< Ezekiel 44 >

1 Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, ó sì wà ní títì.
М-а адус ынапой ла поарта де афарэ а Сфынтулуй Локаш, динспре рэсэрит. Дар ера ынкисэ.
2 Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu-ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ ṣí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí gbà ibẹ̀ wọlé.
Ши Домнул мь-а зис: „Поарта ачаста ва ста ынкисэ, ну се ва дескиде ши нимень ну ва трече пе еа, кэч Домнул Думнезеул луй Исраел а интрат пе еа. Де ачея ва рэмыне ынкисэ!
3 Ọmọ-aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu-ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìloro ẹnu-ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”
Ын че привеште пе воевод, воеводул ва путя сэ шадэ суб еа, ка сэ мэнынче пыня де жертфэ ынаинтя Домнулуй. Ел ва интра пе друмул каре дэ ын тинда порций ши ва еши пе ачелашь друм.”
4 Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu-ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ̀.
М-а дус апой ла поарта де мязэноапте, ынаинтя касей Темплулуй. М-ам уйтат ши ятэ кэ слава Домнулуй умпля Каса Домнулуй! Ши ам кэзут ку фаца ла пэмынт.
5 Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáradára, fetísílẹ̀ dáradára kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa òfin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.
Домнул мь-а зис: „Фиул омулуй, фий ку луаре аминте, уйтэ-те ку окий тэй ши аскултэ ку урекиле тале тот че-ць вой спуне ку привире ла тоате рындуелиле Касей Домнулуй ши ку привире ла тоате леӂиле ей; привеште ку бэгаре де сямэ интраря касей ши тоате ешириле Сфынтулуй Локаш!
6 Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Israẹli!
Ши спуне челор ындэрэтничь, касей луй Исраел: ‘Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Ажунгэ-вэ тоате урычуниле воастре, каса луй Исраел!
7 Ní àfikún pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìríra rẹ tí ó kù, ìwọ mú àwọn àjèjì aláìkọlà àyà àti ara wá sí inú ibi mímọ́ mi, ní lílo ilé mi ní ìlòkulò nígbà tí ìwọ fi oúnjẹ fún mi, ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ìwọ sì ba májẹ̀mú mi jẹ́.
Аць бэгат ын Локашул Меу чел Сфынт ниште стрэинь ку инима нетэятэ ымпрежур ши ку карня нетэятэ ымпрежур ка сэ-Мь спурче каса; аць адус пыня Мя, грэсимя ши сынӂеле ынаинтя тутурор урычунилор воастре ши аць рупт астфел легэмынтул Меу.
8 Dípò kí ìwọ pa òfin mi mọ́, ìwọ fi àwọn mìíràn sí ibi mímọ́ mi.
Н-аць пэзит че требуя пэзит ку привире ла лукруриле Меле челе сфинте, чи й-аць пус ын локул востру, ка сэ факэ службэ ын Локашул Меу чел Сфынт.»
9 Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Àjèjì aláìkọlà àyà àti ara kò gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi, àti pẹ̀lú àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli.
Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Ничун стрэин нетэят ымпрежур ку инима ши нетэят ымпрежур ку трупул сэ ну интре ын Локашул Меу чел Сфынт, ничунул дин стрэиний каре вор фи ын мижлокул копиилор луй Исраел.
10 “‘Àwọn Lefi tí wọn rìn jìnnà kúrò lọ́dọ̀ mi nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ṣìnà, ti wọ́n sì ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi láti tọ àwọn ère wọn lẹ́yìn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Май мулт, левиций каре с-ау депэртат де Мине кынд се рэтэчя Исраел ши се абэтя де ла Мине ка сэ-шь урмезе идолий вор пурта педяпса нелеӂюирилор лор:
11 Wọn le sìn mi ní ibi mímọ́ mi, kí wọn ṣe ìtọ́jú àwọn ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run, kí wọn sì ṣe ìránṣẹ́ nínú rẹ̀; wọn le pa ẹbọ sísun, ki wọn sì rú ẹbọ fún àwọn ènìyàn, kí wọn sì dúró níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
ей вор фи ын Локашул Меу чел Сфынт ка слуӂь, вор пэзи порциле касей ши вор фаче службэ ын касэ; вор жунгия пентру попор вителе рындуите пентру ардериле-де-тот ши пентру челелалте жертфе ши вор ста ынаинтя луй ка сэ-й служяскэ.
12 Ṣùgbọ́n nítorí pé wọn ṣe ìránṣẹ́ fún wọn níwájú àwọn ère wọn, tí wọn sì mu ilé Israẹli ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀, nítorí náà, Èmi tí búra nípa nína ọwọ́ sókè pé, wọn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Пентру кэ й-ау служит ынаинтя идолилор луй ши ау фэкут сэ кадэ ын пэкат каса луй Исраел, де ачея Ымь ридик мына асупра лор», зиче Домнул Думнезеу, «ка сэ-шь поарте педяпса нелеӂюирий лор.
13 Wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi láti ṣe ìránṣẹ́ fún mi, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí súnmọ́ nǹkan kan nínú àwọn ohun mímọ́ mi tàbí ẹbọ mi mímọ́ jùlọ; wọn gbọdọ̀ gba ìtìjú ìwà ìríra wọn.
Ну се вор апропия де Мине ка сэ фие ын служба Мя ка преоць, ну се вор апропия де лукруриле Меле челе сфинте, нич де лукруриле Меле прясфинте, чи вор пурта педяпса рушиний лор ши урычунилор пе каре ле-ау сэвыршит.
14 Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo iṣẹ́ tí a gbọdọ̀ ṣe níbẹ̀.
Тотушь ле вой да паза касей, ый вой ынтребуинца ла тоатэ служба ей ши ла тот че требуе фэкут ын еа.
15 “‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi àti àwọn ìran Sadoku tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Дар преоций, левиций, фиий луй Цадок, каре ау пэзит служба Локашулуй Меу челуй Сфынт кынд се рэтэчяу копиий луй Исраел де ла Мине, ачея се вор апропия де Мине сэ-Мь служяскэ ши вор ста ынаинтя Мя ка сэ-Мь адукэ грэсиме ши сынӂе», зиче Домнул Думнезеу.
16 Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ súnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.
«Ей вор интра ын Локашул Меу чел Сфынт, се вор апропия де маса Мя ка сэ-Мь служяскэ ши вор фи ын служба Мя.
17 “‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ ẹ̀wù ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.
Кынд вор трече пе порциле курций динэунтру, се вор ымбрэка ын хайне де ин; ну вор авя пе ей нимик де лынэ кынд вор фаче служба ын порциле курций динэунтру ши ын касэ.
18 Wọ́n yóò sì dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò sì gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.
Вор авя пе кап ши скуфий де ин ши измене де ин пе коапселе лор, ну се вор ынчинӂе ку чева каре сэ адукэ судоаря,
19 Nígbà tí wọ́n bá lọ sì àgbàlá òde níbi tí àwọn ènìyàn wà, wọn gbọdọ̀ bọ́ ẹ̀wù tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́, ki wọn sì fi wọn sílẹ̀ sí àwọn yàrá mímọ́ náà, kí wọn kí ó sì wọ ẹ̀wù mìíràn, wọn kì yóò sì fi ẹ̀wù wọn sọ àwọn ènìyàn di mímọ́.
яр кынд вор еши сэ се дукэ ын куртя де афарэ, ла попор, вор лепэда вешминтеле ку каре фак служба ши ле вор пуне ын одэиле Сфынтулуй Локаш; се вор ымбрэка ын алтеле ка сэ ну сфинцяскэ попорул ку вешминтеле лор.
20 “‘Wọn kò gbọdọ̀ fá irun, wọn kò sì gbọdọ̀ jẹ́ kí irun wọn gùn, ṣùgbọ́n wọn gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí wọn wà ní gígẹ̀.
Ну-шь вор раде капул, дар нич ну вор лэса пэрул сэ кряскэ ын вое, чи ва требуи сэ-шь тае пэрул.
21 Àlùfáà kankan kò gbọdọ̀ mu ọtí nígbà tí ó bá wọ àgbàlá tí inú.
Ничун преот ну ва бя вин кынд ва интра ын куртя динэунтру.
22 Wọn ko gbọdọ̀ fẹ́ opó ni ìyàwó, wọn kò sì gbọdọ̀ kọ ìyàwó wọn sílẹ̀, wọ́n lè fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ti kò tí i mọ ọkùnrin rí, tí ó sì jẹ́ ìran àwọn ọmọ Israẹli, tàbí kí wọn fẹ́ àwọn opó àlùfáà.
Ну вор луа де невастэ ничо вэдувэ, ничо фемее лэсатэ де бэрбат, чи вор луа нумай фечоаре дин сэмынца касей луй Исраел, тотушь вор путя сэ я ши пе вэдува унуй преот.
23 Wọn yóò sì fi ìyàtọ̀ tí ó wà láàrín mímọ́ àti àìmọ́ kọ́ àwọn ènìyàn mi, wọn yóò sì fihàn wọ́n bi wọn yóò ṣe dá aláìmọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí mímọ́.
Вор ынвэца пе попорул Меу сэ деосебяскэ че есте сфынт де че ну есте сфынт ши вор арэта деосебиря динтре че есте некурат ши че есте курат.
24 “‘Nínú èyíkéyìí èdè-àìyedè, àwọn àlùfáà ní yóò dúró gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin mi. Wọ́n ní láti pa àwọn òfin àti àṣẹ mi mọ́ ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn, wọn sì gbọdọ̀ ya ọjọ́ ìsinmi mi ní mímọ́.
Вор жудека ын неынцелеӂерь ши вор хотэры дупэ леӂиле Меле. Вор пэзи, де асеменя, леӂиле ши порунчиле Меле, ла тоате сэрбэториле Меле ши вор сфинци Сабателе Меле.
25 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nípa sísún mọ́ òkú ènìyàn; ṣùgbọ́n ti òkú ènìyàn yẹn bá jẹ́ baba tàbí ìyá rẹ̀, àbúrò rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin ti kò i ti lọ́kọ, nígbà náà o le sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
Ун преот ну се ва дуче ла ун морт, ка сэ ну се факэ некурат; ну ва путя сэ се факэ некурат декыт пентру ун татэ, пентру о мамэ, пентру ун фиу, пентру о фийкэ, пентру ун фрате ши пентру о сорэ каре ну ера мэритатэ.
26 Lẹ́yìn ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, ki òun kí ó dúró fún ọjọ́ méje.
Дупэ курэцире, и се вор нумэра шапте зиле.
27 Ní ọjọ́ ti yóò wọ àgbàlá ti inú ni ibi mímọ́ láti ṣe ìránṣẹ́ ibi mímọ́, ni kí òun kí ó rú ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Ын зиуа кынд ва интра ын Локашул Меу чел Сфынт, ын куртя динэунтру, ка сэ факэ служба ын Сфынтул Локаш, ышь ва адуче жертфа де испэшире», зиче Домнул Думнезеу.
28 “‘Èmi ni yóò jẹ́ ogún kan ṣoṣo tí àwọn àlùfáà yóò ní. Ẹ kì yóò fún wọn ni ìpín kankan ní Israẹli, Èmi ni yóò jẹ́ ìní wọn.
«Ятэ моштениря пе каре о вор авя: Еу вой фи моштениря лор. Сэ ну ле даць ничо мошие ын Исраел: Еу вой фи мошия лор!
29 Wọn yóò jẹ ọrẹ ẹbọ jíjẹ, ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ ìrékọjá; gbogbo ohun tí a bá yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ni Israẹli ni yóò jẹ́ tiwọn.
Дар се вор хрэни ку даруриле де мынкаре, ку жертфеле де испэшире ши де винэ ши тот че ва фи ынкинат Домнулуй прин фэгэдуинцэ ын Исраел ва фи ал лор.
30 Èyí tí ó dára jùlọ nínú gbogbo àkọ́so èso àti ọrẹ yín yóò jẹ́ ti àwọn àlùfáà. Ẹ ó sì fi àkọ́pò ìyẹ̀fun yín fún wọn kí ìbùkún lè wà lórí gbogbo ilé yín.
Челе май буне дин челе динтый роаде де орьче фел ши партя ридикатэ дин тоате даруриле де мынкаре пе каре ле вець адуче ка дарурь ридикате вор фи але преоцилор; вець да преоцилор ши пырга фэиний воастре, пентру ка бинекувынтаря сэ рэмынэ песте каса воастрэ.
31 Àwọn àlùfáà kì yóò jẹ́ ohunkóhun bí i ẹyẹ tàbí ẹranko, tí ó ti kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí ti ẹranko ńlá fàya.
Преоций ынсэ ну вор мынка дин ничо пасэре сау витэ моартэ орь сфышиятэ де фярэ.

< Ezekiel 44 >