< Ezekiel 39 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
Och du menniskobarn, prophetera emot Gog, och säg: Detta säger Herren Herren: Si, jag vill till dig, Gog, du som en Förste äst af de herrar i Mesech och Thubal.
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
Si, jag skall böja dig omkring, och utlocka dig, och hemta dig ifrå de ändar nordanefter, och låta dig komma in på Israels berg;
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Och skall slå bågan utu dine venstra hand, och bortkasta dina pilar utu dine högra hand.
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
På Israels bergom skall du nederlagd varda, du med allom dinom här, och med det folk som när dig är. Jag skall gifva dig foglom ehvadan de flyga, och djurom på markene till spis.
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Du skall falla på markene; ty jag, Herren Herren, hafver det sagt.
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Och jag skall kasta eld uppå Magog, och uppå dem som i öarna säkre bo, och de skola förnimma, att jag är Herren.
7 “‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
Ty jag vill göra mitt helga Namn kunnigt ibland mitt folk Israel, och skall icke längre låta skämma mitt helga Namn; utan Hedningarne skola förnimma, att jag är Herren, den Helige i Israel.
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
Si, det är allaredo kommet och skedt, säger Herren Herren; det är den dagen, der jag om talat hafver.
9 “‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
Och borgarena uti Israels städer skola utgå, och göra en eld, och uppbränna vapnen, sköldar, spetsar, bågar, pilar, stafrar och stänger, och skola dermed uppehålla eld i sju år;
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
Så att man intet skall behöfva sammanhemta någon ved på markene, eller hugga i skogenom, utan med de vapen skola de uppehålla eld, och skola skinna dem, af hvilkom de skinnade voro, och sköfla dem, af hvilkom de sköflade voro, säger Herren Herren.
11 “‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
Och det skall på den tiden ske, att jag skall gifva Gog ett rum till begrafning i Israel, nämliga den dalen der man går till hafvet österut; så att de der framgå, skola grufva sig derföre, efter man der hafver begrafvit Gog med sinom hop; och det skall kallas Gogs hops dal;
12 “‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
Men Israels hus skall begrafva dem i sju månader långt, att landet skall dermed rensadt varda.
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Ja, allt folket i landena skall hafva till skaffa med deras begrafning, och skall hafva berömmelse deraf, att jag på den dagen mina härlighet bevisat hafver, säger Herren Herren.
14 “‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
Och de skola utskicka män, som allestäds gå omkring i landena, och med dem dödgrafvare, till att begrafva de igenblefna på landena, att det må rensadt varda; efter sju månader skola de begynna ransaka derefter.
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
Och de som omkring landet gå, och någorstäds ene menniskos ben se, de skola uppresa der ett tecken, tilldess att dödgrafvarena begrafva dem också med uti Gogs hops dal.
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
Så skall ock staden heta der Hamona. Alltså skola de rensa landet.
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
Nu, du menniskobarn, så säger Herren Herren: Säg allom foglom, ehvadan de flyga, och allom djurom på markene: Församler eder, och kommer hit, kommer tillhopa allt omkring till mitt slagtoffer, det jag slagtar eder till ett stort slagtoffer, på Israels bergom; och äter kött, och dricker blod.
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
De starkas kött skolen I äta, och förstarnas blod på jordene skolen I dricka; vädrars, lambars, bockars, oxars, hvilke allesammans fete och välgödde äro;
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
Och skolen äta det feta, så att i mätte varden, och dricka blodet, att I druckne varden af det slagtoffer, som jag eder slagtar.
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Mätter eder nu öfver mitt bord, af hästar och resenärar, af starkom och allahanda krigsfolke, säger Herren Herren.
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
Och jag skall låta komma mina härlighet ibland Hedningarna, att alle Hedningar skola se min dom, som jag hafver gå låtit, och mina hand, den jag uppå dem lagt hafver;
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
Och Israels hus alltså, förnimma skall, att jag, Herren, är deras Gud, ifrå den dagen och allt framåt;
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
Och desslikes alle Hedningar skola förnimma, att Israels hus för sina missgerningars skull, och för det de emot mig syndat hade, bortförde voro; hvarföre jag fördolde mitt ansigte för dem, och öfvergaf dem uti deras fiendars händer, så att de allesamman genom svärd falla måste.
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Såsom deras synder och öfverträdelse förtjent hade, gjorde jag dem, och fördolde alltså mitt ansigte för dem.
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
Derföre så säger Herren Herren: Nu vill jag förlossa Jacobs fångar, och förbarma mig öfver hela Israels hus, och nit hafva om mitt helga Namn.
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
Men de skola gerna bära sin försmädelse och sina synder, der de med emot mig syndat hafva, när de säkre uti sitt land bo måga, så att dem ingen förskräcker;
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
Och jag dem ifrå, folken hem igen hemtat, och utu deras fiendars land församlat hafver, och jag i dem helgad vorden är, inför många Hedningars ögon.
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
Alltså skola de förnimma, att jag, Herren, är deras Gud, som dem hafver Iåtit bortföra ibland Hedningarna, och åter låtit församla dem uti sitt land igen, och icke en af dem der blifva låtit;
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Och skall icke mer fördölja mitt ansigte för dem; ty jag hafver utgjutit min Anda öfver Israels hus, säger Herren Herren.

< Ezekiel 39 >