< Ezekiel 43 >

1 Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà mú mi gba ti ẹnu-ọ̀nà tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn,
U meni dǝrwaziƣa, yǝni xǝrⱪⱪǝ ⱪaraydiƣan dǝrwaziƣa apardi;
2 mo sì ri ògo Ọlọ́run Israẹli ń bọ láti ìhà ìlà-oòrùn. Ohùn rẹ̀ dàbí híhó omi, ìtànṣán ògo rẹ̀ sì bo ilẹ̀.
Mana, Israilning Hudasining xan-xǝripi xǝrⱪ tǝrǝptin kǝldi; Uning awazi uluƣ sularning xarⱪiriƣan sadasidǝk idi; yǝr yüzi uning xan-xǝripi bilǝn yorutuldi.
3 Ó sì dàbí ìran tí mo rí, gẹ́gẹ́ bí ìran tí mo rí nígbà tí mo wá láti pa ìlú náà run; ìran náà sì dà bí ìran tí mo rí lẹ́bàá odò Kebari, mo sì dojú mi bolẹ̀.
Mǝn kɵrgǝn bu alamǝt kɵrünüx bolsa, u xǝⱨǝrni ⱨalak ⱪilixⱪa kǝlgǝn ⱪetimda kɵrgǝn alamǝt kɵrünüxtǝk boldi; alamǝt kɵrünüxlǝr yǝnǝ mǝn Kewar dǝryasi boyida turup kɵrgǝn alamǝt kɵrünüxtǝk boldi; mǝn düm yiⱪildim.
4 Ògo Olúwa gba ọ̀nà tí o dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn wọ inú ilé Ọlọ́run wá.
Pǝrwǝrdigarning xan-xǝripi xǝrⱪⱪǝ ⱪaraydiƣan dǝrwaza arⱪiliⱪ ibadǝthaniƣa kirdi;
5 Mo ni ìrusókè ẹ̀mí, ó sì mú mi lọ inú ilé ìdájọ́, sì kíyèsi ògo Olúwa kún inú ilé Ọlọ́run.
Roⱨ meni kɵtürüp, iqki ⱨoyliƣa apardi; mana, Pǝrwǝrdigarning xan-xǝripi ibadǝthanini toldurdi.
6 Nígbà tí ọkùnrin náà dúró ní ẹ̀gbẹ́ mi, mo gbọ́ ẹnìkan tí ó bá mi sọ̀rọ̀ láti inú ilé Ọlọ́run.
Ⱨeliⱪi kixi yenimda turƣanda, ibadǝthanining iqidin Birsining sɵzligǝn awazini anglidim;
7 Ó sì wí pé, “Ọmọ ènìyàn, èyí yìí ni ibi ìgúnwà mi àti ibi tí ó wà fún àtẹ́lẹsẹ̀ mi. Ibi yìí ni èmi yóò máa gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli títí láéláé. Ilé Israẹli kò ní ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mọ́ láéláé àwọn tàbí àwọn ọba wọn nípa àgbèrè àti àwọn ère aláìlẹ́mìí àwọn ọba wọn ní ibi gíga.
U manga: — I insan oƣli, bu Mening tǝhtim selinƣan jay, Mǝn ayaƣ basidiƣan, Mǝn Israillar arisida mǝnggügǝ turidiƣan jaydur; Israil jǝmǝtidikilǝr — ularning ɵzliri yaki padixaⱨliri buzuⱪluⱪi bilǝn yaki «yuⱪiri jaylar»da padixaⱨning jǝsǝtliri bilǝn Mening pak-muⱪǝddǝs namimni yǝnǝ ⱨeq bulƣimaydu.
8 Nígbà tí wọ́n ba gbé ìloro ilé wọn kángun sí ìloro ilé mi àti ìlẹ̀kùn wọn sì ẹ̀gbẹ́ ìlẹ̀kùn mi, pẹ̀lú ògiri nìkan ní àárín èmi pẹ̀lú wọn, wọ́n ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ìwà ìríra wọn. Nígbà náà ni mo pa wọ́n run ní ìbínú mi.
Ular ɵz bosuƣisini Mening bosuƣimning yeniƣa, ixik kexikini Mening ixik kexikimning yeniƣa salƣan, ular bilǝn Meni pǝⱪǝt bir tamla ayrip turatti, ular Mening pak-muⱪǝddǝs namimni yirginqlikliri bilǝn bulƣiƣan. Xunga Mǝn ƣǝzipim bilǝn ularni yoⱪitiwǝttim.
9 Nísinsin yìí jẹ́ kí wọn mú ìwà àgbèrè wọn àti àwọn ère aláìlẹ́mìí àwọn ọba wọn kúrò ni iwájú mi, èmi yóò sì gbé àárín wọn láéláé.
Əmdi ⱨazir ular buzuⱪluⱪini, padixaⱨlarning jǝsǝtlirini Mǝndin yiraⱪ ⱪilsun; wǝ Mǝn ular arisida mǝnggügǝ turimǝn.
10 “Ọmọ ènìyàn, ṣàpèjúwe ilé Ọlọ́run náà fún àwọn ènìyàn Israẹli kí ojú ẹ̀ṣẹ̀ wọn, lè tì wọ́n sì jẹ́ kí wọn wo àwòrán ilé náà,
— Əmdi sǝn, i insan oƣli, Israil jǝmǝtining ɵz ⱪǝbiⱨlikliridin hijalǝt boluxi üqün bu ɵyni ularƣa kɵrsitip bǝrgin; ular kallisida ibadǝthanini ɵlqǝp baⱪsun.
11 tí ojú gbogbo ohun tí wọn ti ṣe bá tì wọ́n, jẹ́ kí wọ́n mọ̀ àwòrán ilé Ọlọ́run náà bí wọ́n ṣe tò ó lẹ́sẹẹsẹ, àbájáde àti àbáwọlé rẹ̀ gbogbo àwòrán àti gbogbo òfin àti ìlànà rẹ̀. Kọ ìwọ̀nyí sílẹ̀ ní iwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ́ olóòtítọ́ si àwòrán rẹ̀, kí wọ́n sì tẹ̀lé gbogbo òfin rẹ̀.
Əgǝrdǝ ular ɵz ⱪilƣanliridin hijil bolsa, ǝmdi sǝn muxu ɵyning xǝklini, uning selinixini, qiⱪix yollirini, kirix yollirini wǝ barliⱪ layiⱨisini wǝ barliⱪ bǝlgilimilirini, — xundaⱪ, barliⱪ xǝklini wǝ barliⱪ ⱪanunlirini ayan ⱪilip bǝrgin; ularning pütkül xǝklini esidǝ tutuxi ⱨǝm uning bǝlgilimilirigǝ ǝmǝl ⱪilixi üqün, uni ularning kɵz aldiƣa yazƣin.
12 “Èyí yìí ní òfin ilé Ọlọ́run náà. Gbogbo àyíká lórí òkè gíga ní yóò jẹ́ ibi mímọ́ jùlọ. Bí èyí ni òfin tẹmpili náà.
Ibadǝthanining ⱪanuni xundaⱪ bolidu: U turƣan taƣning qoⱪⱪisining bekitilgǝn pasilƣiqǝ bolƣan dairisi «ǝng muⱪǝddǝs» bolidu; mana, bu ibadǝthanining ⱪanunidur.
13 “Ìwọ̀nyí ni wíwọ̀n pẹpẹ ìrúbọ ní gígùn ìgbọ̀nwọ́, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ni jíjìn, ó sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ni ìbú, igun rẹ̀ yípo àti etí rẹ̀ jẹ́ ìbú àtẹ́lẹwọ́ kan. Èyí yìí sì ni gíga pẹpẹ ìrúbọ náà.
Ⱪurbangaⱨning «[qong] gǝz»dǝ ɵlqǝngǝn ɵlqǝmliri xundaⱪ idi: — bu gǝz bolsa bir gǝz ⱪoxulƣan bir aliⱪan bolidu. Ⱪurbangaⱨning ǝtrapidiki ulining egizliki bir gǝz, kǝngliki bir gǝz, ǝtrapidiki girwiki bolsa bir aliⱪan idi. Mana bu ⱪurbangaⱨning uli idi.
14 Láti ìsàlẹ̀ rẹ̀ ni ilẹ̀ títí dé ìsàlẹ̀ igun rẹ̀, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì ni gíga o sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ní ìbú. Láti igun rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ títí dé igun rẹ̀ ti òkè tí ó yípo pẹpẹ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní gíga, igun náà sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ní ìbú.
Uning ulidin astinⱪi tǝkqigiqǝ ikki gǝz, kǝngliki bir gǝz idi; bu «kiqik tǝkqǝ»din «qong tǝkqǝ»giqǝ tɵt gǝz, kǝngliki bir gǝz idi;
15 Ibi ìdáná pẹpẹ ìrúbọ náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní gíga, ìwo mẹ́rẹ̀ẹ̀rin sì yọrí jáde sókè láti ibi ìdáná.
ⱪurbangaⱨning ot supisining egizliki tɵt gǝz idi; ot supisida tɵt münggüz qoⱪqiyip qiⱪip turatti.
16 Ibi ìdáná pẹpẹ náà jẹ́ igun mẹ́rin mẹ́rin lọ́gbọọgba, ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ní gígùn, o sì jẹ ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ní ìbú.
Ⱪurbangaⱨning ot supisining uzunluⱪi on ikki gǝz, kǝngliki on ikki gǝz bolup, u tɵt qasiliⱪ idi.
17 Igun ni apá òkè náà jẹ́ igun mẹ́rin lọ́gbọọgba, ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá ní gígùn, ó sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá ní ìbú, pẹ̀lú etí tí ó jẹ́ ìdajì ìgbọ̀nwọ́, ìsàlẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan yípo. Àtẹ̀gùn pẹpẹ ìrúbọ náà dojúkọ ìlà-oòrùn.”
Yuⱪiri tǝkqigiqimu tɵt qasiliⱪ idi, uzunluⱪi on tɵt gǝz, kǝngliki on tɵt gǝz; ǝtrapidiki girwiki bolsa yerim gǝz idi; astining kǝngliki bir gǝz idi; uningƣa qiⱪidiƣan pǝlǝmpiyi xǝrⱪⱪǝ ⱪaraytti.
18 Lẹ́yìn náà, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ̀nyí yóò jẹ́ òfin fún ìrúbọ ẹbọ sísun àti wíwọ̀n ẹ̀jẹ̀ sórí pẹpẹ nígbà tí a bá mọ pẹpẹ tán.
U manga xundaⱪ dedi: — I insan oƣli, Rǝb Pǝrwǝrdigar xundaⱪ dǝydu: Bu ⱪurbangaⱨ üstigǝ kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪlarni sunux wǝ üstigǝ ⱪan sepix üqün uni yasiƣan künidǝ, xular uning bǝlgilimiliri bolidu: —
19 Ẹ̀yin ní láti mú ọ̀dọ́ akọ màlúù gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrékọjá fún àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi, tí ìdílé Sadoku tí ó wá sí agbègbè láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ fún mi ní Olúwa Olódùmarè wí.
sǝn Lawiy ⱪǝbilisidin bolƣan, yǝni Mening hizmitimdǝ bolux üqün Manga yeⱪinlixidiƣan Zadok nǝslidikilǝrdin bolƣan kaⱨinlarƣa gunaⱨ ⱪurbanliⱪi süpitidǝ yax bir torpaⱪni berisǝn;
20 Ẹ ni láti mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, kí ẹ sì fi sórí ìwo mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà lórí pẹpẹ, àti lórí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ìjókòó náà àti sí gbogbo etí rẹ̀ yípo, ìwọ yóò sì sọ pẹpẹ di mímọ́, ìwọ yóò sì ṣe ètùtù rẹ̀.
sǝn uning ⱪenidin azraⱪ elip ⱪurbangaⱨning münggüzlirigǝ, qong tǝkqining tɵt burjikigǝ ⱨǝm ǝtrapidiki girwǝkliri üstigǝ sürisǝn; xuning bilǝn sǝn uni pakizlap wǝ uningƣa kafarǝt ⱪilisǝn.
21 Ìwọ gbọdọ̀ mú akọ màlúù fún ìrékọjá, ìwọ yóò sì sun ún ní apá ibi tí a sàmì sí ní agbègbè ilé Ọlọ́run ní ìta ibi mímọ́.
Sǝn gunaⱨ ⱪurbanliⱪi bolƣan torpaⱪni elip uning jǝsitini «muⱪǝddǝs jay»ning sirtida bolƣan, ibadǝthanidiki alaⱨidǝ bekitilgǝn jayda kɵydürisǝn;
22 “Ní ọjọ́ kejì ìwọ yóò fi ewúrẹ́, òbúkọ aláìlábàwọ́n fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, a sì gbọdọ̀ sọ pẹpẹ di mímọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti ṣọ́ di mímọ́ pẹ̀lú akọ màlúù.
ikkinqi künidǝ sǝn gunaⱨ ⱪurbanliⱪi süpitidǝ bejirim bir tekini sunisǝn; ular ⱪurbangaⱨni torpaⱪ bilǝn paklandurƣandǝk tekǝ bilǝn uni paklaydu.
23 Nígbà tí ìwọ bá parí ìsọdimímọ́, ìwọ yóò fi ọ̀dọ́ akọ màlúù àti ọ̀dọ́ àgbò aláìlábàwọ́n láti inú agbo fún ìrúbọ.
Sǝn uni pakliƣandin keyin, sǝn bejirim yax bir torpaⱪ, ⱪoy padisidin bejirim bir ⱪoqⱪarni sunisǝn;
24 Ìwọ yóò mú wọn lọ sí iwájú Olúwa, àwọn àlùfáà ni yóò fi iyọ̀ wọ́n wọn, wọn yóò sì fi wọ́n rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
sǝn ularni Pǝrwǝrdigarning aldiƣa sunisǝn; kaⱨinlar ularning üstigǝ tuz sepidu wǝ ularni Pǝrwǝrdigarƣa atap kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ süpitidǝ sunidu.
25 “Fún ọjọ́ méje, ìwọ ní láti pèsè akọ ewúrẹ́ kan lójoojúmọ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀; ìwọ yóò sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò láti inú agbo, méjèèjì yóò sì jẹ́ aláìlábàwọ́n.
Yǝttǝ kün sǝn ⱨǝr küni gunaⱨ ⱪurbanliⱪi süpitidǝ bir tekini sunisǝn; ular bejirim yax bir torpaⱪni, ⱪoy padisidin bejirim bir ⱪoqⱪarnimu sunidu.
26 Fún ọjọ́ méje wọn yóò jẹ́ ètùtù fún pẹpẹ, wọn yóò sì sọ ọ́ di mímọ́; nípa bẹ́ẹ̀ wọn yóò yà á sọ́tọ̀.
Ular yǝttǝ kün ⱪurbangaⱨ üqün kafarǝt ⱪilip uni paklaydu; xuning bilǝn ular uni pak-muⱪǝddǝs dǝp ayriydu.
27 Ní ìparí ọjọ́ wọ̀nyí, láti ọjọ́ mẹ́jọ síwájú, àwọn àlùfáà ni yóò gbé àwọn ẹbọ sísun rẹ àti ẹbọ ìdàpọ̀ rẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ. Lẹ́yìn náà, èmi yóò tẹ́wọ́gbà yín ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Bu künlǝr tügigǝndǝ, sǝkkizinqi küni wǝ xu kündin keyin, kaⱨinlar silǝrning kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪliringlarni wǝ inaⱪliⱪ ⱪurbanliⱪliringlarni ⱪurbangaⱨ üstigǝ sunidu; xuning bilǝn Mǝn silǝrni ⱪobul ⱪilimǝn, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.

< Ezekiel 43 >