< Ezekiel 47 >

1 Ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí àbáwọlé tẹmpili náà, mo sì rí omi tí ó ń tú jáde láti abẹ́ ìloro tẹmpili náà sí apá ìhà ìlà-oòrùn (nítorí tẹmpili náà dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn). Omi náà ń tú jáde sí ìsàlẹ̀ láti abẹ́, ní ìhà gúúsù tẹmpili náà, ní ìhà gúúsù pẹpẹ.
Potom přivedl mne zase ke dveřím domu, a aj, vody vycházely od spodku prahu domu na východ; nebo přední strana domu k východu byla, a vody scházely pozpodu po pravé straně domu, po straně polední oltáře.
2 Ó wá mú mi gba ojú ọ̀nà àríwá jáde, ó sì mú mi yí ìta ojú ọ̀nà ìta tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn, omi náà sì ń sàn láti ìhà gúúsù wá.
Odtud mne vyvedl cestou brány půlnoční, a obvedl mne cestou zevnitřní k bráně zevnitřní, cestou, kteráž patří k východu, a aj, vody vyplývaly po pravé straně.
3 Bí ọkùnrin náà ti lọ sí apá ìhà ìlà-oòrùn pẹ̀lú okùn wíwọ̀n nǹkan lọ́wọ́ rẹ̀, ó wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́, ó sì mú mi gba ibi odò kan tí kò jì jù kókósẹ̀ lọ.
Když pak vycházel ten muž k východu, v jehož rukou míra, i naměřil tisíc loket, a provedl mne skrze vodu, vodu do kůtků.
4 Ó sì wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ó sì mú mi gba ibi odò tí ó jì ní ìwọ̀n orúnkún. Ó tún wọn ẹgbẹ̀rún márùn-ún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ó sì mú mi gba odò tí ó dé ìbàdí.
Potom naměřiv tisíc, provedl mne skrze vodu, vodu do kolenou; ještě naměřiv tisíc, provedl mne vodou do pasu.
5 Ó wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ṣùgbọ́n nísinsin yìí odò tí ń kò lè kọjá rẹ̀ ni, nítorí pé odò tí ó kún, ó sì jì tó èyí tí wọ́n le lúwẹ̀ẹ́ nínú rẹ̀ odò tí ẹnikẹ́ni kò le dá kọjá ni.
Opět když naměřil tisíc, byl potok, kteréhož jsem nemohl přebřísti; nebo vyzdvihly se vody, vody, přes něž by se musilo plynouti, potok, kterýž by nemohl přebředen býti.
6 Ó bi mí léèrè pé, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ o rí èyí?” Lẹ́yìn náà, ó mú mi padà sí etí odò.
Tedy řekl mi: Viděl-lis, synu člověčí? I vedl mne, a posadil mne na břeh toho potoka.
7 Nígbà tí mo dé ibẹ̀, mo rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì odò.
Když jsem se pak obrátil, aj, na břehu toho potoka bylo dříví velmi veliké po obou stranách.
8 Ó sọ fún mi pé, “Odò yìí ń tú jáde sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì wọ inú Òkun lọ, a sì mú omi wọn láradá.
I řekl mi: Vody tyto vycházejí od Galilee první, a sstupujíce po rovině, vejdou do moře, a když do moře vpadnou, opraví se vody.
9 Àwọn ohun alààyè tí ó ń rákò yóò máa gbé ní ibikíbi tí odò ti ń sàn. Ẹja yóò pọ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀, nítorí pé odò ń sàn síbẹ̀, ó sì mú kí omi iyọ̀ tutù nini; nítorí náà níbi tí omi ti ń sàn, gbogbo nǹkan ni yóò wà ni ààyè.
I stane se, že každý živočich, kterýž se plazí, všudy, kamžkoli přijdou potokové, ožive, a bude ryb velmi mnoho, proto že když přijdou tam tyto vody, očerstvějí, a živy budou všudy, kdežkoli dojde tento potok.
10 Àwọn apẹja yóò dúró ní etí bèbè odò; láti En-Gedi títí dé En-Eglaimu ààyè yóò wa láti tẹ́ àwọ̀n wọn sílẹ̀. Oríṣìíríṣìí ẹja ni yóò wà gẹ́gẹ́ bí ẹja omi Òkun ńlá.
Stane se i to, že se postaví podlé něho rybáři od Engadi až do studnice Eglaim; budou tu rozstírány síti. Podlé rozličnosti své bude ryb jejich, jako ryb moře velikého, velmi mnoho.
11 Ṣùgbọ́n ẹrẹ̀ àti àbàtà kò ní tòrò; àwa yóò fi wọn sílẹ̀ fún iyọ̀.
Bahna a louže jeho, kteréž se neopraví, soli oddány budou.
12 Àwọn igi eléso ní oríṣìíríṣìí ni yóò máa hù ní bèbè odò ní ìhà ìhín àti ní ìhà ọ̀hún. Ewé wọn kì yóò sì rọ, bẹ́ẹ̀ ní èso wọn kì yóò run, wọn yóò máa ṣe èso tuntun rẹ̀ ní oṣù nítorí pé omi láti ibi mímọ́ ń sàn sí wọn. Èso wọn yóò sì jẹ́ fún jíjẹ àti ewé wọn fún ìwòsàn.”
Při potoku pak poroste na břehu jeho po obou stranách všelijaké dříví ovoce nesoucí, jehož list neprší, aniž ovoce jeho přestává, v měsících svých nese prvotiny; nebo vody jeho z svatyně vycházejí, protož ovoce jeho jest ku pokrmu, a lístí jeho k lékařství.
13 Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ̀nyí ni àwọn ààlà tí ìwọ yóò fi pín ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ogún ìní ní àárín àwọn ẹ̀yà méjìlá Israẹli, pẹ̀lú ìpín méjì fún Josẹfu.
Takto praví Panovník Hospodin: Totoť jest obmezení, v němž sobě dědičně přivlastníte zemi po pokoleních Izraelských dvanácti; Jozefovi dva provazcové.
14 Ìwọ yóò pín ilẹ̀ náà déédé ní àárín wọn. Nítorí pé mo búra nípa nína ọwọ́ sókè láti fi fún àwọn baba ńlá yin, ilẹ̀ yìí yóò di ogún ìní yín.
Dědičně, pravím, jí vládnouti budete, jeden rovně jako druhý, o níž přisáhl jsem, že ji dám otcům vašim. I připadne vám země tato v dědictví.
15 “Èyí yìí ni yóò jẹ́ ààlà ilẹ̀ náà: “Ní ìhà àríwá yóò lọ láti omi Òkun ńlá ní ibi ọ̀nà Hetiloni gbà tí Hamati lọ sí Sedadi,
Toto jest tedy pomezí té země: K straně půlnoční od moře velikého cestou Chetlonu, kudyž se vchází do Sedad,
16 Berota àti Sibraimu, èyí tí ó wà ní ààlà láàrín Damasku àti Hamati títí dé Hasari Hatikonu, èyí tí ó wà ní agbègbè Haurani.
Emat, Berota, Sibraim, kteříž jsou mezi pomezím Damašským, a mezi pomezím Emat, vsi prostřední, kteréž jsou při pomezí Chavrón.
17 Ààlà yóò fẹ̀ láti Òkun lọ sí Hasari Enanu, ní apá ààlà ti Damasku, pẹ̀lú ààlà tí Hamati lọ sí apá àríwá. Èyí ni yóò jẹ́ ààlà ní apá ìhà àríwá.
A tak bude pomezí od moře Azar Enon, pomezí Damašek, a půlnoční strana na půlnoci, a pomezí Emat. A to jest strana půlnoční.
18 Ní ìhà ìlà-oòrùn ààlà yóò wá sí àárín Haurani àti Damasku, lọ sí apá Jordani láàrín Gileadi àti ilẹ̀ Israẹli, títí dé Òkun, àti títí dé Tamari. Èyí ní yóò jẹ́ ààlà ìlà-oòrùn.
Strana pak východní mezi Chavrón a mezi Damaškem, a mezi Galád, a mezi zemí Izraelskou při Jordánu; od toho pomezí při moři východním měřiti budete. A toť jest strana východní.
19 Ní ìhà gúúsù yóò lọ láti Tamari títí dé ibi omi Meriba Kadeṣi, lẹ́yìn náà ni ìhà Wadi tí Ejibiti lọ sí Òkun ńlá. Èyí ni yóò jẹ́ ààlà gúúsù.
Strana pak polední na poledne, od Támar až k vodám sváru v Kádes, od potoka až k moři velikému. A to jest strana polední na poledne.
20 Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, Òkun ńlá ni yóò jẹ́ ààlà títí dé ibi kan ni òdìkejì lẹ́bàá Hamati. Èyí yìí ni yóò jẹ ààlà ìhà ìwọ̀-oòrùn.
Strana pak západní moře veliké, od pomezí až naproti, kudyž se vchází do Emat. Ta jest strana západní.
21 “Ìwọ ní láti pín ilẹ̀ yìí ní àárín ara yín gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà Israẹli.
A tak rozdělíte zemi tuto sobě po pokoleních Izraelských.
22 Ìwọ yóò pín gẹ́gẹ́ bí ìní fún ara yín àti fún àwọn àjèjì tí ó ń gbé ní àárín yín tí ó sì ní àwọn ọmọ. Ìwọ yóò sì ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìbílẹ̀ àwọn ará Israẹli; papọ̀ mọ́ yin ni kí ẹ pín ìní fún wọn ní àárín àwọn ẹ̀yà Israẹli.
I stane se, že když ji rozměříte, bude vám v dědictví i příchozím, kteříž by pohostinu byli mezi vámi, kteříž by zplodili syny mezi vámi; nebo budou vám jako tu zrodilí mezi syny Izraelskými, s vámiť ujmou dědictví mezi pokoleními Izraelskými.
23 Ní àárín gbogbo ẹ̀yà tí àwọn àlejò ń gbé; wọn gbọdọ̀ fi ìní tirẹ̀ fún un,” ní Olúwa Olódùmarè wí.
Protož nechť jest v tom pokolení příchozí, u něhož pohostinu jest. Tu dědictví dáte jemu, praví Panovník Hospodin.

< Ezekiel 47 >