< Ezekiel 46 >

1 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn ni kí a tì pa fún ọjọ́ mẹ́fà tí a fi ń ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ ìsinmi àti ní ọjọ́ oṣù tuntun ni kí a ṣí i.
Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: La porte du parvis intérieur qui donne à l'orient, demeurera fermée pendant les six jours ouvrables; mais au jour du sabbat elle s'ouvrira, et au jour de la nouvelle lune, elle s'ouvrira.
2 Ọmọ-aládé ni kí ó wọlé láti ìta tí ó kángun sí àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà, kí ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà. Àwọn àlùfáà ni yóò rú ọrẹ ẹbọ sísun rẹ̀ àti ọrẹ ìdàpọ̀. Òun ni yóò jọ́sìn ní ìloro ilé ní ẹnu-ọ̀nà, lẹ́yìn náà ni wọn yóò jáde, ṣùgbọ́n wọn kò ni ti ìlẹ̀kùn títí ìrọ̀lẹ́.
Et le prince entrera de dehors par le vestibule de la porte, et s'arrêtera devant les jambages de la porte; et les prêtres offriront son holocauste, et son sacrifice d'actions de grâces; et il adorera sur le seuil de la porte, puis il se retirera. Cependant la porte ne sera pas fermée avant le soir;
3 Ní àwọn ọjọ́ ìsinmi àti àwọn oṣù tuntun ni kí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà jọ́sìn ní iwájú Olúwa ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà.
et le peuple du pays adorera à l'entrée de la même porte aux jours de sabbat et de nouvelles lunes en présence de l'Éternel.
4 Ọrẹ ẹbọ sísun tí ọmọ-aládé mú wá fún Olúwa ni ọjọ́ ìsinmi ní láti jẹ́ ọ̀dọ́ àgbò mẹ́fà àti àgbò kan, gbogbo rẹ̀ gbọdọ̀ jẹ́ aláìlábùkù.
Et l'holocauste que le prince aura à offrir à l'Éternel sera, le jour du sabbat, six brebis sans défaut, et un bélier sans défaut;
5 Ọrẹ ẹbọ jíjẹ tí a mú papọ̀ mọ́ àgbò gbọdọ̀ jẹ́ efa kan, ọrẹ ẹbọ jíjẹ tí a mú pẹ̀lú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ni kí ó pò gẹ́gẹ́ bí ó bá ṣe fẹ́, papọ̀ mọ hínì òróró kan pẹ̀lú efa kọ̀ọ̀kan.
et son offrande, un épha par bélier, et par brebis une offrande telle qu'il pourra la donner, et en huile un hin par épha.
6 Àti ni ọjọ́ oṣù tuntun, ẹgbọrọ màlúù kan àìlábàwọ́n, àti ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́fà, àti àgbò kan: wọn o wà láìlábàwọ́n.
Et au jour de la nouvelle lune, un jeune taureau sans défaut, et six brebis et un bélier qui devront être sans défaut;
7 Yóò si pèsè ọrẹ ẹbọ jíjẹ efa fun ẹgbọrọ akọ màlúù, àti efa kan fun àgbò kan, àti fun àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn gẹ́gẹ́ bi èyí ti ipá rẹ̀ ká, àti hínì òróró kan fún efa kan.
et un épha par taureau, et un épha par bélier; c'est ce qu'il présentera comme offrande; et par brebis ce qu'il pourra donner, et en huile un hin par épha.
8 Nígbà tí ọmọ-aládé bá wọlé, ó gbọdọ̀ gbá àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà wọ inú, kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.
Et quand le prince entrera, il entrera par le chemin du vestibule de la porte, et il sortira par le même chemin.
9 “‘Nígbà tí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá wá síwájú Olúwa ni àwọn àjọ̀dún tí a yàn, ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ti ẹnu-ọ̀nà ìhà àríwá wọlé láti jọ́sìn gbọdọ̀ gba ti ẹnu-ọ̀nà ìhà gúúsù jáde; ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ti ẹnu-ọ̀nà ìhà gúúsù wọlé yóò gba tí ẹnu-ọ̀nà ìhà àríwá jáde. Kò sí ẹni tí ó gbọdọ̀ gba ibi tí ó bá wọlé jáde, ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù gba òdìkejì ẹnu-ọ̀nà tí ó gbà wọlé jáde.
Et quand le peuple du pays se présentera devant l'Éternel aux solennités, celui qui entrera par la porte du nord pour adorer, sortira par la porte du midi, et celui qui entrera par la porte du midi, sortira par la porte du nord. L'on ne doit point se retirer par la porte par laquelle on est entré, mais on sortira en marchant toujours devant soi.
10 Ọmọ-aládé gbọdọ̀ wà ní àárín wọn, kí ó wọlé nígbà tí wọn bá wọlé, kí ó sì jáde nígbà tí wọn bá jáde.
Et le prince entrera parmi eux, quand ils entreront, et en sortant ils sortiront ensemble.
11 “‘Níbi àwọn àjọ̀dún àti àwọn àjọ̀dún tí a yàn, ọrẹ ẹbọ jíjẹ gbọdọ̀ jẹ́ efa kan fún ẹgbọrọ akọ màlúù kan, efa kan fún àgbò kan, àti fún àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn gẹ́gẹ́ bí ó bá ti wu onílúlùkù, pẹ̀lú òróró hínì kan fún efa kan.
Et aux fêtes et aux solennités l'offrande sera un épha par taureau et un épha par bélier, et par brebis ce qu'il pourra donner, et en huile un hin par épha.
12 Nígbà tí ọmọ-aládé bá pèsè ọrẹ àtinúwá fún Olúwa yálà ọrẹ ẹbọ sísun tàbí ọrẹ ẹbọ ìdàpọ̀ ojú ọ̀nà tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn ni kí ó wà ni ṣíṣí sílẹ̀ fún un. Òun yóò rú ọrẹ ẹbọ sísun rẹ̀ tàbí ọrẹ ẹbọ ìdàpọ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ní ọjọ́ ìsinmi. Lẹ́yìn náà, òun yóò jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó bá jáde tán wọn yóò ti ẹnu-ọ̀nà.
Que si le prince offre à l'Éternel un holocauste volontaire ou un sacrifice volontaire d'actions de grâces, on lui ouvrira la porte qui donne à l'orient, et il présentera son holocauste et son sacrifice d'actions de grâces comme il le fera au jour du sabbat. Et quand il sera sorti, on fermera la porte après sa sortie.
13 “‘Ní ojoojúmọ́ ni ìwọ yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan aláìlábùkù fún ọrẹ ẹbọ sísun sí Olúwa; àràárọ̀ ni ìwọ yóò máa pèsè rẹ̀.
Journellement tu offriras à l'Éternel en holocauste un agneau d'un an sans défaut; tu l'offriras tous les matins.
14 Ìwọ yóò sì máa pèsè ọrẹ ẹbọ jíjẹ pẹ̀lú rẹ̀ ní àràárọ̀, èyí yóò ni ìdámẹ́fà nínú efa àti ìdámẹ́fà nínú òróró hínì láti fi po ìyẹ̀fun. Gbígbé ọrẹ ẹbọ jíjẹ fún Olúwa jẹ́ ìlànà tí ó wà títí.
Et tu y ajouteras tous les matins une offrande, la sixième partie d'un épha, et en huile le tiers d'un hin pour humecter la farine, en offrande à l'Éternel: que ce soit une règle éternelle et constante.
15 Nítorí náà ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọrẹ ẹbọ jíjẹ àti òróró ni wọn yóò pèsè ní àràárọ̀ fún ọrẹ ẹbọ sísun ìgbà gbogbo.
Et offrez la brebis et l'offrande et l'huile tous les matins, comme holocauste perpétuel.
16 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ, tí ọmọ-aládé bá mú ọrẹ láti inú ogún ìní rẹ̀ fún ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, yóò jẹ́ ìní tiwọn nípa ogún jíjẹ.
Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Si le prince fait à l'un de ses fils un don, c'est sa propriété, il appartiendra à ses fils; ce sera leur propriété héréditaire.
17 Tí ó bá mú ọrẹ láti inú ogún ìní rẹ̀ fún ọ̀kan lára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀, ọmọ le pamọ́ títí di ọdún ìdásílẹ̀, lẹ́yìn náà yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọmọ-aládé. Ogún ìní rẹ̀ jẹ́ ti àwọn ọmọ rẹ̀ nìkan; ó jẹ́ tiwọn.
Mais si de son patrimoine il fait un don à l'un de ses serviteurs, ce don appartiendra à celui-ci jusqu'à l'année d'affranchissement, puis il reviendra au prince: à ses fils seuls appartient son patrimoine.
18 Ọmọ-aládé kò gbọdọ̀ mú nǹkan kan lára ogún ìní àwọn ènìyàn, tàbí mú wọn kúrò níbi ohun ìní wọn. Ó ní láti fi ogún ìní rẹ̀ láti inú ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kí a ma ba à ya nǹkan kan kúrò lára ìní rẹ̀.’”
Et le prince ne prendra rien de l'héritage du peuple, de manière à l'exproprier; mais c'est de son propre patrimoine qu'il pourra faire des legs à ses fils, afin qu'aucun homme de mon peuple ne soit expulsé de sa propriété.
19 Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà mú mi kọjá ní àbáwọlé tí ó wà lẹ́bàá ẹnu-ọ̀nà, sí àwọn yàrá mímọ́ tí ó kọjú sí ìhà àríwá, èyí tí ó jẹ́ tí àwọn àlùfáà, ó sì fi ibi kan hàn mí ní apá ìwọ̀-oòrùn.
Alors il m'introduisit par l'entrée latérale de la porte dans les chambres saintes réservées aux prêtres et donnant au nord, et voici, il y avait au fond un lieu du côté de l'occident.
20 O sọ fún mi pé, “Èyí yìí ni ibi tí àwọn àlùfáà yóò ti ṣe ọrẹ ẹbọ ìdálẹ́bi àti ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti tí wọn yóò ti ṣe ọrẹ ẹbọ jíjẹ, láti má ṣe jẹ́ kí wọn mú wọn wá sí ìta àgbàlá, kí wọn sì ya àwọn ènìyàn sí mímọ́.”
Et il me dit: C'est ici le lieu où les prêtres feront cuire les victimes pour le délit et pour le péché, et où ils boulangeront les offrandes, de peur qu'en portant ces choses dans le parvis extérieur, ils ne sanctifient le peuple.
21 Ó sì mú mi lọ sí ìta àgbàlá, ó sì mú mi yí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ká, mo sì ri àgbàlá mìíràn ní igun kọ̀ọ̀kan.
Puis il m'emmena dans le parvis extérieur et me fit passer aux quatre angles du parvis, et voici, il y avait une cour à chaque angle du parvis.
22 Ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ìta àgbàlá tí ó pẹnu pọ̀, ogójì ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn àti ọgbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní ìbú; àgbàlá kọ̀ọ̀kan ni igun kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìwọ̀n kan náà.
Aux quatre angles du parvis étaient des cours découvertes, de quarante coudées de longueur et de trente de largeur; toutes quatre elles avaient les mêmes dimensions aux angles.
23 Ní agbègbè inú ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àgbàlá náà ni ọwọ́ ilẹ̀ kan wà yíká wọn, a sì ṣe ibi ìdáná si abẹ́ ọwọ́ náà yípo.
Et toutes quatre elles avaient un mur d'enceinte, et au pied du mur tout autour on avait pratiqué des âtres.
24 Ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ̀nyí ni àwọn ilé ìdáná níbi tí ó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú tẹmpili yóò ti ṣe ẹbọ fún àwọn ènìyàn.”
Et il me dit: C'est là la cuisine où les servants de la maison feront cuire les victimes du peuple.

< Ezekiel 46 >