis of the citee, bi the fillyng of daies of bisegyng. And thou schalt take the thridde part, and schalt kitte bi swerd in the cumpas therof. But thou schalt scatere `the tother thridde part in to the wynd; and Y schal make nakid a swerd aftir hem.
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
And thou schalt take therof a litil noumbre, and thou schalt bynde tho in the hiynesse of thi mentil.
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
And eft thou schalt take of hem, and thou schalt caste forth hem in to the myddis of the fier. And thou schalt brenne hem in fier; and fier schal go out of that in to al the hous of Israel.
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
The Lord God seith these thingis, This is Jerusalem; Y haue sette it in the myddis of hethene men, and londis in the cumpas therof.
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
And it dispiside my domes, that it was more wickid than hethene men; and it dispiside my comaundementis more than londis that ben in the cumpas therof. For thei han cast awei my domes, and thei yeden not in my comaundementis.
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
Therfor the Lord God seith these thingis, For ye `han passid hethene men that ben in youre cumpas, and ye yeden not in my comaundementis, and ye diden not my domes, and ye wrouyten not bi the domes of hethene men that ben in youre cumpas;
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
therfor the Lord God seith these thingis, Lo! Y to thee, and Y my silf schal make domes in the myddis of thee, bifor the iyen of hethene men; and Y schal do thingis in thee,
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
whiche Y dide not, and to whiche Y schal no more make lijk thingis, for alle thin abhomynaciouns.
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
Therfor fadris schulen ete sones in the myddis of thee, and sones schulen ete her fadris; and Y schal make domes in thee, and Y schal wyndewe alle thin remenauntis in to ech wynd.
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
Therfor Y lyue, seith the Lord God, no but for that that thou defoulidist myn hooli thing in alle thin offenciouns, and in alle thin abhomynaciouns; and Y schal breke, and myn iye schal not spare, and Y schal not do merci.
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
The thridde part of thee schal die bi pestilence, and schal be wastid bi hungur in the middis of thee; and the thridde part of thee schal falle doun bi swerd in thi cumpas; forsothe Y schal scatere thi thridde part in to ech wynd, and Y schal drawe out a swerd after hem.
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
And Y schal fille my stronge veniaunce, and Y schal make myn indignacioun to reste in hem, and Y schal be coumfortid. And thei schulen wite, that Y the Lord spak in my feruent loue, whanne Y schal fille al myn indignacioun in hem.
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
And Y schal yyue thee in to desert, in to schenschipe to hethene men that ben in thi cumpas, in the siyt of ech that passith forth.
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
And thou schalt be schenschipe `and blasfemye, ensaumple and wondryng, among hethene men that ben in thi cumpas, whanne Y schal make domes in thee, in strong veniaunce, and indignacioun, and in blamyngis of ire.
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
Y the Lord haue spoke, whanne Y schal sende in to hem the worste arowis of hungur, that schulen bere deth; and whiche Y schal sende, that Y leese you. And Y schal gadere hungur on you, and Y schal al to-breke in you the sadnesse of breed.
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
And Y schal sende in to you hungur, and worste beestis, til to the deth; and pestilence and blood schulen passe bi thee, and Y schal bringe in swerd on thee; Y the Lord spak.

< Ezekiel 5 >