< Ezekiel 5 >

1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
Kami capa, haikaek kanoe to la ah, sam aatkung ih haita kanoe to lah loe, na lu hoi toektaboe mui to aah hanah patoh ah; to pacoengah kazit to coi tah ah loe, sam to tapraek ah.
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
Vangpui takuihaih ni koep naah, sam ahmuen thumto thungah ahmuen maeto la ah loe, vangpui thungah hmai hoi thlaek ah; ahmuen thumto thungah ahmuen maeto haita hoi takroek pet loe, ahmuen thumto thungah ahmuen maeto takhi thungah haeh ah; to sam to ka patomh moe, sumsen hoiah ka boeng han.
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
Sam to zetta ah la ah loe, laprawn hoiah tapawk ah.
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
Lak pacoengah, hmai thungah va ah loe, hmai kangsak ah; to hmai loe Israel imthung takohnawk boih khaeah pha tih.
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
Angraeng Sithaw mah, Hae loe Jerusalem ni; vangpui taengah kaom prae kaminawk hoi prae congcanawk salakah anih to ka suek.
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
Toe Jerusalem loe ka lok takroekhaih to zaesakhaih bangah paqoi lat, a taengah kaom prae kaminawk hoi prae congcanawk pong kanung kue ah, ka paek ih lok to aek o; ka lok takroekhaih to pahnawt o moe, ka paek ih loknawk baktiah caeh o ai.
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
To pongah Angraeng Sithaw mah, Na sak o ih zaehaih loe a taeng ih prae kaminawk hoi prae congcanawk mah sak ih zaehaih pongah pop kue, kang paek ih kaalok baktiah na caeh o ai, ka lok takroekhaih doeh na pazui o ai; na taengah kaom prae kaminawk ih khosakhaih dan baktiah doeh na caeh o ai, tiah thuih.
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
To pogah Angraeng Sithaw mah, Khenah, Kai loe na misa ah ka oh moe, prae congca kaminawk hmaa ah lok kang caek han.
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
Panuet thok hmuen to na sak o pongah, ka sak vai ai ih hmuen, lokcaek vai ai ih lokcaekhaih to ka sak han.
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
To pongah nangmacae hmaa roe ah ampanawk mah a caanawk to caa o ueloe, a caanawk mah ampanawk to caa o tih; nangcae to lok kang caek moe, kanghmat kaminawk to takhi nuiah ka haeh han.
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
Kahing Sithaw mah, Kai ka hing baktih toengah, panuet thok hmuennawk hoi kai ih hmuenciim to nam hnong o sak boeh pongah, kai mah doeh kang paawt mak ai, kang tahmen o mak ai ueloe, kang pathlung o mak ai boeh.
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
Nangcae thung ih kami ahmuen thumto thungah ahmuen maeto loe, nathaih kasae, khokhaahaih hoiah dueh o tih; na taeng ih kami ahmuen thumto thungah ahmuen maeto loe sumsen hoiah dueh o tih; ahmuen thumto thungah ahmuen maeto loe sumsen hoiah ka patom moe, takhi nuiah kang haehsak phaeng han.
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
To tiah ni palung ka phuihaih dip tih, palung ka phuihaih nihcae nuiah kam tiik pacoengah ni, ka poekhaih mong vop tih; palung ka phuihaih nihcae nuiah ka koepsak pacoengah loe, Kai, Angraeng loe a thuih ih lok baktiah sak tangtang, tiah nihcae mah panoek o tih.
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
To pacoengah a taengah caeh kaminawk hmaa ah, nang to kam rosak moe, ataeng kaminawk pahnui thuih hanah kang ohsak han.
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
Palungphuihaih, palungbethaih hoiah kang thuitaek o naah, nangcae loe a taengah kaom prae kaminawk kasae thuihaih, acoehaih hoi dawnrai paekkung ah na om o tih. Angraeng, Kai mah to tiah lok ka thuih boeh.
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
Nangcae paduekkung, khokhahaih ah kaom kahoih ai palaa to, nangcae khaeah kang patoeh han; to naah nangcae nuiah khokhahaih to kang pungsak moe, takaw paekhaih doeh kang pakha pae ving han.
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
Nangcae pacaekthlaek hanah, khokhahaih hoi moi kasannawk to kang patoeh han; nangmah thung hoiah athii longhaih hoi nathaih kasae to tacawt tih, nangcae tuk hanah sumsen to ka sin han, tiah thuih. Angraeng, Kai mah to tiah lok ka thuih boeh.

< Ezekiel 5 >