< Ezekiel 4 >
1 “Nísinsin yìí, ìwọ ọmọ ènìyàn, mú amọ̀ ṣíṣù kan, gbé e sí iwájú rẹ, kí o sì ya àwòrán ìlú Jerusalẹmu sí orí rẹ̀.
“Wee, mũrũ wa mũndũ, rĩu oya iturubarĩ ũrĩige mbere yaku, ũcooke ũkurure itũũra inene rĩa Jerusalemu igũrũ rĩarĩo;
2 Kí o sì dó tì í, kí o sì mọ ilé ìṣọ́ tì í, kí o sì mọ odi tì í, kí o sì gbé ogun sí i, kí o sì to òòlù yí i ká.
Ũcooke ũrĩrigiicĩrie: Rĩakĩrĩre indo cia mbaara cia gũteithia gũtharĩkĩra itũũra, na wake kĩhumbu gĩkinyĩte itũũra, na ũrĩakĩrĩre kambĩ na nja, na ũigithie mĩgogo mĩtungu ya kũrĩmomora ĩrĩrigiicĩirie.
3 Kí o sì fi àwo irin kan ṣe ògiri láàrín rẹ̀ àti ìlú yìí, kí o sì kọjú sí i, a ó sì dó tì í, ìwọ yóò sì dó tì í. Èyí yóò jẹ́ àmì fún ilé Israẹli.
Cooka woe rũgĩo rwa kĩgera, ũrũige rũtuĩke taarĩ rũgiri rwa kĩgera gatagatĩ gaku na itũũra rĩu inene, na ũhũgũre ũthiũ waku na kũu rĩrĩ. Narĩo rĩrigiicĩrio, na nĩwe ũkaarĩrigiicĩria. Ũndũ ũcio nĩũgaatuĩka kĩmenyithia harĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli.
4 “Lẹ́yìn èyí, lọ fi ẹ̀gbẹ́ òsì dùbúlẹ̀, kí o sì gbé ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli lé orí ara rẹ. Iye ọjọ́ tí ìwọ bá fi sùn náà ni ìwọ yóò fi ru ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
“Ningĩ ũkome na mwena waku wa ũmotho, ũcooke wĩigĩrĩre mehia ma andũ a nyũmba ya Isiraeli. Nĩwe ũgaakuua mehia mao matukũ marĩa mothe ũgaakoma na mwena ũcio.
5 Nítorí mo fi iye ọdún tí wọ́n fi ṣẹ̀ fún ọ gẹ́gẹ́ bí iye ọjọ́ tí ìwọ yóò lò. Nítorí náà, ìwọ yóò ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
Nĩngũtuĩrĩire ũkome matukũ maiganaine na mĩaka ya mehia mao. Nĩ ũndũ ũcio matukũ magana matatũ na mĩrongo kenda nĩmo ũgaakuua mehia ma andũ a nyũmba ya Isiraeli.
6 “Tí o bá parí èyí, tún fi ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún dùbúlẹ̀ kí o sì ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Juda fún ogójì ọjọ́, nítorí pé ọjọ́ kan ló dúró fún ọdún kan.
“Warĩkia gwĩka ũguo, ũkome rĩngĩ, ihinda rĩĩrĩ na mwena waku wa ũrĩo, ũkuue mehia ma nyũmba ya Juda. Nĩngũtuĩrĩire matukũ mĩrongo ĩna, o mũthenya ũkarũgamĩrĩra mwaka ũmwe.
7 Ìwọ dojúkọ ìgbógunti Jerusalẹmu, na ọwọ́ rẹ sí i, kí o sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìlú náà.
Hũgũra ũthiũ waku ũwerekerie itũũra rĩa Jerusalemu rĩu rĩrigiicĩirio, ũrĩtambũrũkĩrie guoko kũhumbũrĩtio, ũrĩrathĩre ũhoro wa gũũkĩrĩrwo.
8 Èmi yóò dè ọ́ ní okùn dé bi pé ìwọ kò ní í le yírapadà láti ìhà ọ̀tún sí ìhà òsì títí tí ọjọ́ ìgbóguntì rẹ yóò fi pé.
Nĩngakuoha na mĩhĩndo nĩguo ndũkanahote kwĩgarũra na mwena ũmwe kana ũrĩa ũngĩ nginya rĩrĩa matukũ maku ma kũrigiicĩrio magaathira.
9 “Mú alikama, ọkà bàbà àti barle, erèé àti lẹntili, jéró àti ẹwẹ; fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe àkàrà tí ìwọ yóò máa jẹ nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀ fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
“Oya ngano na cairi, na mboco na ndengũ, na mwere na ngano njirũ; ciĩkĩre thĩinĩ wa ndigithũ ũcihũthagĩre gwĩthondekera mũgate. Mũgate ũcio nĩguo ũrĩrĩĩaga ihinda rĩa matukũ magana matatũ na mĩrongo kenda macio ũgũkorwo ũkomete na mwena.
10 Wọn òsùwọ̀n ogún ṣékélì oúnjẹ tí ìwọ yóò máa jẹ lójoojúmọ́ kí o sì máa jẹ ẹ́ ní àkókò tí a ti yà sọ́tọ̀.
Thima cekeri mĩrongo ĩĩrĩ cia irio iria ũrĩrĩĩaga o mũthenya na ũcirĩĩage mahinda marĩa mabange.
11 Bákan náà, wọn ìdámẹ́fà omi, kí ìwọ ó sì máa mú ní àkókò tí a yà sọ́tọ̀.
Ningĩ ũthime maaĩ gĩcunjĩ gĩa ithathatũ kĩa hini ĩmwe, na ũmanyuuage mahinda o marĩa mabange.
12 Ìwọ yóò sì jẹ ẹ́ bí àkàrà barle; dín in ní ojú àwọn ènìyàn, ìgbẹ́ ènìyàn ni kí o fi dáná rẹ.”
Rĩĩaga irio icio o ta ũrĩa ũngĩrĩa mũgate wa cairi; ũũruge andũ makĩonaga, ũhũthĩrĩte mwaki wakĩtio na mai ma mũndũ.”
13 Olúwa sọ pé, “Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò jẹ oúnjẹ àìmọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí èmi yóò lé wọn lọ.”
Jehova akiuga atĩrĩ, “Ũguo nĩguo andũ a Isiraeli makaarĩĩaga irio irĩ na thaahu marĩ gatagatĩ-inĩ ka ndũrĩrĩ, kũrĩa ngaamatwarithia.”
14 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Kò rí bẹ́ẹ̀ Olúwa Olódùmarè! Láti ìgbà èwe mi di ìsinsin yìí èmi kò tí ì sọ ara mi di aláìmọ́ rí. Èmi kò tí ì jẹ ohun tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko búburú fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Bẹ́ẹ̀ ni ẹran àìmọ́ kan kò tí ì wọ ẹnu mi rí.”
Na niĩ ngiuga atĩrĩ, “Ũguo ti guo, Mwathani Jehova! Niĩ ndirĩ ndethaahia. Kuuma ũnini wakwa nginya rĩu, ndirĩ ndarĩa nyama ya nyamũ ĩkuĩte kana ĩtambuurĩtwo nĩ nyamũ cia gĩthaka. Gũtirĩ nyama ĩrĩ mũgiro ĩrĩ yatoonya kanua gakwa.”
15 Nígbà náà ló wí fún mi pé, “Wò ó, Èmi ó fún ọ ní ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn. Èmi yóò mú ki ó dín àkàrà rẹ lórí ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn.”
Nake akiuga atĩrĩ, “Ũguo nĩ wega; nĩngũreke ũruge mũgate waku na mai ma ngʼombe, handũ ha mwaki wa mai ma mũndũ.”
16 Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èmi yóò dáwọ́ ìpèsè oúnjẹ dúró ní Jerusalẹmu. Ní pípín ni àwọn ènìyàn yóò máa pín oúnjẹ jẹ pẹ̀lú ìfọkànsọ́nà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wọn yóò máa mu omi pẹ̀lú ìdààmú,
Nake agĩcooka akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Mũrũ wa mũndũ, nĩngagirĩrĩria irio itigatoonye Jerusalemu. Andũ acio makaarĩĩaga irio cia gĩthimo magĩtangĩkaga, na manyuuage maaĩ ma gĩthimo matarĩ na kĩĩrĩgĩrĩro,
17 nítorí pé oúnjẹ àti omi yóò wọ́n. Wọn yóò máa wo ara wọn pẹ̀lú ìyanu, èmi yóò sì jẹ́ kí wọ́n ṣọ̀fọ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
nĩ ũndũ nĩgũgakorwo na ũnyiihu wa irio na wa maaĩ. Nĩmakamakaga moona o mũndũ ũrĩa atariĩ na nĩmakahĩnja nĩ ũndũ wa mehia mao.