< Ezekiel 43 >

1 Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà mú mi gba ti ẹnu-ọ̀nà tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn,
Et il me conduisit vers la porte qui regarde l'orient et il me fit entrer.
2 mo sì ri ògo Ọlọ́run Israẹli ń bọ láti ìhà ìlà-oòrùn. Ohùn rẹ̀ dàbí híhó omi, ìtànṣán ògo rẹ̀ sì bo ilẹ̀.
Et voilà que la gloire du Dieu d'Israël vint par la voie de l'orient, et le bruit qu'elle fit à son entrée était comme le bruit d'une grande multitude qui redouble ses clameurs; et à l'entour de cette gloire la terre resplendit comme une flamme.
3 Ó sì dàbí ìran tí mo rí, gẹ́gẹ́ bí ìran tí mo rí nígbà tí mo wá láti pa ìlú náà run; ìran náà sì dà bí ìran tí mo rí lẹ́bàá odò Kebari, mo sì dojú mi bolẹ̀.
Et la vision que j'eus fut comme la vision que j'avais eue lorsque je vins pour marquer la ville. Et j'eus la vision d'un char, comme dans la vision que j'avais eue sur le fleuve Chobar. Et je tombai la face contre terre.
4 Ògo Olúwa gba ọ̀nà tí o dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn wọ inú ilé Ọlọ́run wá.
Et la gloire du Seigneur entra dans le temple par la voie de la porte qui regarde l'orient.
5 Mo ni ìrusókè ẹ̀mí, ó sì mú mi lọ inú ilé ìdájọ́, sì kíyèsi ògo Olúwa kún inú ilé Ọlọ́run.
Et l'Esprit me ravit, et il m'introduisit dans le parvis intérieur, et voilà que le temple était plein de la gloire de Dieu.
6 Nígbà tí ọkùnrin náà dúró ní ẹ̀gbẹ́ mi, mo gbọ́ ẹnìkan tí ó bá mi sọ̀rọ̀ láti inú ilé Ọlọ́run.
Et je me tins immobile; et voilà qu'une voix me parla du temple, et l'homme se tenait auprès de moi.
7 Ó sì wí pé, “Ọmọ ènìyàn, èyí yìí ni ibi ìgúnwà mi àti ibi tí ó wà fún àtẹ́lẹsẹ̀ mi. Ibi yìí ni èmi yóò máa gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli títí láéláé. Ilé Israẹli kò ní ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mọ́ láéláé àwọn tàbí àwọn ọba wọn nípa àgbèrè àti àwọn ère aláìlẹ́mìí àwọn ọba wọn ní ibi gíga.
Et la voix me dit: Fils de l'homme, tu vois la place de mon trône et la trace de mes pieds; c'est ici que mon nom s'abritera pour tous les siècles au milieu de la maison d'Israël. Et la maison d'Israël, ses enfants et leurs rois ne profaneront plus mon saint nom, soit par leurs prostitutions, soit par les meurtres qu'au milieu d'eux commettaient leurs rois,
8 Nígbà tí wọ́n ba gbé ìloro ilé wọn kángun sí ìloro ilé mi àti ìlẹ̀kùn wọn sì ẹ̀gbẹ́ ìlẹ̀kùn mi, pẹ̀lú ògiri nìkan ní àárín èmi pẹ̀lú wọn, wọ́n ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ìwà ìríra wọn. Nígbà náà ni mo pa wọ́n run ní ìbínú mi.
Lorsqu'ils avaient mon portique près de leurs portiques, et mes portes auprès de leurs portes. Et ils avaient fait de mon mur comme un lien entre eux et moi; mais ils ont profané mon saint nom par leurs iniquités. Et je les ai broyés en ma colère, et ils ont péri.
9 Nísinsin yìí jẹ́ kí wọn mú ìwà àgbèrè wọn àti àwọn ère aláìlẹ́mìí àwọn ọba wọn kúrò ni iwájú mi, èmi yóò sì gbé àárín wọn láéláé.
Et maintenant, qu'ils répudient loin de moi leurs prostitutions, et je m'abriterai au milieu d'eux dans tous les siècles.
10 “Ọmọ ènìyàn, ṣàpèjúwe ilé Ọlọ́run náà fún àwọn ènìyàn Israẹli kí ojú ẹ̀ṣẹ̀ wọn, lè tì wọ́n sì jẹ́ kí wọn wo àwòrán ilé náà,
Et toi, fils de l'homme, montre ce temple à la maison d'Israël, et ils cesseront de pécher; montre-leur son plan et sa distribution.
11 tí ojú gbogbo ohun tí wọn ti ṣe bá tì wọ́n, jẹ́ kí wọ́n mọ̀ àwòrán ilé Ọlọ́run náà bí wọ́n ṣe tò ó lẹ́sẹẹsẹ, àbájáde àti àbáwọlé rẹ̀ gbogbo àwòrán àti gbogbo òfin àti ìlànà rẹ̀. Kọ ìwọ̀nyí sílẹ̀ ní iwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ́ olóòtítọ́ si àwòrán rẹ̀, kí wọ́n sì tẹ̀lé gbogbo òfin rẹ̀.
Et eux-mêmes accepteront les châtiments de toutes les choses qu'ils ont faites. Décris-leur le temple, ses issues, toute sa structure; fais-leur connaître ses règlements et toutes ses lois; décris-les devant eux, et ils garderont mes ordonnances et mes commandements, et ilsles mettront en pratique.
12 “Èyí yìí ní òfin ilé Ọlọ́run náà. Gbogbo àyíká lórí òkè gíga ní yóò jẹ́ ibi mímọ́ jùlọ. Bí èyí ni òfin tẹmpili náà.
Et tu leur montreras le plan du temple sur le sommet de la montagne, et toute son étendue sera sainte et sacrée.
13 “Ìwọ̀nyí ni wíwọ̀n pẹpẹ ìrúbọ ní gígùn ìgbọ̀nwọ́, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ni jíjìn, ó sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ni ìbú, igun rẹ̀ yípo àti etí rẹ̀ jẹ́ ìbú àtẹ́lẹwọ́ kan. Èyí yìí sì ni gíga pẹpẹ ìrúbọ náà.
Et voici les mesures de l'autel: il sera d'une grande coudée, c'est-à-dire d'une coudée et un palme; sa cavité aura une coudée; il aura une coudée de large, et un palme pour la corniche du rebord tout alentour. Et voici la hauteur de l'autel:
14 Láti ìsàlẹ̀ rẹ̀ ni ilẹ̀ títí dé ìsàlẹ̀ igun rẹ̀, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì ni gíga o sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ní ìbú. Láti igun rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ títí dé igun rẹ̀ ti òkè tí ó yípo pẹpẹ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní gíga, igun náà sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ní ìbú.
À partir du commencement de la cavité jusqu'au grand propitiatoire, deux coudées de haut sur une de large; et du petit propitiatoire an grand propitiatoire, quatre coudées de haut et une de large.
15 Ibi ìdáná pẹpẹ ìrúbọ náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní gíga, ìwo mẹ́rẹ̀ẹ̀rin sì yọrí jáde sókè láti ibi ìdáná.
Et l'Ariel sera de quatre coudées, et à partir de l'Ariel, au-dessous des cornes, il y aura une coudée.
16 Ibi ìdáná pẹpẹ náà jẹ́ igun mẹ́rin mẹ́rin lọ́gbọọgba, ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ní gígùn, o sì jẹ ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ní ìbú.
Et l'Ariel sera long de douze coudées sur douze de large; c'est un tétragone aux côtés égaux.
17 Igun ni apá òkè náà jẹ́ igun mẹ́rin lọ́gbọọgba, ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá ní gígùn, ó sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá ní ìbú, pẹ̀lú etí tí ó jẹ́ ìdajì ìgbọ̀nwọ́, ìsàlẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan yípo. Àtẹ̀gùn pẹpẹ ìrúbọ náà dojúkọ ìlà-oòrùn.”
Et le propitiatoire sera long de quatorze coudées sur quatorze de large; ses quatre côtéssont égaux. Et il a tout alentour une corniche d'une demi-coudée en saillie d'une coudée de hauteur; et ses degrés regardent l'orient.
18 Lẹ́yìn náà, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ̀nyí yóò jẹ́ òfin fún ìrúbọ ẹbọ sísun àti wíwọ̀n ẹ̀jẹ̀ sórí pẹpẹ nígbà tí a bá mọ pẹpẹ tán.
Et la voix me dit: Fils de l'homme, ainsi parle le Seigneur Dieu d'Israël: Voici la règle pour l'autel: du jour où il aura été fait, on y offrira des holocaustes, et on y versera le sang des victimes:
19 Ẹ̀yin ní láti mú ọ̀dọ́ akọ màlúù gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrékọjá fún àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi, tí ìdílé Sadoku tí ó wá sí agbègbè láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ fún mi ní Olúwa Olódùmarè wí.
Et tu donneras aux prêtres lévites, à. ceux de la famille de Sadduc, qui s'approchent de moi, dit le Seigneur Dieu, un veau choisi parmi le troupeau, afin de me le sacrifier pour le péché.
20 Ẹ ni láti mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, kí ẹ sì fi sórí ìwo mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà lórí pẹpẹ, àti lórí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ìjókòó náà àti sí gbogbo etí rẹ̀ yípo, ìwọ yóò sì sọ pẹpẹ di mímọ́, ìwọ yóò sì ṣe ètùtù rẹ̀.
Et ils prendront de son sang, et ils le mettront sur les quatre cornes de l'autel et sur les quatre angles du propitiatoire, et sur la base tout alentour, et ainsi ils le purifieront.
21 Ìwọ gbọdọ̀ mú akọ màlúù fún ìrékọjá, ìwọ yóò sì sun ún ní apá ibi tí a sàmì sí ní agbègbè ilé Ọlọ́run ní ìta ibi mímọ́.
Et ils prendront le veau offert pour le péché, et il sera brûlé par le feu, dans le lieu séparé du temple, hors du sanctuaire.
22 “Ní ọjọ́ kejì ìwọ yóò fi ewúrẹ́, òbúkọ aláìlábàwọ́n fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, a sì gbọdọ̀ sọ pẹpẹ di mímọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti ṣọ́ di mímọ́ pẹ̀lú akọ màlúù.
Et le second jour ils prendront deux chevreaux sans tache pour le péché, et ils purifieront l'autel, comme ils l'auront purifié avec le veau.
23 Nígbà tí ìwọ bá parí ìsọdimímọ́, ìwọ yóò fi ọ̀dọ́ akọ màlúù àti ọ̀dọ́ àgbò aláìlábàwọ́n láti inú agbo fún ìrúbọ.
Et lorsqu'ils auront achevé la purification, ils offriront un veau sans tache et un bélier sans tache.
24 Ìwọ yóò mú wọn lọ sí iwájú Olúwa, àwọn àlùfáà ni yóò fi iyọ̀ wọ́n wọn, wọn yóò sì fi wọ́n rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
Et vous les offrirez devant le Seigneur; et les prêtres les saupoudreront de sel, et ils les offriront en holocauste au Seigneur.
25 “Fún ọjọ́ méje, ìwọ ní láti pèsè akọ ewúrẹ́ kan lójoojúmọ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀; ìwọ yóò sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò láti inú agbo, méjèèjì yóò sì jẹ́ aláìlábàwọ́n.
Pendant sept jours, tu offriras chaque jour pour le péché un chevreau, un veau et un bélier choisis parmi les bœufs et les brebis; et on sacrifiera ces victimes, toutes sans tache,
26 Fún ọjọ́ méje wọn yóò jẹ́ ètùtù fún pẹpẹ, wọn yóò sì sọ ọ́ di mímọ́; nípa bẹ́ẹ̀ wọn yóò yà á sọ́tọ̀.
Durant sept jours. Et ils purifieront l'autel, ils le sanctifieront, et ils consacreront leurs mains.
27 Ní ìparí ọjọ́ wọ̀nyí, láti ọjọ́ mẹ́jọ síwájú, àwọn àlùfáà ni yóò gbé àwọn ẹbọ sísun rẹ àti ẹbọ ìdàpọ̀ rẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ. Lẹ́yìn náà, èmi yóò tẹ́wọ́gbà yín ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Et à partir du huitième jour et dans la suite les prêtres sacrifieront sur l'autel vos holocaustes et vos victimes pour le salut; et je vous agréerai, dit le Seigneur.

< Ezekiel 43 >