< Ezekiel 4 >

1 “Nísinsin yìí, ìwọ ọmọ ènìyàn, mú amọ̀ ṣíṣù kan, gbé e sí iwájú rẹ, kí o sì ya àwòrán ìlú Jerusalẹmu sí orí rẹ̀.
«و تو نیز‌ای پسر انسان آجری بگیر و آن راپیش روی خود بگذار و شهر اورشلیم را برآن نقش نما.۱
2 Kí o sì dó tì í, kí o sì mọ ilé ìṣọ́ tì í, kí o sì mọ odi tì í, kí o sì gbé ogun sí i, kí o sì to òòlù yí i ká.
و آن را محاصره کن و در برابرش برجها ساخته، سنگری در مقابلش برپا نما و به اطرافش اردو زده، منجنیقها به هر سوی آن برپاکن.۲
3 Kí o sì fi àwo irin kan ṣe ògiri láàrín rẹ̀ àti ìlú yìí, kí o sì kọjú sí i, a ó sì dó tì í, ìwọ yóò sì dó tì í. Èyí yóò jẹ́ àmì fún ilé Israẹli.
و تابه آهنین برای خود گرفته، آن را در میان خود و شهر، دیواری آهنین بگذار و روی خود رابر آن بدار و محاصره خواهد شد و تو آن رامحاصره کن تا آیتی به جهت خاندان اسرائیل بشود.۳
4 “Lẹ́yìn èyí, lọ fi ẹ̀gbẹ́ òsì dùbúlẹ̀, kí o sì gbé ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli lé orí ara rẹ. Iye ọjọ́ tí ìwọ bá fi sùn náà ni ìwọ yóò fi ru ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
پس تو بر پهلوی چپ خود بخواب و گناه خاندان اسرائیل را بر آن بگذار. موافق شماره روزهایی که بر آن بخوابی، گناه ایشان را متحمل خواهی شد.۴
5 Nítorí mo fi iye ọdún tí wọ́n fi ṣẹ̀ fún ọ gẹ́gẹ́ bí iye ọjọ́ tí ìwọ yóò lò. Nítorí náà, ìwọ yóò ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
و من سالهای گناه ایشان را مطابق شماره روزها یعنی سیصد و نود روز بر تونهاده‌ام. پس متحمل گناه خاندان اسرائیل خواهی شد.۵
6 “Tí o bá parí èyí, tún fi ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún dùbúlẹ̀ kí o sì ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Juda fún ogójì ọjọ́, nítorí pé ọjọ́ kan ló dúró fún ọdún kan.
و چون اینها را به انجام رسانیده باشی، بازبه پهلوی راست خود بخواب و چهل روزمتحمل گناه خاندان یهودا خواهی شد. هر روزی را به جهت سالی برای تو قرار داده‌ام.۶
7 Ìwọ dojúkọ ìgbógunti Jerusalẹmu, na ọwọ́ rẹ sí i, kí o sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìlú náà.
و بازوی خود را برهنه کرده، روی به محاصره اورشلیم بدار و به ضد آن نبوت کن.۷
8 Èmi yóò dè ọ́ ní okùn dé bi pé ìwọ kò ní í le yírapadà láti ìhà ọ̀tún sí ìhà òsì títí tí ọjọ́ ìgbóguntì rẹ yóò fi pé.
و اینک بندها بر تومی نهم و تا روزهای محاصره ات را به اتمام نرسانیده باشی از پهلو به پهلوی دیگرت نخواهی غلطید.۸
9 “Mú alikama, ọkà bàbà àti barle, erèé àti lẹntili, jéró àti ẹwẹ; fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe àkàrà tí ìwọ yóò máa jẹ nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀ fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
پس گندم و جو و باقلا و عدس و ارزن وجلبان برای خود گرفته، آنها را در یک ظرف بریزو خوراکی از آنها برای خود بپز و تمامی روزهایی که به پهلوی خود می‌خوابی، یعنی سیصد و نود روز آن را خواهی خورد.۹
10 Wọn òsùwọ̀n ogún ṣékélì oúnjẹ tí ìwọ yóò máa jẹ lójoojúmọ́ kí o sì máa jẹ ẹ́ ní àkókò tí a ti yà sọ́tọ̀.
وغذایی که می‌خوری به وزن خواهد بود، یعنی بیست مثقال برای هر روز. وقت به وقت آن راخواهی خورد.۱۰
11 Bákan náà, wọn ìdámẹ́fà omi, kí ìwọ ó sì máa mú ní àkókò tí a yà sọ́tọ̀.
و آب را به پیمایش یعنی سدس یک هین خواهی نوشید. آن را وقت به وقت خواهی نوشید.۱۱
12 Ìwọ yóò sì jẹ ẹ́ bí àkàrà barle; dín in ní ojú àwọn ènìyàn, ìgbẹ́ ènìyàn ni kí o fi dáná rẹ.”
و قرصهای نان جو که می‌خوری، آنها را بر سرگین انسان در نظر ایشان خواهی پخت.۱۲
13 Olúwa sọ pé, “Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò jẹ oúnjẹ àìmọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí èmi yóò lé wọn lọ.”
و خداوند فرمود به همین منوال بنی‌اسرائیل نان نجس در میان امت هایی که من ایشان را به میان آنها پراکنده می‌سازم خواهندخورد.»۱۳
14 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Kò rí bẹ́ẹ̀ Olúwa Olódùmarè! Láti ìgbà èwe mi di ìsinsin yìí èmi kò tí ì sọ ara mi di aláìmọ́ rí. Èmi kò tí ì jẹ ohun tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko búburú fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Bẹ́ẹ̀ ni ẹran àìmọ́ kan kò tí ì wọ ẹnu mi rí.”
پس گفتم: «آه‌ای خداوند یهوه اینک جان من نجس نشده و از طفولیت خود تا به حال میته یادریده شده را نخورده‌ام و خوراک نجس به دهانم نرفته است.»۱۴
15 Nígbà náà ló wí fún mi pé, “Wò ó, Èmi ó fún ọ ní ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn. Èmi yóò mú ki ó dín àkàrà rẹ lórí ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn.”
آنگاه به من گفت: «بدان که سرگین گاو را به عوض سرگین انسان به تو دادم، پس نان خود را بر آن خواهی پخت.»۱۵
16 Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èmi yóò dáwọ́ ìpèsè oúnjẹ dúró ní Jerusalẹmu. Ní pípín ni àwọn ènìyàn yóò máa pín oúnjẹ jẹ pẹ̀lú ìfọkànsọ́nà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wọn yóò máa mu omi pẹ̀lú ìdààmú,
و مرا گفت: «ای پسر انسان اینک من عصای نان را در اورشلیم خواهم شکست و نان را به وزن و عسرت خواهندخورد و آب را به پیمایش و حیرت خواهندنوشید.۱۶
17 nítorí pé oúnjẹ àti omi yóò wọ́n. Wọn yóò máa wo ara wọn pẹ̀lú ìyanu, èmi yóò sì jẹ́ kí wọ́n ṣọ̀fọ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
زیرا که محتاج نان و آب خواهند شد وبه حیرت بر یکدیگر نظر خواهند انداخت و به‌سبب گناهان خود گداخته خواهند شد.۱۷

< Ezekiel 4 >