< Ezekiel 44 >

1 Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, ó sì wà ní títì.
Então ele me trouxe de volta pelo caminho do portão exterior do santuário, que olha para o leste; e ele estava fechado.
2 Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu-ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ ṣí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí gbà ibẹ̀ wọlé.
Yahweh me disse: “Este portão deve estar fechado. Não será aberta, nenhum homem entrará por ela; pois Javé, o Deus de Israel, entrou por ela. Portanto, ele será fechado.
3 Ọmọ-aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu-ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìloro ẹnu-ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”
Quanto ao príncipe, ele se sentará nela como príncipe para comer pão diante de Iavé. Ele entrará pelo caminho do alpendre do portão e sairá pelo mesmo caminho”.
4 Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu-ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ̀.
Então ele me trouxe pelo caminho do portão norte diante da casa; e olhei, e eis que a glória de Iavé encheu a casa de Iavé; então caí de cara.
5 Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáradára, fetísílẹ̀ dáradára kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa òfin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.
Yahweh me disse: “Filho do homem, marca bem, e vê com teus olhos, e ouve com teus ouvidos tudo o que te digo a respeito de todas as ordenanças da casa de Yahweh e todas as suas leis; e marca bem a entrada da casa, com cada saída do santuário.
6 Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Israẹli!
Dirás aos rebeldes, até mesmo à casa de Israel: 'O Senhor Javé diz: “Vós, casa de Israel, que basta de todas as vossas abominações,
7 Ní àfikún pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìríra rẹ tí ó kù, ìwọ mú àwọn àjèjì aláìkọlà àyà àti ara wá sí inú ibi mímọ́ mi, ní lílo ilé mi ní ìlòkulò nígbà tí ìwọ fi oúnjẹ fún mi, ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ìwọ sì ba májẹ̀mú mi jẹ́.
em que trouxestes estrangeiros, incircuncisos de coração e incircuncisos de carne, para estar no meu santuário, para profaná-lo, até a minha casa, quando oferecerdes o meu pão, a gordura e o sangue; e eles quebraram o meu pacto, para acrescentar a todas as vossas abominações.
8 Dípò kí ìwọ pa òfin mi mọ́, ìwọ fi àwọn mìíràn sí ibi mímọ́ mi.
Vocês não cumpriram o dever de minhas coisas sagradas; mas colocaram para vocês mesmos os executantes do meu dever em meu santuário”.
9 Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Àjèjì aláìkọlà àyà àti ara kò gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi, àti pẹ̀lú àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli.
O Senhor Javé diz: “Nenhum estrangeiro, incircunciso de coração e incircunciso de carne, entrará em meu santuário, de qualquer estrangeiro que se encontre entre os filhos de Israel”.
10 “‘Àwọn Lefi tí wọn rìn jìnnà kúrò lọ́dọ̀ mi nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ṣìnà, ti wọ́n sì ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi láti tọ àwọn ère wọn lẹ́yìn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
“““Mas os levitas que se afastaram de mim quando Israel se desviou, que se afastaram de mim depois de seus ídolos, eles suportarão sua iniqüidade.
11 Wọn le sìn mi ní ibi mímọ́ mi, kí wọn ṣe ìtọ́jú àwọn ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run, kí wọn sì ṣe ìránṣẹ́ nínú rẹ̀; wọn le pa ẹbọ sísun, ki wọn sì rú ẹbọ fún àwọn ènìyàn, kí wọn sì dúró níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
Yet eles serão ministros em meu santuário, tendo supervisão às portas da casa, e ministrando na casa. Eles matarão o holocausto e o sacrifício pelo povo, e estarão diante deles para ministrar a eles.
12 Ṣùgbọ́n nítorí pé wọn ṣe ìránṣẹ́ fún wọn níwájú àwọn ère wọn, tí wọn sì mu ilé Israẹli ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀, nítorí náà, Èmi tí búra nípa nína ọwọ́ sókè pé, wọn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Como eles ministraram a eles diante de seus ídolos, e se tornaram um obstáculo de iniqüidade para a casa de Israel, por isso levantei minha mão contra eles”, diz o Senhor Javé, “e eles suportarão sua iniqüidade”.
13 Wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi láti ṣe ìránṣẹ́ fún mi, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí súnmọ́ nǹkan kan nínú àwọn ohun mímọ́ mi tàbí ẹbọ mi mímọ́ jùlọ; wọn gbọdọ̀ gba ìtìjú ìwà ìríra wọn.
Eles não se aproximarão de mim, para executar o ofício de sacerdote para mim, nem se aproximarão de nenhuma das minhas coisas santas, das coisas que são santíssimas; mas suportarão sua vergonha e suas abominações que cometeram”.
14 Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo iṣẹ́ tí a gbọdọ̀ ṣe níbẹ̀.
No entanto, farei deles artistas do dever da casa, por todos os seus serviços e por tudo o que nela for feito.
15 “‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi àti àwọn ìran Sadoku tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
“““Mas os sacerdotes levíticos, os filhos de Zadok, que cumpriram o dever de meu santuário quando os filhos de Israel se desviaram de mim, se aproximarão de mim para ministrar a mim. Eles estarão diante de mim para me oferecer a gordura e o sangue”, diz o Senhor Yahweh.
16 Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ súnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.
“Eles entrarão em meu santuário, e se aproximarão da minha mesa, para ministrar a mim, e guardarão minha instrução.
17 “‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ ẹ̀wù ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.
“““Será que quando entrarem pelos portões do tribunal interno, serão vestidos com roupas de linho. Nenhuma lã virá sobre eles enquanto ministrarem nos portões do pátio interno, e dentro dele.
18 Wọ́n yóò sì dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò sì gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.
Eles terão turbantes de linho na cabeça, e calças de linho na cintura. Eles não se vestirão com nada que os faça suar.
19 Nígbà tí wọ́n bá lọ sì àgbàlá òde níbi tí àwọn ènìyàn wà, wọn gbọdọ̀ bọ́ ẹ̀wù tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́, ki wọn sì fi wọn sílẹ̀ sí àwọn yàrá mímọ́ náà, kí wọn kí ó sì wọ ẹ̀wù mìíràn, wọn kì yóò sì fi ẹ̀wù wọn sọ àwọn ènìyàn di mímọ́.
Quando saírem para o pátio exterior, mesmo para o pátio exterior para o povo, despirão suas vestes nas quais ministram e as colocarão nos quartos sagrados. Vestirão outras vestes, para não santificar o povo com suas vestes.
20 “‘Wọn kò gbọdọ̀ fá irun, wọn kò sì gbọdọ̀ jẹ́ kí irun wọn gùn, ṣùgbọ́n wọn gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí wọn wà ní gígẹ̀.
“““Eles não devem raspar a cabeça, nem permitir que suas fechaduras cresçam muito tempo. Eles só cortarão os cabelos de suas cabeças.
21 Àlùfáà kankan kò gbọdọ̀ mu ọtí nígbà tí ó bá wọ àgbàlá tí inú.
““Nenhum sacerdote deve beber vinho quando entrar na corte interna.
22 Wọn ko gbọdọ̀ fẹ́ opó ni ìyàwó, wọn kò sì gbọdọ̀ kọ ìyàwó wọn sílẹ̀, wọ́n lè fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ti kò tí i mọ ọkùnrin rí, tí ó sì jẹ́ ìran àwọn ọmọ Israẹli, tàbí kí wọn fẹ́ àwọn opó àlùfáà.
Eles não levarão para suas esposas uma viúva, ou uma viúva que seja repudiada; mas levarão virgens da descendência da casa de Israel, ou uma viúva que seja viúva de um sacerdote.
23 Wọn yóò sì fi ìyàtọ̀ tí ó wà láàrín mímọ́ àti àìmọ́ kọ́ àwọn ènìyàn mi, wọn yóò sì fihàn wọ́n bi wọn yóò ṣe dá aláìmọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí mímọ́.
Ensinarão ao meu povo a diferença entre o santo e o comum, e o farão discernir entre o impuro e o limpo.
24 “‘Nínú èyíkéyìí èdè-àìyedè, àwọn àlùfáà ní yóò dúró gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin mi. Wọ́n ní láti pa àwọn òfin àti àṣẹ mi mọ́ ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn, wọn sì gbọdọ̀ ya ọjọ́ ìsinmi mi ní mímọ́.
“““Em uma controvérsia, eles se levantarão para julgar. Eles a julgarão de acordo com minhas ordenanças. Eles manterão minhas leis e meus estatutos em todas as minhas festas designadas. Tornarão santos os meus sábados.
25 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nípa sísún mọ́ òkú ènìyàn; ṣùgbọ́n ti òkú ènìyàn yẹn bá jẹ́ baba tàbí ìyá rẹ̀, àbúrò rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin ti kò i ti lọ́kọ, nígbà náà o le sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
“““Eles não devem ir a nenhuma pessoa morta para se contaminar; mas para pai, ou para mãe, ou para filho, ou para filha, para irmão, ou para irmã que não teve marido, eles podem se contaminar.
26 Lẹ́yìn ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, ki òun kí ó dúró fún ọjọ́ méje.
Depois que ele estiver limpo, eles contarão com ele sete dias.
27 Ní ọjọ́ ti yóò wọ àgbàlá ti inú ni ibi mímọ́ láti ṣe ìránṣẹ́ ibi mímọ́, ni kí òun kí ó rú ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
No dia em que ele entrar no santuário, na corte interna, para ministrar no santuário, ele oferecerá sua oferta pelo pecado”, diz o Senhor Yahweh.
28 “‘Èmi ni yóò jẹ́ ogún kan ṣoṣo tí àwọn àlùfáà yóò ní. Ẹ kì yóò fún wọn ni ìpín kankan ní Israẹli, Èmi ni yóò jẹ́ ìní wọn.
“'Eles terão uma herança: Eu sou sua herança; e vocês não lhes darão nenhuma posse em Israel”. Eu sou sua possessão.
29 Wọn yóò jẹ ọrẹ ẹbọ jíjẹ, ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ ìrékọjá; gbogbo ohun tí a bá yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ni Israẹli ni yóò jẹ́ tiwọn.
Eles comerão a oferta de refeição, a oferta pelo pecado e a oferta pela culpa; e toda coisa devota em Israel será deles.
30 Èyí tí ó dára jùlọ nínú gbogbo àkọ́so èso àti ọrẹ yín yóò jẹ́ ti àwọn àlùfáà. Ẹ ó sì fi àkọ́pò ìyẹ̀fun yín fún wọn kí ìbùkún lè wà lórí gbogbo ilé yín.
As primícias de cada coisa, e cada oferta de tudo, de todas as suas ofertas, serão para o sacerdote. Você também dará aos sacerdotes a primeira de sua massa, para fazer descansar uma bênção sobre sua casa.
31 Àwọn àlùfáà kì yóò jẹ́ ohunkóhun bí i ẹyẹ tàbí ẹranko, tí ó ti kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí ti ẹranko ńlá fàya.
Os sacerdotes não comerão de nada que morra por si mesmo ou que seja rasgado, seja pássaro ou animal.

< Ezekiel 44 >