< Ezekiel 46 >

1 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn ni kí a tì pa fún ọjọ́ mẹ́fà tí a fi ń ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ ìsinmi àti ní ọjọ́ oṣù tuntun ni kí a ṣí i.
Ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: la porte du parvis intérieur, laquelle regarde l'Orient, sera fermée les six jours ouvriers, mais elle sera ouverte le jour du Sabbat, et pareillement elle sera ouverte le jour de la nouvelle lune.
2 Ọmọ-aládé ni kí ó wọlé láti ìta tí ó kángun sí àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà, kí ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà. Àwọn àlùfáà ni yóò rú ọrẹ ẹbọ sísun rẹ̀ àti ọrẹ ìdàpọ̀. Òun ni yóò jọ́sìn ní ìloro ilé ní ẹnu-ọ̀nà, lẹ́yìn náà ni wọn yóò jáde, ṣùgbọ́n wọn kò ni ti ìlẹ̀kùn títí ìrọ̀lẹ́.
Et le Prince y entrera par le chemin de l'allée de la porte [du parvis] extérieur, et se tiendra près de l'un des poteaux de [l'autre] porte, et les Sacrificateurs prépareront son holocauste et ses sacrifices de prospérité; puis il se prosternera sur le seuil de cette [autre] porte, et ensuite il sortira; mais cette [autre] porte ne sera point fermée jusques au soir.
3 Ní àwọn ọjọ́ ìsinmi àti àwọn oṣù tuntun ni kí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà jọ́sìn ní iwájú Olúwa ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà.
Tellement que le peuple du pays se prosternera devant l'Eternel à l'entrée de cette [autre] porte-ci, les jours de Sabbat et des nouvelles lunes.
4 Ọrẹ ẹbọ sísun tí ọmọ-aládé mú wá fún Olúwa ni ọjọ́ ìsinmi ní láti jẹ́ ọ̀dọ́ àgbò mẹ́fà àti àgbò kan, gbogbo rẹ̀ gbọdọ̀ jẹ́ aláìlábùkù.
Or l'holocauste que le Prince offrira à l'Eternel le jour du Sabbat sera de six agneaux sans tare, et d'un bélier sans tare.
5 Ọrẹ ẹbọ jíjẹ tí a mú papọ̀ mọ́ àgbò gbọdọ̀ jẹ́ efa kan, ọrẹ ẹbọ jíjẹ tí a mú pẹ̀lú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ni kí ó pò gẹ́gẹ́ bí ó bá ṣe fẹ́, papọ̀ mọ hínì òróró kan pẹ̀lú efa kọ̀ọ̀kan.
Et le gâteau pour le bélier [sera] d'un épha, et le gâteau pour chacun des agneaux sera selon ce qu'il pourra donner; mais il y aura un hin d'huile pour chaque épha.
6 Àti ni ọjọ́ oṣù tuntun, ẹgbọrọ màlúù kan àìlábàwọ́n, àti ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́fà, àti àgbò kan: wọn o wà láìlábàwọ́n.
Et au jour de la nouvelle Lune [son holocauste] sera d'un jeune veau, sans tare, et de six agneaux et d'un bélier, aussi sans tare.
7 Yóò si pèsè ọrẹ ẹbọ jíjẹ efa fun ẹgbọrọ akọ màlúù, àti efa kan fun àgbò kan, àti fun àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn gẹ́gẹ́ bi èyí ti ipá rẹ̀ ká, àti hínì òróró kan fún efa kan.
Et il offrira pour le gâteau du veau, un épha, et pour le gâteau du bélier, un [autre] épha, et pour chacun des agneaux selon ce qu'il pourra donner; mais [il y aura] un hin d'huile pour chaque épha.
8 Nígbà tí ọmọ-aládé bá wọlé, ó gbọdọ̀ gbá àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà wọ inú, kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.
Et comme le Prince sera entré [au Temple] par le chemin de l'allée de cette [même] porte [du parvis] extérieur, laquelle regarde l'Orient, aussi sortira-t-il par le même chemin.
9 “‘Nígbà tí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá wá síwájú Olúwa ni àwọn àjọ̀dún tí a yàn, ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ti ẹnu-ọ̀nà ìhà àríwá wọlé láti jọ́sìn gbọdọ̀ gba ti ẹnu-ọ̀nà ìhà gúúsù jáde; ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ti ẹnu-ọ̀nà ìhà gúúsù wọlé yóò gba tí ẹnu-ọ̀nà ìhà àríwá jáde. Kò sí ẹni tí ó gbọdọ̀ gba ibi tí ó bá wọlé jáde, ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù gba òdìkejì ẹnu-ọ̀nà tí ó gbà wọlé jáde.
Mais quand le peuple du pays [y] entrera pour se présenter devant l'Eternel, aux fêtes solennelles, celui qui y entrera par le chemin de la porte du Septentrion pour y adorer l'Eternel, sortira par le chemin de la porte du Midi; et celui qui y entrera par le chemin de la porte du Midi, sortira par le chemin de la porte qui regarde vers le Septentrion; tellement que personne ne retournera par le chemin de la porte par laquelle il sera entré, mais il sortira par celle qui est vis-à-vis.
10 Ọmọ-aládé gbọdọ̀ wà ní àárín wọn, kí ó wọlé nígbà tí wọn bá wọlé, kí ó sì jáde nígbà tí wọn bá jáde.
Alors le Prince entrera parmi eux, quand ils entreront; et quand ils sortiront, ils sortiront [ensemble].
11 “‘Níbi àwọn àjọ̀dún àti àwọn àjọ̀dún tí a yàn, ọrẹ ẹbọ jíjẹ gbọdọ̀ jẹ́ efa kan fún ẹgbọrọ akọ màlúù kan, efa kan fún àgbò kan, àti fún àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn gẹ́gẹ́ bí ó bá ti wu onílúlùkù, pẹ̀lú òróró hínì kan fún efa kan.
Or dans ces fêtes solennelles, et dans ces solennités, le gâteau d'un veau sera d'un épha, et [le gâteau] d'un bélier d'un [autre] épha, et le gâteau de chacun des agneaux sera selon que le Prince pourra donner, et il y aura un hin d'huile pour chaque épha.
12 Nígbà tí ọmọ-aládé bá pèsè ọrẹ àtinúwá fún Olúwa yálà ọrẹ ẹbọ sísun tàbí ọrẹ ẹbọ ìdàpọ̀ ojú ọ̀nà tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn ni kí ó wà ni ṣíṣí sílẹ̀ fún un. Òun yóò rú ọrẹ ẹbọ sísun rẹ̀ tàbí ọrẹ ẹbọ ìdàpọ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ní ọjọ́ ìsinmi. Lẹ́yìn náà, òun yóò jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó bá jáde tán wọn yóò ti ẹnu-ọ̀nà.
Que si le Prince offre un sacrifice volontaire, quelque holocauste, soit quelques sacrifices de prospérités en offrande volontaire à l'Eternel, on lui ouvrira la porte qui regarde l'Orient, et il offrira son holocauste et ses sacrifices de prospérités comme il les offre le jour du Sabbat, puis il sortira, et après qu'il sera sorti, on fermera cette porte.
13 “‘Ní ojoojúmọ́ ni ìwọ yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan aláìlábùkù fún ọrẹ ẹbọ sísun sí Olúwa; àràárọ̀ ni ìwọ yóò máa pèsè rẹ̀.
Tu sacrifieras chaque jour en holocauste à l'Eternel un agneau d'un an sans tare, tu le sacrifieras tous les matins.
14 Ìwọ yóò sì máa pèsè ọrẹ ẹbọ jíjẹ pẹ̀lú rẹ̀ ní àràárọ̀, èyí yóò ni ìdámẹ́fà nínú efa àti ìdámẹ́fà nínú òróró hínì láti fi po ìyẹ̀fun. Gbígbé ọrẹ ẹbọ jíjẹ fún Olúwa jẹ́ ìlànà tí ó wà títí.
Tu offriras aussi tous les matins avec lui un gâteau, fait de la sixième partie d'un épha, et de la troisième d'un hin d'huile pour en détremper la fine farine; c'est là le gâteau continuel qu'il faut offrir par ordonnances perpétuelles.
15 Nítorí náà ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọrẹ ẹbọ jíjẹ àti òróró ni wọn yóò pèsè ní àràárọ̀ fún ọrẹ ẹbọ sísun ìgbà gbogbo.
Ainsi on offrira tous les matins [en] holocauste continuel cet agneau et ce gâteau détrempé avec cette huile.
16 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ, tí ọmọ-aládé bá mú ọrẹ láti inú ogún ìní rẹ̀ fún ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, yóò jẹ́ ìní tiwọn nípa ogún jíjẹ.
Ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: quand le Prince aura fait un don [de quelque pièce] de son héritage à quelqu'un de ses fils, ce don appartiendra à ses fils; parce qu'ils ont droit de possession en l'héritage.
17 Tí ó bá mú ọrẹ láti inú ogún ìní rẹ̀ fún ọ̀kan lára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀, ọmọ le pamọ́ títí di ọdún ìdásílẹ̀, lẹ́yìn náà yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọmọ-aládé. Ogún ìní rẹ̀ jẹ́ ti àwọn ọmọ rẹ̀ nìkan; ó jẹ́ tiwọn.
Mais s'il fait un don [de quelque pièce] de son héritage à l'un de ses serviteurs, le don lui appartiendra bien, mais seulement jusques à l'an d'affranchissement, auquel il retournera au Prince; [car] quoi qu'il en soit, c'est son héritage qui appartient à ses fils, [c'est pourquoi] il leur demeurera.
18 Ọmọ-aládé kò gbọdọ̀ mú nǹkan kan lára ogún ìní àwọn ènìyàn, tàbí mú wọn kúrò níbi ohun ìní wọn. Ó ní láti fi ogún ìní rẹ̀ láti inú ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kí a ma ba à ya nǹkan kan kúrò lára ìní rẹ̀.’”
Et le Prince n'usurpera rien de l'héritage du peuple, les fraudant de la possession qui leur appartient, [seulement] il laissera en héritage à ses fils la possession qui lui appartient, afin qu'aucun de mon peuple ne soit chassé de sa possession.
19 Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà mú mi kọjá ní àbáwọlé tí ó wà lẹ́bàá ẹnu-ọ̀nà, sí àwọn yàrá mímọ́ tí ó kọjú sí ìhà àríwá, èyí tí ó jẹ́ tí àwọn àlùfáà, ó sì fi ibi kan hàn mí ní apá ìwọ̀-oòrùn.
Puis il me mena par l'entrée qui était vers le côté de la porte, aux chambres saintes qui appartenaient aux Sacrificateurs, lesquelles regardaient vers le Septentrion, et voilà, il y avait un certain lieu aux deux côtés du fond qui regardaient vers l'Occident.
20 O sọ fún mi pé, “Èyí yìí ni ibi tí àwọn àlùfáà yóò ti ṣe ọrẹ ẹbọ ìdálẹ́bi àti ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti tí wọn yóò ti ṣe ọrẹ ẹbọ jíjẹ, láti má ṣe jẹ́ kí wọn mú wọn wá sí ìta àgbàlá, kí wọn sì ya àwọn ènìyàn sí mímọ́.”
Et il me dit: c'est là le lieu auquel les Sacrificateurs bouilliront [le reste de la bête qu'on aura sacrifiée pour] le délit, et [le reste de la bête qu'on aura sacrifiée pour] le péché, et où ils cuiront les gâteaux; afin qu'ils ne les emportent point au parvis extérieur pour en sanctifier le peuple.
21 Ó sì mú mi lọ sí ìta àgbàlá, ó sì mú mi yí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ká, mo sì ri àgbàlá mìíràn ní igun kọ̀ọ̀kan.
Puis il me fit sortir vers le parvis extérieur, et me fit traverser vers les quatre coins du parvis, et voici, il y avait un parvis à chaque coin du parvis.
22 Ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ìta àgbàlá tí ó pẹnu pọ̀, ogójì ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn àti ọgbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní ìbú; àgbàlá kọ̀ọ̀kan ni igun kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìwọ̀n kan náà.
Tellement qu'aux quatre coins de ce parvis il y avait d'autres parvis qui y étaient joints, et ils étaient longs de quarante [coudées], et larges de trente; [et] tous quatre avaient une même mesure, [et] avaient leurs [quatre] coins.
23 Ní agbègbè inú ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àgbàlá náà ni ọwọ́ ilẹ̀ kan wà yíká wọn, a sì ṣe ibi ìdáná si abẹ́ ọwọ́ náà yípo.
Tous ces quatre parvis avaient une rangée de bâtiments élevés tout à l'entour, et ce qui était bâti au dessous de ces rangées de bâtiment élevé, tout [à] l'entour, c'étaient des lieux propres à cuire.
24 Ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ̀nyí ni àwọn ilé ìdáná níbi tí ó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú tẹmpili yóò ti ṣe ẹbọ fún àwọn ènìyàn.”
Et il me dit: ce sont ici les cuisines, où ceux qui font le service de la maison cuiront les sacrifices du peuple.

< Ezekiel 46 >