< Ezekiel 4 >

1 “Nísinsin yìí, ìwọ ọmọ ènìyàn, mú amọ̀ ṣíṣù kan, gbé e sí iwájú rẹ, kí o sì ya àwòrán ìlú Jerusalẹmu sí orí rẹ̀.
A ty, synu człowieczy, weź sobie glinianą tabliczkę, połóż ją przed sobą i wyryj na niej miasto Jerozolimę;
2 Kí o sì dó tì í, kí o sì mọ ilé ìṣọ́ tì í, kí o sì mọ odi tì í, kí o sì gbé ogun sí i, kí o sì to òòlù yí i ká.
Sporządź jego oblężenie, zbuduj przeciwko niemu szańce, usyp przeciwko niemu wał, uszykuj przeciwko niemu wojska i ustaw przeciwko niemu tarany dokoła.
3 Kí o sì fi àwo irin kan ṣe ògiri láàrín rẹ̀ àti ìlú yìí, kí o sì kọjú sí i, a ó sì dó tì í, ìwọ yóò sì dó tì í. Èyí yóò jẹ́ àmì fún ilé Israẹli.
Następnie weź sobie patelnię żelazną, postaw ją [jakby] mur żelazny pomiędzy sobą a miastem i odwróć swą twarz przeciwko niemu. Ono będzie oblężone, a ty będziesz je oblegał. To [będzie] znak dla domu Izraela.
4 “Lẹ́yìn èyí, lọ fi ẹ̀gbẹ́ òsì dùbúlẹ̀, kí o sì gbé ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli lé orí ara rẹ. Iye ọjọ́ tí ìwọ bá fi sùn náà ni ìwọ yóò fi ru ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Potem połóż się na lewym boku i złóż na nim nieprawość domu Izraela. Ile dni będziesz na nim leżał, tak długo będziesz znosił ich nieprawość.
5 Nítorí mo fi iye ọdún tí wọ́n fi ṣẹ̀ fún ọ gẹ́gẹ́ bí iye ọjọ́ tí ìwọ yóò lò. Nítorí náà, ìwọ yóò ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
A ja wyznaczam ci lata ich nieprawości według liczby dni: trzysta dziewięćdziesiąt dni. Tak długo będziesz znosił nieprawość domu Izraela.
6 “Tí o bá parí èyí, tún fi ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún dùbúlẹ̀ kí o sì ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Juda fún ogójì ọjọ́, nítorí pé ọjọ́ kan ló dúró fún ọdún kan.
A [gdy] je wypełnisz, położysz się na prawym boku i będziesz znosił nieprawość domu Judy przez czterdzieści dni. Wyznaczam ci jeden dzień za każdy rok.
7 Ìwọ dojúkọ ìgbógunti Jerusalẹmu, na ọwọ́ rẹ sí i, kí o sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìlú náà.
Tak więc obróć swoją twarz na oblężenie Jerozolimy, obnaż swoje ramię i prorokuj przeciwko niej.
8 Èmi yóò dè ọ́ ní okùn dé bi pé ìwọ kò ní í le yírapadà láti ìhà ọ̀tún sí ìhà òsì títí tí ọjọ́ ìgbóguntì rẹ yóò fi pé.
A oto kładę na ciebie pęta, abyś nie mógł się obrócić z jednego boku na drugi, aż wypełnisz dni swego oblężenia.
9 “Mú alikama, ọkà bàbà àti barle, erèé àti lẹntili, jéró àti ẹwẹ; fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe àkàrà tí ìwọ yóò máa jẹ nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀ fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
Weź sobie też pszenicę, jęczmień, bób, soczewicę, proso i orkisz, włóż to do jednego naczynia i przygotuj sobie z tego chleb, a będziesz go jadł przez tyle dni, ile będziesz leżeć na swym boku – przez trzysta dziewięćdziesiąt dni.
10 Wọn òsùwọ̀n ogún ṣékélì oúnjẹ tí ìwọ yóò máa jẹ lójoojúmọ́ kí o sì máa jẹ ẹ́ ní àkókò tí a ti yà sọ́tọ̀.
A waga twego pokarmu, który będziesz jadł, wyniesie dwadzieścia syklów na dzień. Będziesz go jadł w ustalonym czasie.
11 Bákan náà, wọn ìdámẹ́fà omi, kí ìwọ ó sì máa mú ní àkókò tí a yà sọ́tọ̀.
Także wodę będziesz pił w określonej ilości; szóstą [część] hinu będziesz pił w ustalonym czasie.
12 Ìwọ yóò sì jẹ ẹ́ bí àkàrà barle; dín in ní ojú àwọn ènìyàn, ìgbẹ́ ènìyàn ni kí o fi dáná rẹ.”
[Chleb] będziesz jadł jak podpłomyki jęczmienne, upieczesz go na ich oczach na ludzkich odchodach.
13 Olúwa sọ pé, “Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò jẹ oúnjẹ àìmọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí èmi yóò lé wọn lọ.”
I PAN powiedział: Tak synowie Izraela będą jeść swój nieczysty chleb wśród pogan, do których ich wypędzę.
14 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Kò rí bẹ́ẹ̀ Olúwa Olódùmarè! Láti ìgbà èwe mi di ìsinsin yìí èmi kò tí ì sọ ara mi di aláìmọ́ rí. Èmi kò tí ì jẹ ohun tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko búburú fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Bẹ́ẹ̀ ni ẹran àìmọ́ kan kò tí ì wọ ẹnu mi rí.”
I powiedziałem: Ach, Panie BOŻE! Oto moja dusza [nigdy] się nie splamiła: od mojego dzieciństwa aż do tej pory nie jadłem padliny ani tego, co [zwierzę] rozszarpało; żadne mięso obrzydłe nie weszło do moich ust.
15 Nígbà náà ló wí fún mi pé, “Wò ó, Èmi ó fún ọ ní ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn. Èmi yóò mú ki ó dín àkàrà rẹ lórí ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn.”
Ale on powiedział do mnie: Oto daję ci odchody wołowe zamiast odchodów ludzkich, abyś sobie na nich upiekł chleb.
16 Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èmi yóò dáwọ́ ìpèsè oúnjẹ dúró ní Jerusalẹmu. Ní pípín ni àwọn ènìyàn yóò máa pín oúnjẹ jẹ pẹ̀lú ìfọkànsọ́nà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wọn yóò máa mu omi pẹ̀lú ìdààmú,
Potem powiedział do mnie: Synu człowieczy, oto ja zniszczę zapas chleba w Jerozolimie, tak że będą jedli chleb w odważonej ilości i w zmartwieniu i będą pić wodę w odmierzonej ilości i z przerażeniem;
17 nítorí pé oúnjẹ àti omi yóò wọ́n. Wọn yóò máa wo ara wọn pẹ̀lú ìyanu, èmi yóò sì jẹ́ kí wọ́n ṣọ̀fọ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Aby im brakowało chleba i wody, aby każdy z nich był przerażony i niszczał w swoich nieprawościach.

< Ezekiel 4 >