< Ezekiel 44 >

1 Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, ó sì wà ní títì.
Ningĩ mũndũ ũcio akĩnjookia nginya kĩhingo-inĩ kĩa nyumĩrĩra ya handũ-harĩa-haamũre, kĩrĩa kĩangʼetheire mwena wa irathĩro, nakĩo kĩarĩ kĩhinge.
2 Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu-ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ ṣí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí gbà ibẹ̀ wọlé.
Nake Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Kĩhingo gĩkĩ kĩrĩikaraga kĩrĩ kĩhinge. Gĩtikanahingũrwo; gũtirĩ mũndũ ũgaagĩtoonyera. Kĩrĩikaraga kĩhingĩtwo tondũ nĩkĩo Jehova, Ngai wa Isiraeli, aatoonyeire.
3 Ọmọ-aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu-ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìloro ẹnu-ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”
Mũthamaki we mwene nowe wiki ũngĩikara mwena wa thĩinĩ wa itoonyero rĩu na arĩĩre irio hau mbere ya Jehova. Arĩĩtoonyagĩra gĩthaku gĩa itoonyero rĩu, na akiuma na nja akoimĩra njĩra o ro ĩyo.”
4 Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu-ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ̀.
Ningĩ mũndũ ũcio akĩndwara na njĩra ya kĩhingo kĩa mwena wa gathigathini nginya hau mbere ya hekarũ. Ngĩcũthĩrĩria, ngĩona riiri wa Jehova ũiyũrĩte hekarũ ĩyo ya Jehova, na niĩ ngĩĩgũithia, ngĩturumithia ũthiũ thĩ.
5 Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáradára, fetísílẹ̀ dáradára kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa òfin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.
Nake Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Mũrũ wa mũndũ, rora wega, na ũthikĩrĩrie wega, na ũrũmbũiye maũndũ mothe marĩa ngũkwĩra makoniĩ mawatho mothe megiĩ hekarũ ya Jehova. Rũmbũiya ũhoro wa itoonyero rĩa hekarũ, na njĩra ciothe cia kuuma handũ-harĩa-haamũre.
6 Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Israẹli!
Ĩra andũ aya aremi a nyũmba ya Isiraeli atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli, maũndũ manyu ma magigi nĩmaiganĩte!
7 Ní àfikún pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìríra rẹ tí ó kù, ìwọ mú àwọn àjèjì aláìkọlà àyà àti ara wá sí inú ibi mímọ́ mi, ní lílo ilé mi ní ìlòkulò nígbà tí ìwọ fi oúnjẹ fún mi, ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ìwọ sì ba májẹ̀mú mi jẹ́.
Hamwe na maũndũ marĩa mothe marĩ magigi mwekire, nĩmwatoonyirie andũ a kũngĩ matarĩ aruu ngoro na mwĩrĩ handũ-hakwa-harĩa-haamũre, mũgĩthaahia hekarũ yakwa rĩrĩa mwandutĩire irio, na maguta, na thakame, na mũgĩthũkia kĩrĩkanĩro gĩakwa.
8 Dípò kí ìwọ pa òfin mi mọ́, ìwọ fi àwọn mìíràn sí ibi mímọ́ mi.
Handũ ha kũruta wĩra wanyu ũrĩa wagĩrĩire ũkoniĩ maũndũ makwa marĩa matheru, mwatuire andũ angĩ arũgamĩrĩri a handũ-hakwa-harĩa-haamũre.
9 Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Àjèjì aláìkọlà àyà àti ara kò gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi, àti pẹ̀lú àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli.
Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Gũtirĩ mũndũ wa kũngĩ ũtarĩ mũruu ngoro na mwĩrĩ ũngĩtoonya handũ-hakwa-harĩa-haamũre, o na angĩkorwo nĩ andũ a kũngĩ arĩa matũũranagia na andũ a Isiraeli.
10 “‘Àwọn Lefi tí wọn rìn jìnnà kúrò lọ́dọ̀ mi nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ṣìnà, ti wọ́n sì ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi láti tọ àwọn ère wọn lẹ́yìn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
“‘Alawii arĩa maanjehereire makĩndaihĩrĩria hĩndĩ ĩrĩa andũ a Isiraeli maaturuurire na makĩehera harĩ niĩ makĩrũmĩrĩra mĩhianano yao-rĩ, no nginya magaacookererwo nĩ mehia mao.
11 Wọn le sìn mi ní ibi mímọ́ mi, kí wọn ṣe ìtọ́jú àwọn ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run, kí wọn sì ṣe ìránṣẹ́ nínú rẹ̀; wọn le pa ẹbọ sísun, ki wọn sì rú ẹbọ fún àwọn ènìyàn, kí wọn sì dúró níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
Andũ acio no matungatage handũ-hakwa-harĩa-haamũre, na maikaragie ihingo cia hekarũ o na matungatage thĩinĩ wayo; no mathĩnje nyamũ cia maruta ma njino, na marutagĩre andũ magongona mao, na marũgamage mbere ya andũ makamatungatĩra.
12 Ṣùgbọ́n nítorí pé wọn ṣe ìránṣẹ́ fún wọn níwájú àwọn ère wọn, tí wọn sì mu ilé Israẹli ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀, nítorí náà, Èmi tí búra nípa nína ọwọ́ sókè pé, wọn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.
No rĩrĩ, tondũ nĩo maamatungatĩire marĩ mbere ya mĩhianano yao, na magĩtũma andũ a nyũmba ya Isiraeli magũe mehia-inĩ-rĩ, nĩ ũndũ ũcio na niĩ nĩndĩhĩtĩte njoete guoko na igũrũ atĩ no nginya magaacookererwo nĩ mehia mao, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
13 Wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi láti ṣe ìránṣẹ́ fún mi, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí súnmọ́ nǹkan kan nínú àwọn ohun mímọ́ mi tàbí ẹbọ mi mímọ́ jùlọ; wọn gbọdọ̀ gba ìtìjú ìwà ìríra wọn.
Andũ acio matigacooka kũnguhĩrĩria mandungatagĩre ta athĩnjĩri-Ngai, kana makuhĩrĩrie kĩndũ o na kĩrĩkũ kĩa indo ciakwa iria theru, kana maruta makwa marĩa matheru mũno; no nginya magaacookererwo nĩ gĩconoko kĩa maũndũ marĩa marĩ magigi maneeka.
14 Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo iṣẹ́ tí a gbọdọ̀ ṣe níbẹ̀.
No nĩngamatua arũgamĩrĩri a maũndũ ma hekarũ, na mawĩra mothe marĩa mabataire kũrutwo kũu thĩinĩ.
15 “‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi àti àwọn ìran Sadoku tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
“‘No rĩrĩ, athĩnjĩri-Ngai, acio marĩ Alawii na a rũciaro rwa Zadoku, o acio maarutire mawĩra ma handũ-hakwa-harĩa-haamũre na wĩhokeku rĩrĩa andũ a Isiraeli meeherire makiuma harĩ niĩ, nĩo marĩnguhagĩrĩria makandungatĩra; marĩrũgamaga mbere yakwa makaruta magongona ma maguta na ma thakame, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
16 Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ súnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.
Acio oiki nĩo marĩtoonyaga handũ-hakwa-harĩa-haamũre; acio oiki nĩo marĩĩkuhagĩrĩria metha yakwa makandungatĩra na makaruta wĩra wakwa.
17 “‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ ẹ̀wù ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.
“‘Hĩndĩ ĩrĩa megũtoonya ihingo-inĩ cia nja ya na thĩinĩ, marĩĩhumbaga nguo cia gatani; matikanehumbe nguo o na ĩmwe ya guoya wa ngʼondu hĩndĩ ĩrĩa megũtungata ihingo-inĩ cia nja ĩrĩa ya na thĩinĩ, kana kũu hekarũ thĩinĩ.
18 Wọ́n yóò sì dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò sì gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.
Nĩmeyohage iremba cia gatani mĩtwe, na nguo cia gatani cia thĩinĩ njohero-inĩ. Matikanehumbe kĩndũ o na kĩrĩkũ kĩngĩtũma mathigine.
19 Nígbà tí wọ́n bá lọ sì àgbàlá òde níbi tí àwọn ènìyàn wà, wọn gbọdọ̀ bọ́ ẹ̀wù tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́, ki wọn sì fi wọn sílẹ̀ sí àwọn yàrá mímọ́ náà, kí wọn kí ó sì wọ ẹ̀wù mìíràn, wọn kì yóò sì fi ẹ̀wù wọn sọ àwọn ènìyàn di mímọ́.
Hĩndĩ ĩrĩa mekuuma matoonye nja ya nyumĩrĩra kũrĩa andũ marĩ-rĩ, makaruta nguo iria megũtungataga nacio, na magacitiga tũnyũmba-inĩ tũrĩa twamũre, na makehumba nguo ingĩ, nĩgeetha matikae kwamũra andũ acio na ũndũ wa nguo icio ciao.
20 “‘Wọn kò gbọdọ̀ fá irun, wọn kò sì gbọdọ̀ jẹ́ kí irun wọn gùn, ṣùgbọ́n wọn gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí wọn wà ní gígẹ̀.
“‘Matikanenjwo njuĩrĩ ĩthire mĩtwe, kana mareke njuĩrĩ ciao iraihe mũno, no nĩ maigage njuĩrĩ ciao cia mĩtwe irĩ nenge.
21 Àlùfáà kankan kò gbọdọ̀ mu ọtí nígbà tí ó bá wọ àgbàlá tí inú.
Ningĩ gũtikanagĩe na mũthĩnjĩri-Ngai ũkũnyua ndibei rĩrĩa egũtoonya nja ya na thĩinĩ.
22 Wọn ko gbọdọ̀ fẹ́ opó ni ìyàwó, wọn kò sì gbọdọ̀ kọ ìyàwó wọn sílẹ̀, wọ́n lè fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ti kò tí i mọ ọkùnrin rí, tí ó sì jẹ́ ìran àwọn ọmọ Israẹli, tàbí kí wọn fẹ́ àwọn opó àlùfáà.
Matikanahikie atumia a ndigwa, kana mahikie atumia arĩa matiganĩte na athuuri ao; no rĩrĩ, no mahikie airĩtu gathirange a rũciaro rwa andũ a Isiraeli, kana atumia a ndigwa a athĩnjĩri-Ngai.
23 Wọn yóò sì fi ìyàtọ̀ tí ó wà láàrín mímọ́ àti àìmọ́ kọ́ àwọn ènìyàn mi, wọn yóò sì fihàn wọ́n bi wọn yóò ṣe dá aláìmọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí mímọ́.
No nginya marutage andũ akwa ũtiganu wa maũndũ marĩa matheru na marĩa ma ndũire, na mamoonagie gũkũũrana maũndũ marĩa marĩ thaahu na marĩa matarĩ thaahu.
24 “‘Nínú èyíkéyìí èdè-àìyedè, àwọn àlùfáà ní yóò dúró gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin mi. Wọ́n ní láti pa àwọn òfin àti àṣẹ mi mọ́ ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn, wọn sì gbọdọ̀ ya ọjọ́ ìsinmi mi ní mímọ́.
“‘Kũngĩgĩa ngarari-rĩ, athĩnjĩri-Ngai no nginya matuithanagie ciira, na maũtue kũringana na matuĩro makwa ma ciira. Nĩmarĩmenyagĩrĩra mawatho makwa na kĩrĩra kĩa watho wakwa wa kũrũmĩrĩrwo igũrũ rĩa ciathĩ ciakwa ciothe iria njathane, na maikaragie Thabatũ ciakwa irĩ theru.
25 “‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nípa sísún mọ́ òkú ènìyàn; ṣùgbọ́n ti òkú ènìyàn yẹn bá jẹ́ baba tàbí ìyá rẹ̀, àbúrò rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin ti kò i ti lọ́kọ, nígbà náà o le sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
“‘Mũthĩnjĩri-Ngai ndakanethaahie na ũndũ wa gũkuhĩrĩria kĩimba; no rĩrĩ, ũrĩa ũkuĩte angĩkorwo nĩ ithe kana nyina, kana mũriũ kana mwarĩ, kana mũrũ wa nyina kana mwarĩ wa nyina ũtahikĩte-rĩ, hĩndĩ ĩyo no ethaahie.
26 Lẹ́yìn ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, ki òun kí ó dúró fún ọjọ́ méje.
Aarĩkia gũtherio-rĩ, no nginya eterere mĩthenya mũgwanja.
27 Ní ọjọ́ ti yóò wọ àgbàlá ti inú ni ibi mímọ́ láti ṣe ìránṣẹ́ ibi mímọ́, ni kí òun kí ó rú ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Mũthenya ũrĩa agaacooka gũtoonya nja ĩrĩa ya na thĩinĩ ya handũ-harĩa-haamũre nĩguo agatungate thĩinĩ wa handũ-harĩa-haamũre-rĩ, no nginya erutĩre iruta rĩa mehia, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
28 “‘Èmi ni yóò jẹ́ ogún kan ṣoṣo tí àwọn àlùfáà yóò ní. Ẹ kì yóò fún wọn ni ìpín kankan ní Israẹli, Èmi ni yóò jẹ́ ìní wọn.
“‘Niĩ no niĩ igai rĩa athĩnjĩri-Ngai. Mũtikanamagaĩre igai gũkũ bũrũri wa Isiraeli; Nĩ niĩ ngũtuĩka igai rĩao.
29 Wọn yóò jẹ ọrẹ ẹbọ jíjẹ, ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ ìrékọjá; gbogbo ohun tí a bá yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ni Israẹli ni yóò jẹ́ tiwọn.
Marĩĩrĩĩaga maruta ma ngano, na maruta ma mehia, na maruta ma mahĩtia; nakĩo kĩndũ o gĩothe kĩrĩa kĩrutĩirwo Jehova gũkũ bũrũri wa Isiraeli gĩgaatuĩka kĩao.
30 Èyí tí ó dára jùlọ nínú gbogbo àkọ́so èso àti ọrẹ yín yóò jẹ́ ti àwọn àlùfáà. Ẹ ó sì fi àkọ́pò ìyẹ̀fun yín fún wọn kí ìbùkún lè wà lórí gbogbo ilé yín.
Maciaro mothe ma mbere marĩa mega, na iheo cianyu ciothe cia mwanya, igaatuĩka cia athĩnjĩri-Ngai. No nginya mũmaheage gĩcunjĩ kĩa mbere kĩa mũtu ũrĩa mũhinyu nĩgeetha kĩrathimo gĩtũũre kwanyu mĩciĩ.
31 Àwọn àlùfáà kì yóò jẹ́ ohunkóhun bí i ẹyẹ tàbí ẹranko, tí ó ti kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí ti ẹranko ńlá fàya.
Athĩnjĩri-Ngai matikanarĩe nyamũ o na ĩrĩkũ ĩngĩkorwo ĩkuĩte, ĩrĩ nyoni, kana matigari ma nyamũ yũragĩtwo nĩ nyamũ ĩngĩ.

< Ezekiel 44 >