< Ezekiel 44 >

1 Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, ó sì wà ní títì.
Și m-a dus înapoi pe calea porții sanctuarului de afară, care dă spre est; și ea [era] închisă.
2 Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu-ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ ṣí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí gbà ibẹ̀ wọlé.
Atunci DOMNUL mi-a spus: Această poartă să fie închisă, să nu se deschidă și niciun om să nu intre pe ea, pentru că DOMNUL, Dumnezeul lui Israel, a intrat pe ea; de aceea să fie închisă.
3 Ọmọ-aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu-ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìloro ẹnu-ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”
[Aceasta este] pentru prinț; prințul va ședea în ea pentru a mânca pâine înaintea DOMNULUI; el va intra pe calea porticului [acelei] porți și va ieși tot pe calea lui.
4 Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu-ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ̀.
Apoi m-a dus pe calea porții de nord, înaintea casei; și eu am privit și, iată, gloria DOMNULUI umplea casa DOMNULUI, și am căzut cu fața la pământ.
5 Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáradára, fetísílẹ̀ dáradára kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa òfin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.
Și DOMNUL mi-a spus: Fiu al omului, ia aminte și privește cu ochii tăi și ascultă cu urechile tale tot ce îți spun referitor la toate rânduielile casei DOMNULUI și la toate legile ei; și ia aminte la intrarea casei, la toate ieșirile sanctuarului.
6 Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Israẹli!
Și să spui celor răzvrătiți, casei lui Israel: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Voi casă a lui Israel, fie-vă destul toate urâciunile voastre,
7 Ní àfikún pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìríra rẹ tí ó kù, ìwọ mú àwọn àjèjì aláìkọlà àyà àti ara wá sí inú ibi mímọ́ mi, ní lílo ilé mi ní ìlòkulò nígbà tí ìwọ fi oúnjẹ fún mi, ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ìwọ sì ba májẹ̀mú mi jẹ́.
În aceea că ați adus [în sanctuarul meu] străini, necircumciși în inimă și necircumciși în carne, să fie în sanctuarul meu, să îl murdărească, [în chiar] casa mea, când oferiți pâinea mea, grăsimea și sângele, iar ei au călcat legământul meu din cauza tuturor urâciunilor voastre.
8 Dípò kí ìwọ pa òfin mi mọ́, ìwọ fi àwọn mìíràn sí ibi mímọ́ mi.
Și nu ați păzit însărcinarea lucrurilor mele sfinte; ci ați pus păzitori ai însărcinării mele în sanctuarul meu pentru voi înșivă.
9 Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Àjèjì aláìkọlà àyà àti ara kò gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi, àti pẹ̀lú àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli.
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Niciun străin, necircumcis în inimă, nici necircumcis în carne, să nu intre în sanctuarul meu, din toți străinii câți [se vor afla] între copiii lui Israel.
10 “‘Àwọn Lefi tí wọn rìn jìnnà kúrò lọ́dọ̀ mi nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ṣìnà, ti wọ́n sì ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi láti tọ àwọn ère wọn lẹ́yìn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Și leviții care s-au depărtat de mine, când Israel rătăcea, care au rătăcit de la mine după idolii lor, să își poarte nelegiuirea lor.
11 Wọn le sìn mi ní ibi mímọ́ mi, kí wọn ṣe ìtọ́jú àwọn ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run, kí wọn sì ṣe ìránṣẹ́ nínú rẹ̀; wọn le pa ẹbọ sísun, ki wọn sì rú ẹbọ fún àwọn ènìyàn, kí wọn sì dúró níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
Totuși ei să fie servitori în sanctuarul meu, [având] sarcina la porțile casei și servind casei; ei să înjunghie ofranda arsă și sacrificiul pentru popor și să stea în picioare înaintea lor să le servească.
12 Ṣùgbọ́n nítorí pé wọn ṣe ìránṣẹ́ fún wọn níwájú àwọn ère wọn, tí wọn sì mu ilé Israẹli ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀, nítorí náà, Èmi tí búra nípa nína ọwọ́ sókè pé, wọn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Pentru că ei le-au servit înaintea idolilor lor și au făcut să cadă casa lui Israel în nelegiuire; de aceea mi-am ridicat mâna împotriva lor, spune Domnul DUMNEZEU și ei își vor purta nelegiuirea.
13 Wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi láti ṣe ìránṣẹ́ fún mi, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí súnmọ́ nǹkan kan nínú àwọn ohun mímọ́ mi tàbí ẹbọ mi mímọ́ jùlọ; wọn gbọdọ̀ gba ìtìjú ìwà ìríra wọn.
Și să nu se apropie de mine, ca să îmi facă serviciul de preot, nici să nu se apropie de vreunul din lucrurile mele sfinte, în [locul] preasfânt; ci să își poarte rușinea și urâciunile lor pe care le-au făcut.
14 Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo iṣẹ́ tí a gbọdọ̀ ṣe níbẹ̀.
Ci îi voi face păzitori ai sarcinii casei, pentru tot serviciul ei și pentru tot ce se va face în ea.
15 “‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi àti àwọn ìran Sadoku tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Dar preoții, leviții, fiii lui Țadoc, care au păzit sarcina sanctuarului meu când copiii lui Israel au rătăcit de la mine, ei să se apropie de mine ca să îmi servească; și să stea în picioare înaintea mea pentru a-mi aduce grăsimea și sângele, spune Domnul DUMNEZEU;
16 Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ súnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.
Ei să intre în sanctuarul meu și să se apropie de masa mea, pentru a-mi servi și să păzească însărcinarea mea.
17 “‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ ẹ̀wù ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.
Și se va întâmpla, când vor intra pe porțile curții interioare, [că] vor fi îmbrăcați cu haine de in și să nu pună lână pe ei în timp ce servesc în porțile curții interioare și înăuntru.
18 Wọ́n yóò sì dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò sì gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.
Să aibă bonete de in pe capetele lor și să aibă izmene de in pe coapsele lor; să nu [se] încingă cu vreun lucru care să îi facă să transpire.
19 Nígbà tí wọ́n bá lọ sì àgbàlá òde níbi tí àwọn ènìyàn wà, wọn gbọdọ̀ bọ́ ẹ̀wù tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́, ki wọn sì fi wọn sílẹ̀ sí àwọn yàrá mímọ́ náà, kí wọn kí ó sì wọ ẹ̀wù mìíràn, wọn kì yóò sì fi ẹ̀wù wọn sọ àwọn ènìyàn di mímọ́.
Și când ies în curtea exterioară, în curtea exterioară la popor, să se dezbrace de hainele lor în care au servit și să le pună în camerele sfinte; și să îmbrace alte haine; și să nu sfințească poporul cu hainele lor.
20 “‘Wọn kò gbọdọ̀ fá irun, wọn kò sì gbọdọ̀ jẹ́ kí irun wọn gùn, ṣùgbọ́n wọn gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí wọn wà ní gígẹ̀.
Nici să nu își radă capetele, nici să nu permită șuvițelor lor să crească lungi; ei doar să își tundă scurt capetele.
21 Àlùfáà kankan kò gbọdọ̀ mu ọtí nígbà tí ó bá wọ àgbàlá tí inú.
Nici să nu bea vin vreunul dintre preoți când intră în curtea interioară.
22 Wọn ko gbọdọ̀ fẹ́ opó ni ìyàwó, wọn kò sì gbọdọ̀ kọ ìyàwó wọn sílẹ̀, wọ́n lè fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ti kò tí i mọ ọkùnrin rí, tí ó sì jẹ́ ìran àwọn ọmọ Israẹli, tàbí kí wọn fẹ́ àwọn opó àlùfáà.
Nici să nu își ia de soții [vreo] văduvă, nici pe cea divorțată, ci să ia tinere din sămânța casei lui Israel sau o văduvă de preot.
23 Wọn yóò sì fi ìyàtọ̀ tí ó wà láàrín mímọ́ àti àìmọ́ kọ́ àwọn ènìyàn mi, wọn yóò sì fihàn wọ́n bi wọn yóò ṣe dá aláìmọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí mímọ́.
Și să învețe pe poporul meu [deosebirea] dintre [ce este] sfânt și [ce] nu [este] sfânt și să îi facă să discearnă între necurat și curat.
24 “‘Nínú èyíkéyìí èdè-àìyedè, àwọn àlùfáà ní yóò dúró gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin mi. Wọ́n ní láti pa àwọn òfin àti àṣẹ mi mọ́ ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn, wọn sì gbọdọ̀ ya ọjọ́ ìsinmi mi ní mímọ́.
Și în neînțelegeri ei să stea în picioare la judecată; [și] să judece conform cu judecățile mele; și să păzească legile mele și statutele mele în toate adunările mele; și să sfințească sabatele mele.
25 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nípa sísún mọ́ òkú ènìyàn; ṣùgbọ́n ti òkú ènìyàn yẹn bá jẹ́ baba tàbí ìyá rẹ̀, àbúrò rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin ti kò i ti lọ́kọ, nígbà náà o le sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
Și să nu vină la nicio persoană moartă să se întineze, numai pentru tată sau pentru mamă sau pentru fiu sau pentru fiică, pentru frate sau pentru soră care nu a avut soț, se pot întina.
26 Lẹ́yìn ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, ki òun kí ó dúró fún ọjọ́ méje.
Și după ce se curățește, să îi numere șapte zile.
27 Ní ọjọ́ ti yóò wọ àgbàlá ti inú ni ibi mímọ́ láti ṣe ìránṣẹ́ ibi mímọ́, ni kí òun kí ó rú ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Și, în ziua când el intră în sanctuar, în curtea interioară, pentru a servi în sanctuar, să ofere ofranda lui pentru păcat, spune Domnul DUMNEZEU.
28 “‘Èmi ni yóò jẹ́ ogún kan ṣoṣo tí àwọn àlùfáà yóò ní. Ẹ kì yóò fún wọn ni ìpín kankan ní Israẹli, Èmi ni yóò jẹ́ ìní wọn.
Și aceasta să le fie ca moștenire, eu [sunt] moștenirea lor; și să nu le dați nicio stăpânire în Israel, eu [sunt] stăpânirea lor.
29 Wọn yóò jẹ ọrẹ ẹbọ jíjẹ, ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ ìrékọjá; gbogbo ohun tí a bá yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ni Israẹli ni yóò jẹ́ tiwọn.
Ei vor mânca darul de mâncare și ofranda pentru păcat și ofranda pentru fărădelege; și fiecare lucru dedicat în Israel va fi al lor.
30 Èyí tí ó dára jùlọ nínú gbogbo àkọ́so èso àti ọrẹ yín yóò jẹ́ ti àwọn àlùfáà. Ẹ ó sì fi àkọ́pò ìyẹ̀fun yín fún wọn kí ìbùkún lè wà lórí gbogbo ilé yín.
Și primele dintre toate roadele dintâi din toate [lucrurile și] fiecare dar dintre toate, din fiecare [fel] de daruri, vor fi ale preoților; voi să dați de asemenea preotului cel dintâi din aluatul vostru, ca să facă să se odihnească binecuvântarea în casa voastră.
31 Àwọn àlùfáà kì yóò jẹ́ ohunkóhun bí i ẹyẹ tàbí ẹranko, tí ó ti kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí ti ẹranko ńlá fàya.
Preoții să nu mănânce din vreun lucru care a murit de la sine, sau sfâșiat, fie pasăre fie animal.

< Ezekiel 44 >